< Proverbs 16 >

1 Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.
Mĩbango ya ngoro nĩ ya mũndũ, no icookio rĩa rũrĩmĩ riumaga harĩ Jehova.
2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.
Mũndũ onaga mĩthiĩre yake yothe ĩrĩ mĩega, no Jehova nĩwe ũthimaga matanya.
3 Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé Olúwa lọ́wọ́, èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.
Rekagĩrĩria Jehova maũndũ mothe marĩa ũrĩĩkaga, nayo mĩbango yaku nĩĩrĩgaacagĩra.
4 Olúwa ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́ kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.
Jehova ombire indo ciothe irĩ na gĩtũmi gĩacio, ĩĩ-ni, o na arĩa aaganu aamoombire nĩ ũndũ wa mũthenya wa thĩĩna.
5 Olúwa kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀ mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.
Mũndũ wothe wa ngoro ya mwĩtĩĩo nĩ kĩndũ kĩrĩ magigi harĩ Jehova. Menyai na ma atĩrĩ, ndakaaga kũherithio.
6 Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀ nípasẹ̀ ìbẹ̀rù Olúwa ènìyàn sá fún ibi.
Mehia nĩmahorohagĩrio nĩ wendo na wĩhokeku, na nĩ ũndũ wa gwĩtigĩra Jehova-rĩ, mũndũ nĩeheragĩra ũũru.
7 Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ Olúwa lọ́rùn, yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.
Rĩrĩa mĩthiĩre ya mũndũ yakenia Jehova-rĩ, atũmaga o na thũ ciake itũũranie nake na thayũ.
8 Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ.
Kaba indo nini cionekete na njĩra ya ũthingu, gũkĩra uumithio mũnene ũtarĩ wa kĩhooto.
9 Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.
Mũndũ nĩabangaga na ngoro mũthiĩre wake, no Jehova nĩwe ũroragia makinya make kũrĩa ekũgerera.
10 Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké.
Mĩromo ya mũthamaki yaragia ũhoro taarĩ ndũmĩrĩri, na kanua gake gatiagĩrĩirwo kuogomia kĩhooto.
11 Òdínwọ̀n àti òsùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.
Igeri na ratiri cia ma nĩ cia Jehova; mahiga mothe ma gũthima marĩa marĩ mũhuko-rĩ, o namo no wĩra wake.
12 Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́ nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.
Kũrĩ athamaki-rĩ, gwĩka ũũru nĩ ũndũ ũrĩ magigi, nĩgũkorwo gĩtĩ kĩa ũnene kĩĩhaandaga nĩ ũndũ wa ũthingu.
13 Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́, wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́.
Athamaki nĩmakenagĩra mĩromo ĩrĩa yaragia ma; nĩ marĩ bata na mũndũ waragia ũhoro wa ma.
14 Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́ ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.
Mangʼũrĩ ma mũthamaki nĩ ta mũtũmwo wa gĩkuũ, no mũndũ mũũgĩ nĩakamahooreria.
15 Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè; ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.
Gũthererwo gĩthiithi nĩ mũthamaki nĩ muoyo; ũtugi wake ũtariĩ ta itu rĩa mbura ĩrĩa ĩkũragia irio.
16 Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ àti láti yan òye dípò o fàdákà!
Hĩ! Kaĩ kũgĩa ũũgĩ nĩ kwega gũkĩra thahabu-ĩ, gũthuura ũtaũku gũgakĩra kũgĩa na betha!
17 Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi, ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.
Njĩra njariĩ ya arĩa arũngĩrĩru yeheragĩra ũũru; mũndũ ũrĩa ũmenyagĩrĩra mĩthiĩre yake nĩ muoyo wake mwene agitagĩra.
18 Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun, agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú.
Mwĩtĩĩo ũrũmagĩrĩrwo nĩ mwanangĩko, roho wa mwĩtũũgĩrio ũkarũmĩrĩrwo nĩ kũgũa.
19 Ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrín àwọn olùpọ́njú jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.
Nĩ kaba roho wa kwĩnyiihia na gũkorwo hamwe na arĩa ahinyĩrĩrie, gũkĩra kũgayana indo cia ndaho na arĩa etĩĩi.
20 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ìre, ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
Mũndũ ũrĩa ũrũmbũyagia mataaro nĩagaacagĩra, na kũrathimwo nĩ mũndũ ũrĩa wĩhokaga Jehova.
21 Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.
Arĩa oogĩ ngoro-inĩ metagwo akũũrani maũndũ, na ciugo njega itũũgagĩria ũtaaro.
22 Òye jẹ́ orísun ìyè fún àwọn tí ó ní i, ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.
Ũtaũku nĩ gĩthima kĩa muoyo kũrĩ arĩa marĩ naguo, no ũrimũ ũrehaga iherithia kũrĩ andũ arĩa akĩĩgu.
23 Ọkàn ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀ ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ dàgbà.
Ngoro ya mũndũ mũũgĩ nĩyo ĩtongoragia kanua gake, nayo mĩromo yake ĩtũũgagĩria ũtaaro.
24 Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.
Ndeto njega nĩ igua rĩa ũũkĩ, irĩ mũrĩo ngoro-inĩ, na harĩ mahĩndĩ nĩ ũgima.
25 Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.
Kũrĩ njĩra mũndũ onaga ta yagĩrĩire, no marigĩrĩrio mayo yerekagĩra gĩkuũ-inĩ.
26 Ọkàn alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún ara rẹ̀; nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ lọ.
Kũhũũta kwa mũruti wa wĩra nĩkuo kũmũteithagia, ngʼaragu yake nĩyo ĩmũtindĩkaga.
27 Ènìyàn búburú ń pète ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.
Kĩmaramari gĩthugundaga ũũru, na mĩario yakĩo nĩ ta mwaki wa gũcina.
28 Aláyídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀ olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn ní yà.
Mũndũ mwaganu arehaga ngarari, na mũhuhu ũtigithanagia andũ marĩ ũrata mũnene.
29 Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀ ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.
Mũndũ wa haaro aheenagĩrĩria mũndũ wa itũũra rĩake, akamũtongoria njĩra-inĩ ĩtarĩ njega.
30 Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte; ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.
Mũndũ ũrĩa uunagĩra andũ riitho akoragwo agĩthugunda waganu, ũrĩa ũtembanagia mĩromo akoragwo agĩthugunda ũũru.
31 Adé ògo ni ewú orí jẹ́, ìgbé ayé òdodo ní í mú ni dé bẹ̀.
Mbuĩ nĩ thũmbĩ ya riiri; cionekaga nĩ ũndũ wa mũtũũrĩre wa ũthingu.
32 Ó sàn láti jẹ́ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ, ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun ṣẹ́gun ìlú lọ.
Nĩ kaba mũndũ mũkirĩrĩria gũkĩra njamba ya ita, na nĩ kaba mũndũ ũrĩa ũrigagĩrĩria marakara make gũkĩra ũrĩa wĩnyiitagĩra itũũra inene.
33 A ṣẹ́ kèké si ìṣẹ́po aṣọ, ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
Mĩtĩ ĩcuukagĩrwo maru-inĩ, no itua o rĩothe riumaga kũrĩ Jehova.

< Proverbs 16 >