< Proverbs 16 >

1 Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.
Az embernél vannak az elme gondolatjai; de az Úrtól van a nyelv felelete.
2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.
Minden útai tiszták az embernek a maga szemei előtt; de a ki a lelkeket vizsgálja, az Úr az!
3 Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé Olúwa lọ́wọ́, èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.
Bízzad az Úrra a te dolgaidat; és a te gondolatid véghez mennek.
4 Olúwa ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́ kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.
Mindent teremtett az Úr az ő maga czéljára; az istentelent is a büntetésnek napjára.
5 Olúwa kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀ mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.
Útálatos az Úrnak minden, a ki elméjében felfuvalkodott, kezemet adom rá, hogy nem marad büntetetlen.
6 Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀ nípasẹ̀ ìbẹ̀rù Olúwa ènìyàn sá fún ibi.
Könyörületességgel és igazsággal töröltetik el a bűn; és az Úrnak félelme által távozhatunk el a gonosztól.
7 Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ Olúwa lọ́rùn, yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.
Mikor jóakarattal van az Úr valakinek útaihoz, még annak ellenségeit is jóakaróivá teszi.
8 Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ.
Jobb a kevés igazsággal, mint a gazdag jövedelem hamissággal.
9 Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.
Az embernek elméje gondolja meg az ő útát; de az Úr igazgatja annak járását.
10 Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké.
Jósige van a király ajkain; az ítéletben ne szóljon hamisságot az ő szája.
11 Òdínwọ̀n àti òsùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.
Az Úré az igaz mérték és mérőserpenyő, az ő műve minden mérőkő.
12 Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́ nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.
Útálatos legyen a királyoknál istentelenséget cselekedni; mert igazsággal erősíttetik meg a királyiszék.
13 Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́, wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́.
Kedvesek a királyoknak az igaz beszédek; és az igazmondót szereti a király.
14 Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́ ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.
A királynak felgerjedt haragja olyan, mint a halál követe; de a bölcs férfiú leszállítja azt.
15 Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè; ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.
A királynak vidám orczájában élet van; jóakaratja olyan, mint a tavaszi eső fellege.
16 Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ àti láti yan òye dípò o fàdákà!
Szerzeni bölcseséget, oh menynyivel jobb az aranynál; és szerzeni eszességet, kivánatosb az ezüstnél!
17 Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi, ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.
Az igazak országútja eltávozás a gonosztól; megtartja magát az, a ki megőrzi az ő útát.
18 Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun, agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú.
A megromlás előtt kevélység jár, és az eset előtt felfuvalkodottság.
19 Ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrín àwọn olùpọ́njú jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.
Jobb alázatos lélekkel lenni a szelídekkel, mint zsákmányon osztozni a kevélyekkel.
20 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ìre, ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
A ki figyelmez az igére, jót nyer; és a ki bízik az Úrban, oh mely boldog az!
21 Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.
A ki elméjében bölcs, hívatik értelmesnek; a beszédnek pedig édessége neveli a tudományt.
22 Òye jẹ́ orísun ìyè fún àwọn tí ó ní i, ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.
Életnek kútfeje az értelem annak, a ki bírja azt; de a bolondok fenyítéke bolondságuk.
23 Ọkàn ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀ ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ dàgbà.
A bölcsnek elméje értelmesen igazgatja az ő száját, és az ő ajkain öregbíti a tudományt.
24 Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.
Lépesméz a gyönyörűséges beszédek; édesek a léleknek, és meggyógyítói a tetemeknek.
25 Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.
Van oly út, mely igaz az ember szeme előtt, de vége a halálnak úta.
26 Ọkàn alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún ara rẹ̀; nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ lọ.
A munkálkodó lelke magának munkálkodik; mert az ő szája kényszeríti őt.
27 Ènìyàn búburú ń pète ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.
A haszontalan ember gonoszt ás ki, és az ő ajkain mintegy égő tűz van;
28 Aláyídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀ olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn ní yà.
A gonosz ember versengést szerez, és a susárló elválasztja a jó barátokat.
29 Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀ ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.
Az erőszakos ember elhiteti az ő felebarátját, és nem jó úton viszi őt.
30 Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte; ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.
A ki behúnyja szemeit, azért teszi, hogy álnokságot gondoljon; a ki összeszorítja ajkait, már véghez vitte a gonoszságot.
31 Adé ògo ni ewú orí jẹ́, ìgbé ayé òdodo ní í mú ni dé bẹ̀.
Igen szép ékes korona a vénség, az igazságnak útában találtatik.
32 Ó sàn láti jẹ́ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ, ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun ṣẹ́gun ìlú lọ.
Jobb a hosszútűrő az erősnél; és a ki uralkodik a maga indulatján, annál, a ki várost vesz meg.
33 A ṣẹ́ kèké si ìṣẹ́po aṣọ, ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
Az ember kebelében vetnek sorsot; de az Úrtól van annak minden ítélete.

< Proverbs 16 >