< Proverbs 16 >

1 Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.
W człowieku są zamysły serca, ale odpowiedź języka jest od PANA.
2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.
Wszystkie drogi człowieka są czyste w jego oczach, ale PAN waży duchy.
3 Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé Olúwa lọ́wọ́, èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.
Powierz PANU swe dzieła, a twoje zamysły będą utwierdzone.
4 Olúwa ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́ kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.
PAN uczynił wszystko dla samego siebie, nawet niegodziwego na dzień zła.
5 Olúwa kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀ mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.
Każdy, który jest wyniosłego serca, budzi odrazę w PANU; choć weźmie innych do pomocy, nie uniknie kary.
6 Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀ nípasẹ̀ ìbẹ̀rù Olúwa ènìyàn sá fún ibi.
Dzięki miłosierdziu i prawdzie oczyszcza się nieprawość, a w bojaźni PANA oddalamy się od zła.
7 Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ Olúwa lọ́rùn, yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.
Gdy drogi człowieka podobają się PANU, to godzi z nim nawet jego nieprzyjaciół.
8 Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ.
Lepiej mieć mało ze sprawiedliwością niż wiele dochodów nieprawnych.
9 Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.
Serce człowieka obmyśla swe drogi, ale PAN kieruje jego krokami.
10 Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké.
Wyrok Boży [jest] na wargach króla; jego usta nie błądzą w sądzie.
11 Òdínwọ̀n àti òsùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.
Sprawiedliwa waga i szale [należą do] PANA i wszystkie odważniki w worku są jego dziełem.
12 Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́ nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.
Popełnienie niegodziwości budzi odrazę w królach, bo sprawiedliwością tron jest umocniony.
13 Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́, wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́.
Wargi sprawiedliwe są rozkoszą królów, kochają oni tego, który mówi to, co słuszne.
14 Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́ ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.
Gniew króla jest posłańcem śmierci, ale mądry człowiek przebłaga go.
15 Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè; ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.
W jasności twarzy króla [jest] życie, a jego przychylność jest jak obłok z późnym deszczem.
16 Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ àti láti yan òye dípò o fàdákà!
O wiele lepiej jest nabyć mądrość niż złoto; a nabyć rozum lepiej niż srebro.
17 Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi, ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.
Droga prawych [to] odstąpić od zła; kto strzeże swojej drogi, strzeże swej duszy.
18 Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun, agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú.
Pycha poprzedza zgubę, a wyniosły duch – upadek.
19 Ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrín àwọn olùpọ́njú jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.
Lepiej być uniżonego ducha z pokornymi, niż dzielić łup z pysznymi.
20 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ìre, ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
Kto zważa na słowo, znajdzie dobro, a kto ufa PANU, [jest] błogosławiony.
21 Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.
Kto [jest] mądrego serca, zwie się rozumnym, a słodycz warg pomnaża wiedzę.
22 Òye jẹ́ orísun ìyè fún àwọn tí ó ní i, ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.
Rozum [jest] zdrojem życia dla tych, którzy go mają, a pouczenie głupich jest głupotą.
23 Ọkàn ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀ ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ dàgbà.
Serce mądrego czyni jego usta roztropnymi i dodaje nauki jego wargom.
24 Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.
Miłe słowa są [jak] plaster miodu, słodycz dla duszy i lekarstwo dla kości.
25 Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.
Jest droga, która [wydaje się] człowiekowi słuszna, ale jej końcem jest droga do śmierci.
26 Ọkàn alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún ara rẹ̀; nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ lọ.
Robotnik pracuje dla siebie, bo usta pobudzają go [do tego].
27 Ènìyàn búburú ń pète ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.
Człowiek nikczemny wykopuje zło, a na jego wargach jakby ogień płonący.
28 Aláyídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀ olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn ní yà.
Człowiek przewrotny rozsiewa spory, a plotkarz rozdziela przyjaciół.
29 Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀ ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.
Człowiek gwałtowny zwabia swego bliźniego i wprowadza go na drogę niedobrą.
30 Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte; ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.
Mruga swymi oczami, by knuć podstępy; rusza wargami i popełnia zło.
31 Adé ògo ni ewú orí jẹ́, ìgbé ayé òdodo ní í mú ni dé bẹ̀.
Siwa głowa [jest] koroną chwały, zdobywa się ją na drodze sprawiedliwości.
32 Ó sàn láti jẹ́ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ, ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun ṣẹ́gun ìlú lọ.
Lepszy jest nieskory do gniewu niż mocarz, a kto panuje nad swym duchem, [jest lepszy] niż ten, kto zdobywa miasto.
33 A ṣẹ́ kèké si ìṣẹ́po aṣọ, ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
Losy wrzuca się w zanadrze, ale całe rozstrzygnięcie ich zależy od PANA.

< Proverbs 16 >