< Proverbs 19 >

1 Ó sàn kí ènìyàn jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ kò lábùkù ju aláìgbọ́n tí ètè rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà.
Le pauvre qui marche dans son intégrité, vaut mieux que celui qui pervertit ses lèvres, et qui est fou.
2 Kò dára láti ní ìtara láìní ìmọ̀, tàbí kí ènìyàn kánjú kí ó sì ṣìnà.
La vie même sans science n'est pas une chose bonne; et celui qui se hâte des pieds, s'égare.
3 Ìwà òmùgọ̀ ènìyàn fúnra rẹ̀ a pa ẹ̀mí rẹ̀ run; síbẹ̀ ọkàn rẹ̀ yóò máa bínú sí Olúwa.
La folie de l'homme renversera son intention, et son cœur se dépitera contre l'Eternel.
4 Ọrọ̀ máa ń fa ọ̀rẹ́ púpọ̀; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ tálákà tún kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
Les richesses assemblent beaucoup d'amis; mais celui qui est pauvre, est abandonné de son ami.
5 Ajẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà, ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde kò ní lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
Le faux témoin ne demeurera point impuni; et celui qui profère des mensonges, n'échappera point.
6 Ọ̀pọ̀ ń wá ojúrere olórí; gbogbo ènìyàn sì ni ọ̀rẹ́ ẹni tí ó lawọ́.
Plusieurs supplient celui qui est en état [de faire du bien], et chacun est ami d'un homme qui donne.
7 Gbogbo ará ilé e tálákà ni ó pa á tì, mélòó mélòó ni ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tí ń sá fún un! Bí ó tilẹ̀ ń lé wọn kiri pẹ̀lú ẹ̀bẹ̀, kò tilẹ̀ le rí wọn rárá.
Tous les frères du pauvre le haïssent; combien plus ses amis se retireront-ils de lui? Poursuit-il? il n'y a que des paroles pour lui.
8 Ẹni tí ó gba ọgbọ́n fẹ́ràn ọkàn ara rẹ̀; ẹni tí ó bá káràmáṣìkí òye yóò gbèrú.
Celui qui acquiert du sens, aime son âme; et celui qui prend garde à l'intelligence, c'est pour trouver le bien.
9 Ajẹ́rìí èké kì yóò lọ láìjìyà ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde yóò parun.
Le faux témoin ne demeurera point impuni; et celui qui profère des mensonges, périra.
10 Kò yẹ aláìgbọ́n láti máa gbé nínú ọláńlá, mélòó mélòó bí ó ti burú tó fún ẹrú láti jẹ ọba lórí ọmọ-aládé.
L'aise ne sied pas bien à un fou; combien moins sied-il à un esclave, de dominer sur les personnes de distinction?
11 Ọgbọ́n ènìyàn a máa fún un ní sùúrù; fún ògo rẹ̀ ni láti fojú fo àṣìṣe dá.
La prudence de l'homme retient sa colère; c'est un honneur pour lui de passer par-dessus le tort qu'on lui fait.
12 Ìbínú ọba dàbí kíké e kìnnìún, ṣùgbọ́n ojúrere rẹ̀ dàbí ìrì lára koríko.
L'indignation du Roi est comme le rugissement d'un jeune lion; mais sa faveur est comme la rosée sur l'herbe.
13 Aṣiwèrè ọmọ jẹ́ ìparun baba rẹ̀, aya tí ó máa ń jà sì dàbí ọ̀ṣọ̀ọ̀rọ̀ òjò.
L'enfant insensé est un grand malheur à son père, et les querelles de la femme sont une gouttière continuelle.
14 A máa ń jogún ilé àti ọrọ̀ lọ́dọ̀ òbí, ṣùgbọ́n aya olóye láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni.
La maison et les richesses sont l'héritage des pères; mais la femme prudente est de par l'Eternel.
15 Ọ̀lẹ ṣíṣe máa ń fa oorun sísùn fọnfọn, ebi yóò sì máa pa ènìyàn tí ó lọ́ra.
La paresse fait venir le sommeil, et l'âme négligente aura faim.
16 Ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́ ẹ̀kọ́ pa ẹnu rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá kẹ́gàn ọ̀nà rẹ̀ yóò kú.
Celui qui garde le commandement, garde son âme; [mais] celui qui méprise ses voies, mourra.
17 Ẹni tí ó ṣàánú tálákà, Olúwa ní ó yá, yóò sì pín in lérè ohun tí ó ti ṣe.
Celui qui a pitié du pauvre, prête à l'Eternel, et il lui rendra son bienfait.
18 Bá ọmọ rẹ wí nítorí nínú ìyẹn ni ìrètí wà; àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ lọ́wọ́ nínú ìparun un rẹ̀.
Châtie ton enfant tandis qu'il y a de l'espérance, et ne va point jusqu'à le faire mourir.
19 Ènìyàn onínú-fùfù gbọdọ̀ gba èrè ìwà rẹ̀; bí ìwọ bá gbà á là, ìwọ yóò tún ní láti ṣe é lẹ́ẹ̀kan sí i.
Celui qui est de grande furie en porte la peine; et si tu l'en retires, tu y en ajouteras davantage.
20 Fetí sí ìmọ̀ràn kí o sì gba ẹ̀kọ́, ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín ìwọ yóò di ọlọ́gbọ́n.
Ecoute le conseil, et reçois l'instruction, afin que tu deviennes sage en ton dernier temps.
21 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ète inú ọkàn ènìyàn, ṣùgbọ́n ìfẹ́ Olúwa ní ó máa ń borí.
Il y a plusieurs pensées au cœur de l'homme, mais le conseil de l'Eternel est permanent.
22 Ohun tí ènìyàn ń fẹ́ ni ìfẹ́ tí kì í yẹ̀; ó sàn láti jẹ́ tálákà ju òpùrọ́ lọ.
Ce que l'homme doit désirer, c'est d'user de miséricorde; et le pauvre vaut mieux que l'homme menteur.
23 Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ìyè wá; nígbà náà ọkàn ń balẹ̀, láìsí ewu.
La crainte de l'Eternel conduit à la vie, et celui qui l'a, passera la nuit étant rassasié, sans qu'il soit visité d'aucun mal.
24 Ọ̀lẹ ki ọwọ́ rẹ̀ bọ inú àwo oúnjẹ; kò tilẹ̀ ní mú u padà wá sí ẹnu rẹ̀.
Le paresseux cache sa main dans le sein, et il ne daigne même pas la ramener à sa bouche.
25 Na ẹlẹ́gàn, òpè yóò sì kọ́gbọ́n; bá olóye ènìyàn wí, yóò sì ní ìmọ̀ sí i.
Si tu bats le moqueur, le niais en deviendra avisé; et si tu reprends l'homme intelligent, il entendra ce qu'il faut savoir.
26 Ẹni tí ó ṣìkà sí baba rẹ̀, tí ó sì lé ìyá rẹ̀ jáde òun ni ọmọ tí ń ṣe ìtìjú, tí ó sì mú ẹ̀gàn wá.
L'enfant qui fait honte et confusion, détruit le père, et chasse la mère.
27 Ọmọ mi, dẹ́kun láti tẹ́tí sí ẹ̀kọ́, tí í mú ni ṣìnà kúrò nínú ọ̀rọ̀-ìmọ̀.
Mon fils, cesse d'ouïr ce qui te pourrait apprendre à te fourvoyer des paroles de la science.
28 Ẹlẹ́rìí búburú fi ìdájọ́ ṣẹ̀sín, ẹnu ènìyàn búburú sì ń gbé ibi mì.
Le témoin qui a un mauvais cœur se moque de la justice; et la bouche des méchants engloutit l'iniquité.
29 A ti pèsè ìjìyà sílẹ̀ fún ẹlẹ́gàn; àti pàṣán fún ẹ̀yìn àwọn aṣiwèrè.
Les jugements sont préparés pour les moqueurs, et les grands coups pour le dos des fous.

< Proverbs 19 >