< Proverbs 2 >
1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
Mon fils, si tu reçois mes paroles et que tu caches par-devers toi mes commandements
2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
pour rendre ton oreille attentive à la sagesse, si tu inclines ton cœur à l’intelligence,
3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
si tu appelles le discernement, si tu adresses ta voix à l’intelligence,
4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
si tu la cherches comme de l’argent et que tu la recherches comme des trésors cachés,
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
alors tu comprendras la crainte de l’Éternel et tu trouveras la connaissance de Dieu.
6 Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
Car l’Éternel donne la sagesse; de sa bouche [procèdent] la connaissance et l’intelligence:
7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
il réserve de sains conseils pour les hommes droits; il est un bouclier pour ceux qui marchent dans l’intégrité,
8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
protégeant les sentiers de juste jugement et gardant la voie de ses saints.
9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
Alors tu discerneras la justice et le juste jugement et la droiture, toute bonne voie.
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
Si la sagesse entre dans ton cœur et si la connaissance est agréable à ton âme,
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
la réflexion te préservera, l’intelligence te protégera:
12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
Pour te sauver du mauvais chemin, de l’homme qui prononce des choses perverses,
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
[de ceux] qui abandonnent les sentiers de la droiture pour marcher dans les voies de ténèbres,
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
qui se réjouissent à mal faire, qui s’égaient en la perversité du mal,
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
dont les sentiers sont tortueux et qui s’égarent dans leurs voies;
16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
Pour te sauver de la femme étrangère, de l’étrangère qui use de paroles flatteuses,
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
qui abandonne le guide de sa jeunesse, et qui a oublié l’alliance de son Dieu;
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
– car sa maison penche vers la mort, et ses chemins vers les trépassés:
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
aucun de ceux qui entrent auprès d’elle ne revient ni n’atteint les sentiers de la vie;
20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
– afin que tu marches dans la voie des gens de bien, et que tu gardes les sentiers des justes.
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
Car les hommes droits habiteront le pays, et les hommes intègres y demeureront de reste;
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.
mais les méchants seront retranchés du pays, et les perfides en seront arrachés.