< Proverbs 2 >
1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
My son, if thou wouldst but accept my words, and treasure up my commandments with thee;
2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
To let thy ear listen unto wisdom: [if] thou wouldst incline thy heart to understanding.
3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
For if thou wilt call after intelligence; if after understanding thou wilt lift up thy voice;
4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
If thou wilt seek her as silver, and search for her as for hidden treasures:
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
Then wilt thou understand the fear of the Lord, and the knowledge of God wilt thou find.
6 Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
For the Lord giveth wisdom: out of his mouth [come] knowledge and understanding.
7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
He treasureth up sound wisdom for the righteous, as a shield to those that walk in integrity:
8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
That men may keep the paths of justice; and the way of his pious servants doth he guard.
9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
Then wilt thou understand righteousness, and justice, and equity: yea, every track of goodness.
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
For wisdom will enter thy heart, and knowledge will be pleasant unto thy soul;
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
Discretion will watch over thee, understanding will keep thee;
12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
To deliver thee from the way of the bad, from the man that speaketh perverse things;
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
[From those] who leave the paths of uprightness, to walk in the ways of darkness;
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
Who rejoice to do evil, who are delighted in the perverseness of the bad;
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
Who as regardeth their paths are crooked, and froward in their tracks.
16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
To deliver thee from the adulteress, from the alien woman that useth flattering speeches;
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
That forsaketh the friend of her youth, and forgetteth the covenant of her God.
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
For she sinketh unto death—her house, and unto the departed [lead] her tracks.
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
All that come unto her return not again, and they will not reach the paths of life.
20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
In order that thou mayest walk in the way of good men, and observe the paths of the righteous.
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
For the upright will dwell on the earth, and the perfect will be left remaining on it.
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.
But the wicked will be cut off from the earth, and the treacherous shall be plucked up therefrom.