< Proverbs 18 >
1 Ènìyàn tí kò ba ni rẹ́ a máa lépa ìmọ̀ ara rẹ̀; ó kọjú ìjà sí gbogbo ìdájọ́ òdodo.
Busca coisas desejaveis aquelle que se separa e se entremette em toda a sabedoria.
2 Aláìgbọ́n kò rí inú dídùn sí òye ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí sísọ èrò tirẹ̀.
Não toma prazer o tolo na intelligencia, senão em que se descubra o seu coração.
3 Nígbà ti ènìyàn búburú dé ni ẹ̀gàn dé, nígbà ti ẹ̀gàn dé ni ìtìjú dé.
Vindo o impio, vem tambem o desprezo, e com a vergonha a ignominia.
4 Ọ̀rọ̀ ẹnu ènìyàn jẹ́ omi jíjìn, ṣùgbọ́n orísun ọgbọ́n jẹ́ odò tí ń sàn.
Aguas profundas são as palavras da bocca do homem, e ribeiro trasbordante é a fonte da sabedoria.
5 Kò dára kí ènìyàn ṣe ojúsàájú fún ènìyàn búburú tàbí kí a fi ìdájọ́ òdodo du aláìṣẹ̀.
Não é bom ter respeito á pessoa do impio para derribar o justo em juizo.
6 Ètè aláìgbọ́n dá ìjà sílẹ̀ ẹnu rẹ̀ sì ń ṣokùnfà ẹgba.
Os beiços do tolo entram na contenda, e a sua bocca por acoites brada.
7 Ẹnu aláìgbọ́n ni ó ba tirẹ̀ jẹ́, ètè rẹ̀ sì jẹ́ ìdẹ̀kùn fún ọkàn rẹ̀.
A bocca do tolo é a sua propria destruição, e os seus labios um laço para a sua alma.
8 Ọ̀rọ̀ olófòófó dàbí oúnjẹ àdídùn; wọ́n a sì wọ ìsàlẹ̀ inú lọ.
As palavras do assoprador são como doces bocados; e ellas descem ao intimo do ventre.
9 Ẹni tí kò ṣe déédé nínú iṣẹ́ rẹ̀ arákùnrin ló jẹ́ fún apanirun.
Tambem o negligente na sua obra é irmão do desperdiçador.
10 Orúkọ Olúwa, ilé ìṣọ́ agbára ni; olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì rí ìgbàlà.
Torre forte é o nome do Senhor; a elle correrá o justo, e estará em alto retiro.
11 Ọ̀rọ̀ olówó ni ìlú olódi wọn; wọ́n rò ó bí i wí pé odi tí kò ṣe é gùn ni.
A fazenda do rico é a cidade da sua fortaleza, e como um muro alto na sua imaginação.
12 Ṣáájú ìṣubú ọkàn ènìyàn a kọ́kọ́ máa gbéraga, ṣùgbọ́n ìrẹ̀lẹ̀ ni ó máa ń ṣáájú ọlá.
Antes de ser quebrantado eleva-se o coração do homem; e diante da honra vae a humildade.
13 Ẹni tí ó ń fèsì kí ó tó gbọ́, èyí ni ìwà òmùgọ̀ àti ìtìjú rẹ̀.
O que responde antes d'ouvir, estulticia lhe é, e vergonha.
14 Ọkàn ènìyàn a máa gbé e ró nígbà àìsàn, ṣùgbọ́n ta ni ó le forí ti ọkàn tí ó rẹ̀wẹ̀sì.
O espirito do homem sosterá a sua enfermidade, mas ao espirito abatido quem levantará?
15 Ọkàn olóye ní i gba ìmọ̀; etí ọlọ́gbọ́n ní í ṣe àwárí rẹ̀.
O coração do entendido adquire o conhecimento, e o ouvido dos sabios busca o conhecimento.
16 Ẹ̀bùn máa ń ṣí ọ̀nà fún ẹni tí ń fún ni lẹ́bùn a sì mú un wọlé sí ọ̀dọ̀ àwọn olókìkí.
O presente do homem lhe alarga o caminho e o leva diante dos grandes.
17 Ẹni tí ó kọ́kọ́ rọjọ́ máa ń dàbí i pé ó jàre, títí ẹlòmíràn yóò fi bọ́ síwájú kí ó sì tú àṣírí gbogbo.
O que primeiro começa o seu pleito justo é; porém vem o seu companheiro, e o examina.
18 Ìbò dídì máa ń parí ìjà a sì mú kí àwọn alátakò méjì jìnnà sí ara wọn.
A sorte faz cessar os pleitos, e faz separação entre os poderosos.
19 Arákùnrin tí a ṣẹ̀ sí ṣòro yípadà ju ìlú olódi lọ, ìjà wọ sì dàbí ọ̀pá ìdábùú ààfin.
O irmão offendido é mais difficil de conquistar do que uma cidade forte; e as contendas são como os ferrolhos d'um palacio.
20 Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ikùn ènìyàn a yó; láti inú ìkórè ẹnu rẹ̀ ni ó ti jẹ yó.
Do fructo da bocca de cada um se fartará o seu ventre: dos renovos dos seus labios se fartará.
21 Ikú àti ìyè ń bẹ nípa ahọ́n wọn, àwọn tí ó sì fẹ́ràn rẹ̀ yóò jẹ ẹ́.
A morte e a vida estão no poder da lingua; e aquelle que a ama comerá do seu fructo.
22 Ẹni tí ó rí aya fẹ́, rí ohun rere, o sì gba ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa.
O que acha mulher acha o bem e alcança a benevolencia do Senhor.
23 Tálákà ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú, ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ a dáhùn pẹ̀lú ìkanra.
O pobre falla com rogos, mas o rico responde com durezas.
24 Ènìyàn tí ó ní ọ̀rẹ́ púpọ̀ le è parun, ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ kan wà tí ó súnmọ́ ni tímọ́tímọ́ ju arákùnrin.
O homem que tem amigos haja-se amigavelmente, e ha amigo mais chegado do que um irmão.