< Proverbs 16 >
1 Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.
Les préparations du cœur sont à l'homme; mais le discours de la langue est de par l'Eternel.
2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.
Chacune des voies de l'homme lui semble pure; mais l'Eternel pèse les esprits.
3 Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé Olúwa lọ́wọ́, èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.
Remets tes affaires à l'Eternel, et tes pensées seront bien ordonnées.
4 Olúwa ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́ kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.
L'Eternel a fait tout pour soi-même; et même le méchant pour le jour de la calamité.
5 Olúwa kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀ mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.
L'Eternel a en abomination tout homme hautain de cœur; de main en main il ne demeurera point impuni.
6 Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀ nípasẹ̀ ìbẹ̀rù Olúwa ènìyàn sá fún ibi.
Il y aura propitiation pour l'iniquité par la miséricorde et la vérité; et on se détourne du mal par la crainte de l'Eternel.
7 Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ Olúwa lọ́rùn, yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.
Quand l'Eternel prend plaisir aux voies de l'homme, il apaise envers lui ses ennemis mêmes.
8 Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ.
Il vaut mieux un peu de bien avec justice, qu'un gros revenu là où l'on n'a point de droit.
9 Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.
Le cœur de l'homme délibère de sa voie; mais l'Eternel conduit ses pas.
10 Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké.
Il y a divination aux lèvres du Roi, et sa bouche ne se fourvoiera point du droit.
11 Òdínwọ̀n àti òsùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.
La balance et le trébuchet justes sont de l'Eternel, et tous les poids du sachet sont son œuvre.
12 Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́ nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.
Ce doit être une abomination aux Rois de faire injustice, parce que le trône est établi par la justice.
13 Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́, wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́.
Les Rois [doivent prendre] plaisir aux lèvres de justice, et aimer celui qui profère des choses justes.
14 Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́ ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.
Ce sont autant de messagers de mort que la colère du Roi; mais l'homme sage l'apaisera.
15 Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè; ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.
C'est vie que le visage serein du Roi, et sa faveur est comme la nuée portant la pluie de la dernière saison.
16 Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ àti láti yan òye dípò o fàdákà!
Combien est-il plus précieux que le fin or, d'acquérir de la sagesse; et combien est-il plus excellent que l'argent, d'acquérir de la prudence?
17 Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi, ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.
Le chemin relevé des hommes droits, c'est de se détourner du mal; celui-là garde son âme qui prend garde à son train.
18 Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun, agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú.
L'orgueil va devant l'écrasement; et la fierté d'esprit devant la ruine.
19 Ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrín àwọn olùpọ́njú jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.
Mieux vaut être humilié d'esprit avec les débonnaires, que de partager le butin avec les orgueilleux.
20 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ìre, ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
Celui qui prend garde à la parole, trouvera le bien; et celui qui se confie en l'Eternel, est bienheureux.
21 Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.
On appellera prudent le sage de cœur; et la douceur des lèvres augmente la doctrine.
22 Òye jẹ́ orísun ìyè fún àwọn tí ó ní i, ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.
La prudence est à ceux qui la possèdent une source de vie; mais l'instruction des fous est une folie.
23 Ọkàn ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀ ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ dàgbà.
Le cœur sage conduit prudemment sa bouche, et ajoute doctrine sur ses lèvres.
24 Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.
Les paroles agréables sont des rayons de miel, douceur à l'âme, et santé aux os.
25 Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.
II y a telle voie qui semble droite à l'homme, mais dont la fin sont les voies de la mort.
26 Ọkàn alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún ara rẹ̀; nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ lọ.
L'âme de celui qui travaille, travaille pour lui-même, parce que sa bouche se courbe devant lui.
27 Ènìyàn búburú ń pète ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.
Le méchant creuse le mal, et il y a comme un feu brûlant sur ses lèvres.
28 Aláyídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀ olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn ní yà.
L'homme qui use de renversements, sème des querelles, et le rapporteur met le plus grand ami en division.
29 Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀ ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.
L'homme violent attire son compagnon, et le fait marcher par une voie qui n'est pas bonne.
30 Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte; ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.
Il fait signe des yeux pour machiner des renversements, et remuant ses lèvres il exécute le mal.
31 Adé ògo ni ewú orí jẹ́, ìgbé ayé òdodo ní í mú ni dé bẹ̀.
Les cheveux blancs sont une couronne d'honneur; et elle se trouvera dans la voie de la justice.
32 Ó sàn láti jẹ́ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ, ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun ṣẹ́gun ìlú lọ.
Celui qui est tardif à colère, vaut mieux que l'homme fort; et celui qui est le maître de son cœur, vaut mieux que celui qui prend des villes.
33 A ṣẹ́ kèké si ìṣẹ́po aṣọ, ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
On jette le sort au giron, mais tout ce qui en doit arriver, est de par l'Eternel.