< Proverbs 16 >
1 Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.
A l'homme de former des plans en son cœur; mais à Dieu d'exaucer ce qu'exprime la langue.
2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.
Toutes les voies d'un homme sont pures à ses yeux; mais l'Éternel pèse les cœurs.
3 Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé Olúwa lọ́wọ́, èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.
Repose-toi sur Dieu de tes affaires, et tes plans seront assurés.
4 Olúwa ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́ kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.
L'Éternel a fait toutes choses pour leur fin; ainsi, l'impie pour le jour du malheur.
5 Olúwa kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀ mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.
Tout orgueilleux est pour l'Éternel une abomination; en aucun temps il ne demeure impuni.
6 Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀ nípasẹ̀ ìbẹ̀rù Olúwa ènìyàn sá fún ibi.
L'amour et la fidélité expient la faute, et la crainte de l'Éternel fait fuir le mal.
7 Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ Olúwa lọ́rùn, yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.
Si l'Éternel est favorable à la voie d'un homme, Il réconcilie même ses ennemis avec lui.
8 Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ.
Mieux vaut peu avec la justice, qu'un gros revenu avec l'iniquité.
9 Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.
L'homme en son cœur se trace sa voie; c'est l'Éternel qui dirige sa marche.
10 Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké.
Les lèvres du roi prononcent des oracles; et, quand il juge, sa bouche n'est point inique.
11 Òdínwọ̀n àti òsùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.
Le poids et la balance justes viennent de l'Éternel; Il a fait toutes les pierres qu'on a dans sa bourse.
12 Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́ nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.
Les rois auront horreur de faire le mal; car par la justice un trône est affermi.
13 Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́, wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́.
Les bonnes grâces du roi seront pour les lèvres vraies, et celui qui parle sincèrement, aura son amour.
14 Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́ ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.
Colère de roi, messages de mort: aussi le sage la calmera.
15 Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè; ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.
Un regard riant du roi donne la vie, et sa faveur est comme un nuage pluvieux du printemps.
16 Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ àti láti yan òye dípò o fàdákà!
Combien la possession de la sagesse vaut mieux que l'or! et que la possession de la sagesse est préférable à l'argent.
17 Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi, ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.
La voie des gens de bien, c'est de fuir le mal; il préserve sa vie celui qui surveille ses voies.
18 Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun, agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú.
L'orgueil précède la ruine, et la présomption, la chute.
19 Ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrín àwọn olùpọ́njú jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.
Mieux vaut vivre humble avec les pauvres, que de partager le butin avec les superbes.
20 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ìre, ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
Qui dans les affaires agit sensément, trouve le bonheur; et heureux qui se confie dans l'Éternel!
21 Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.
L'homme au cœur sage est appelé sensé, et l'aménité des paroles avance l'instruction.
22 Òye jẹ́ orísun ìyè fún àwọn tí ó ní i, ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.
La prudence pour qui l'a est une source de vie; les insensés sont punis par leur propre folie.
23 Ọkàn ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀ ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ dàgbà.
Le cœur du sage rend sa bouche sensée, et par ses discours avance l'instruction.
24 Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.
Les discours gracieux sont des rayons de miel, doux au cœur, restaurants pour le corps.
25 Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.
Telle voie semble droite à l'homme; mais elle aboutit au chemin de la mort.
26 Ọkàn alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún ara rẹ̀; nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ lọ.
La faim du travailleur travaille pour lui, car sa bouche lui en impose la charge.
27 Ènìyàn búburú ń pète ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.
L'homme dangereux prépare le malheur, et sur ses lèvres il y a comme un feu qui brûle.
28 Aláyídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀ olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn ní yà.
L'homme tortueux excite les divisions; et le rapporteur désunit les intimes.
29 Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀ ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.
L'homme qui veut nuire, séduit son prochain, et l'engage dans une voie qui n'est pas la bonne;
30 Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte; ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.
il ferme les yeux pour méditer la fraude, il serre les lèvres… il a consommé le crime.
31 Adé ògo ni ewú orí jẹ́, ìgbé ayé òdodo ní í mú ni dé bẹ̀.
Les cheveux blancs sont une couronne d'honneur; c'est sur le chemin de la justice qu'on la trouve.
32 Ó sàn láti jẹ́ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ, ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun ṣẹ́gun ìlú lọ.
L'homme patient est supérieur au héros, et celui qui a l'empire de son âme, au preneur de villes.
33 A ṣẹ́ kèké si ìṣẹ́po aṣọ, ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
On jette le sort dans le pan de la robe; mais sa décision vient de l'Éternel.