< Proverbs 16 >
1 Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.
Los planes del corazón pertenecen al hombre, pero la respuesta de la lengua es de Yahvé.
2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.
Todos los caminos del hombre son limpios ante sus propios ojos, pero Yahvé sopesa los motivos.
3 Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé Olúwa lọ́wọ́, èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.
Encomienda tus obras a Yahvé, y tus planes tendrán éxito.
4 Olúwa ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́ kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.
Yahvé ha hecho todo para su propio fin. sí, incluso los malvados para el día del mal.
5 Olúwa kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀ mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.
Todo el que es orgulloso de corazón es una abominación para Yahvé; ciertamente no quedarán impunes.
6 Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀ nípasẹ̀ ìbẹ̀rù Olúwa ènìyàn sá fún ibi.
Por la misericordia y la verdad se expía la iniquidad. Por el temor a Yahvé los hombres se apartan del mal.
7 Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ Olúwa lọ́rùn, yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.
Cuando los caminos del hombre agradan a Yahvé, hace que hasta sus enemigos estén en paz con él.
8 Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ.
Mejor es un poco con la justicia, que los grandes ingresos con la injusticia.
9 Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.
El corazón del hombre planea su curso, pero Yahvé dirige sus pasos.
10 Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké.
Los juicios inspirados están en los labios del rey. No traicionará su boca.
11 Òdínwọ̀n àti òsùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.
Las balanzas y los platillos honestos son de Yahvé; todos los pesos de la bolsa son obra suya.
12 Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́ nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.
Es una abominación que los reyes hagan el mal, porque el trono se establece por la justicia.
13 Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́, wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́.
Los labios justos son la delicia de los reyes. Valoran a quien dice la verdad.
14 Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́ ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.
La ira del rey es un mensajero de la muerte, pero un hombre sabio lo apaciguará.
15 Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè; ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.
En la luz del rostro del rey está la vida. Su favor es como una nube de la lluvia de primavera.
16 Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ àti láti yan òye dípò o fàdákà!
¡Cuánto mejor es conseguir sabiduría que oro! Sí, conseguir la comprensión es ser elegido más que la plata.
17 Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi, ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.
El camino de los rectos es apartarse del mal. El que guarda su camino preserva su alma.
18 Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun, agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú.
La soberbia precede a la destrucción, y un espíritu arrogante antes de una caída.
19 Ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrín àwọn olùpọ́njú jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.
Es mejor tener un espíritu humilde con los pobres, que repartir el botín con los orgullosos.
20 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ìre, ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
El que presta atención a la Palabra encuentra la prosperidad. Quien confía en Yahvé es bendecido.
21 Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.
Los sabios de corazón serán llamados prudentes. El placer de los labios favorece la instrucción.
22 Òye jẹ́ orísun ìyè fún àwọn tí ó ní i, ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.
La comprensión es una fuente de vida para quien la tiene, pero el castigo de los tontos es su locura.
23 Ọkàn ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀ ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ dàgbà.
El corazón del sabio instruye a su boca, y añade el aprendizaje a sus labios.
24 Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.
Las palabras agradables son un panal, dulce para el alma, y salud para los huesos.
25 Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.
Hay un camino que le parece correcto al hombre, pero al final lleva a la muerte.
26 Ọkàn alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún ara rẹ̀; nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ lọ.
El apetito del trabajador trabaja para él, porque su boca le urge.
27 Ènìyàn búburú ń pète ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.
Un hombre sin valor trama una travesura. Su discurso es como un fuego abrasador.
28 Aláyídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀ olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn ní yà.
El hombre perverso suscita conflictos. Un susurrador separa a los amigos cercanos.
29 Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀ ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.
El hombre violento seduce a su prójimo, y lo lleva por un camino que no es bueno.
30 Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte; ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.
El que guiña los ojos para tramar perversidades, el que comprime sus labios, está empeñado en el mal.
31 Adé ògo ni ewú orí jẹ́, ìgbé ayé òdodo ní í mú ni dé bẹ̀.
Las canas son una corona de gloria. Se consigue con una vida de rectitud.
32 Ó sàn láti jẹ́ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ, ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun ṣẹ́gun ìlú lọ.
El que es lento para la ira es mejor que el poderoso; el que gobierna su espíritu, que el que toma una ciudad.
33 A ṣẹ́ kèké si ìṣẹ́po aṣọ, ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
La suerte está echada, pero todas sus decisiones provienen de Yahvé.