< Proverbs 2 >

1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
Mon fils, si tu reçois mes paroles; et si tu gardes avec toi mes préceptes;
2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
rendant ton oreille attentive à la sagesse, et inclinant ton cœur vers l’intelligence;
3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
oui, si tu appelles la prudence, et si tu élèves ta voix vers l’intelligence,
4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
si tu la cherches comme l’argent, et si tu la creuses comme pour découvrir un trésor; —
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
alors tu comprendras la crainte de Yahweh, et tu trouveras la connaissance de Dieu.
6 Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
Car Yahweh donne la sagesse, de sa bouche sortent la science et la prudence;
7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
il garde le bonheur pour les hommes droits, il est un bouclier pour ceux qui marchent dans la perfection;
8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
il protège les sentiers de l’équité, il veille sur la voie de ses fidèles. —
9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
Alors tu comprendras la justice, l’équité, la droiture et tous les sentiers du bien.
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
Lorsque la sagesse viendra dans ton cœur, et que la science fera les délices de ton âme,
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
la réflexion veillera sur toi, et l’intelligence te gardera,
12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
pour te délivrer de la voie du mal, de l’homme qui tient des discours pervers,
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
de ceux qui abandonnent les droits sentiers, afin de marcher dans des chemins ténébreux,
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
qui se réjouissent de faire le mal, et mettent leur plaisir dans les pires perversités,
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
dont les sentiers sont tortueux et qui suivent des voies obliques; —
16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
pour te délivrer de la femme qui est à un autre, de l’étrangère qui use de paroles doucereuses,
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
qui abandonne le compagnon de sa jeunesse, et oublie l’alliance de son Dieu;
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
car elle penche avec sa maison vers la mort, et sa route conduit aux enfers;
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
de tous ceux qui vont à elle, nul ne revient, aucun ne retrouve les sentiers de la vie.
20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
Ainsi tu marcheras dans la voie des hommes de bien, et tu garderas les sentiers des justes.
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
Car les hommes droits habiteront la terre et les hommes intègres y demeureront;
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.
mais les méchants seront retranchés de la terre, et les infidèles en seront arrachés.

< Proverbs 2 >