< Proverbs 18 >

1 Ènìyàn tí kò ba ni rẹ́ a máa lépa ìmọ̀ ara rẹ̀; ó kọjú ìjà sí gbogbo ìdájọ́ òdodo.
Svémyslný hledá toho, což se jemu líbí, a ve všelijakou věc plete se.
2 Aláìgbọ́n kò rí inú dídùn sí òye ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí sísọ èrò tirẹ̀.
Nezalibuje sobě blázen v rozumnosti, ale v tom, což zjevuje srdce jeho.
3 Nígbà ti ènìyàn búburú dé ni ẹ̀gàn dé, nígbà ti ẹ̀gàn dé ni ìtìjú dé.
Když přijde bezbožný, přichází také pohrdání, a s lehkomyslným útržka.
4 Ọ̀rọ̀ ẹnu ènìyàn jẹ́ omi jíjìn, ṣùgbọ́n orísun ọgbọ́n jẹ́ odò tí ń sàn.
Slova úst muže vody hluboké, potok rozvodnilý pramen moudrosti.
5 Kò dára kí ènìyàn ṣe ojúsàájú fún ènìyàn búburú tàbí kí a fi ìdájọ́ òdodo du aláìṣẹ̀.
Přijímati osobu bezbožného není dobré, abys převrátil spravedlivého v soudu.
6 Ètè aláìgbọ́n dá ìjà sílẹ̀ ẹnu rẹ̀ sì ń ṣokùnfà ẹgba.
Rtové blázna směřují k svadě, a ústa jeho bití se domluví.
7 Ẹnu aláìgbọ́n ni ó ba tirẹ̀ jẹ́, ètè rẹ̀ sì jẹ́ ìdẹ̀kùn fún ọkàn rẹ̀.
Ústa blázna k setření jemu, a rtové jeho osídlem duši jeho.
8 Ọ̀rọ̀ olófòófó dàbí oúnjẹ àdídùn; wọ́n a sì wọ ìsàlẹ̀ inú lọ.
Slova utrhače jsou jako ubitých, ale však sstupují do vnitřností života.
9 Ẹni tí kò ṣe déédé nínú iṣẹ́ rẹ̀ arákùnrin ló jẹ́ fún apanirun.
Také ten, kdož jest nedbalý v práci své, bratr jest mrhače.
10 Orúkọ Olúwa, ilé ìṣọ́ agbára ni; olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì rí ìgbàlà.
Věže pevná jest jméno Hospodinovo; k němu se uteče spravedlivý, a bude povýšen.
11 Ọ̀rọ̀ olówó ni ìlú olódi wọn; wọ́n rò ó bí i wí pé odi tí kò ṣe é gùn ni.
Zboží bohatého jest město pevné jeho, a jako zed vysoká v mysli jeho.
12 Ṣáájú ìṣubú ọkàn ènìyàn a kọ́kọ́ máa gbéraga, ṣùgbọ́n ìrẹ̀lẹ̀ ni ó máa ń ṣáájú ọlá.
Před setřením vyvyšuje se srdce člověka, ale před povýšením bývá ponížení.
13 Ẹni tí ó ń fèsì kí ó tó gbọ́, èyí ni ìwà òmùgọ̀ àti ìtìjú rẹ̀.
Kdož odpovídá něco, prvé než vyslyší, počítá se to za bláznovství jemu a za lehkost.
14 Ọkàn ènìyàn a máa gbé e ró nígbà àìsàn, ṣùgbọ́n ta ni ó le forí ti ọkàn tí ó rẹ̀wẹ̀sì.
Duch muže snáší nemoc svou, ducha pak zkormouceného kdo snese?
15 Ọkàn olóye ní i gba ìmọ̀; etí ọlọ́gbọ́n ní í ṣe àwárí rẹ̀.
Srdce rozumného dosahuje umění, a ucho moudrých hledá umění.
16 Ẹ̀bùn máa ń ṣí ọ̀nà fún ẹni tí ń fún ni lẹ́bùn a sì mú un wọlé sí ọ̀dọ̀ àwọn olókìkí.
Dar člověka uprostranňuje jemu, a před oblíčej mocných přivodí jej.
17 Ẹni tí ó kọ́kọ́ rọjọ́ máa ń dàbí i pé ó jàre, títí ẹlòmíràn yóò fi bọ́ síwájú kí ó sì tú àṣírí gbogbo.
Spravedlivý zdá se ten, kdož jest první v své při, ale když přichází bližní jeho, tedy stihá jej.
18 Ìbò dídì máa ń parí ìjà a sì mú kí àwọn alátakò méjì jìnnà sí ara wọn.
Los pokojí svady, a mezi silnými rozeznává.
19 Arákùnrin tí a ṣẹ̀ sí ṣòro yípadà ju ìlú olódi lọ, ìjà wọ sì dàbí ọ̀pá ìdábùú ààfin.
Bratr křivdou uražený tvrdší jest než město nedobyté, a svárové jsou jako závora u hradu.
20 Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ikùn ènìyàn a yó; láti inú ìkórè ẹnu rẹ̀ ni ó ti jẹ yó.
Ovocem úst jednoho každého nasyceno bývá břicho jeho, úrodou rtů svých nasycen bude.
21 Ikú àti ìyè ń bẹ nípa ahọ́n wọn, àwọn tí ó sì fẹ́ràn rẹ̀ yóò jẹ ẹ́.
Smrt i život jest v moci jazyka, a ten, kdož jej miluje, bude jísti ovoce jeho.
22 Ẹni tí ó rí aya fẹ́, rí ohun rere, o sì gba ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa.
Kdo nalezl manželku, nalezl věc dobrou, a navážil lásky od Hospodina.
23 Tálákà ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú, ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ a dáhùn pẹ̀lú ìkanra.
Poníženě mluví chudý, ale bohatý odpovídá tvrdě.
24 Ènìyàn tí ó ní ọ̀rẹ́ púpọ̀ le è parun, ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ kan wà tí ó súnmọ́ ni tímọ́tímọ́ ju arákùnrin.
Ten, kdož má přátely, má se míti přátelsky, poněvadž přítel bývá vlastnější než bratr.

< Proverbs 18 >