< Proverbs 2 >

1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
Min Søn! dersom du vil tage imod mine Ord og gemme mine Rud hos dig,
2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
saa at du lader dit Øre give Agt paa Visdommen, bøjer dit Hjerte til Indsigt;
3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
ja, dersom du kalder paa Forstanden, opløfter din Røst efter Indsigt;
4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
dersom du søger efter den som efter Sølv og ransager efter den som efter skjulte Skatte:
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
Da skal du forstaa Herrens Frygt og finde Guds Kundskab.
6 Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
Thi Herren giver Visdom, af hans Mund er Kundskab og Indsigt.
7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
Han gemmer det varige gode til de oprigtige; han er et Skjold for dem, som vandre fuldkommelig,
8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
saa han bevogter Rettens Stier og bevarer sine helliges Vej.
9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
Da skal du forstaa Ret og Retfærdighed og Retvished, al god Vej.
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
Thi Visdom skal komme i dit Hjerte og Kundskab være liflig for din Sjæl.
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
Kløgt skal bevare dig og Indsigt bevogte dig
12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
for at fri dig fra Ondskabs Vej, fra en Mand, som taler forvendte Ting;
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
fra dem, som forlade Rettens Stier for at gaa paa Mørkets Veje;
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
dem, som glæde sig ved at gøre ondt og fryde sig i Ondskabs Forvendthed;
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
dem, hvis Stier ere krogede, og hvis Veje ere bugtede;
16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
for at fri dig fra en fremmed Kvinde, fra en ubekendt, som gør sine Ord glatte,
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
hende, som har forladt sin Ungdoms Ven, og som har glemt sin Guds Pagt;
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
thi hendes Hus bøjer ned imod Døden og hendes Veje til Dødningerne;
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
alle de, som gaa ind til hende, skulle ikke komme tilbage og ikke naa Livsens Stier; —
20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
paa det du kan vandre paa de godes Vej og holde dig paa de retfærdiges Stier.
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
Thi de retskafne skulle bo i Landet og de oprigtige blive tilovers derudi;
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.
men de ugudelige skulle udryddes af Landet og de troløse udslettes deraf.

< Proverbs 2 >