< Proverbs 13 >

1 Ọlọ́gbọ́n ọmọ gba ẹ̀kọ́ baba rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹlẹ́gàn kò gbọ́ ìbáwí.
Mądry syn [przyjmuje] pouczenie ojca, a szyderca nie słucha strofowania.
2 Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ènìyàn ń gbádùn ohun rere, ṣùgbọ́n, ìfẹ́ ọkàn aláìṣòótọ́ ní ìwà ipá.
Człowiek będzie spożywać dobro z owocu swoich ust, a dusza przewrotnych [będzie spożywać] przemoc.
3 Ẹnikẹ́ni tí ó ṣọ́ ẹnu rẹ̀ pa ẹnu ara rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ gbàù gbàù yóò parun.
Kto strzeże swych ust, strzeże swojej duszy; kto [szeroko] otwiera swe wargi, będzie zniszczony.
4 Ọkàn ọ̀lẹ ń fẹ́, ṣùgbọ́n kò rí nǹkan kan, ṣùgbọ́n ọkàn àwọn ti kì í ṣe ọ̀lẹ rí ìtẹ́lọ́rùn.
Dusza leniwego pragnie, a nic nie ma, a dusza pracowitych zostanie obficie nasycona.
5 Olódodo kórìíra ohun tí í ṣe irọ́, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú hu ìwà ìríra àti ìtìjú.
Sprawiedliwy nienawidzi kłamliwego słowa, a niegodziwy staje się obrzydliwy i zhańbiony.
6 Òdodo ń ṣamọ̀nà ènìyàn olóòtítọ́ inú, ṣùgbọ́n ìwà búburú ṣí ẹlẹ́ṣẹ̀ ní ipò.
Sprawiedliwość strzeże tego, który postępuje uczciwie, a niegodziwość powala grzesznika.
7 Ènìyàn kan díbọ́n bí ẹni tí ó ní ọrọ̀ síbẹ̀ kò ní nǹkan kan ẹlòmíràn díbọ́n bí i tálákà, síbẹ̀ ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
Znajduje się taki, który czyni siebie bogatym, a nie ma nic; inny czyni siebie ubogim, choć ma wiele bogactw.
8 Ọrọ̀ ènìyàn le è ra ẹ̀mí rẹ̀ ṣùgbọ́n tálákà kì í gbọ́ ìdẹ́rùbà.
Okupem za życie człowieka jest jego bogactwo, a ubogi nie słucha strofowania.
9 Ìmọ́lẹ̀ olódodo tàn roro, ṣùgbọ́n fìtílà ènìyàn búburú ni a pa kú.
Radośnie błyszczy światło sprawiedliwych, a pochodnia niegodziwych zgaśnie.
10 Ìgbéraga máa ń dá ìjà sílẹ̀ ni ṣùgbọ́n ọgbọ́n wà nínú àwọn tí ń gba ìmọ̀ràn.
Spór powstaje tylko dzięki pysze, a mądrość jest przy tych, co przyjmują radę.
11 Owó tí a fi ọ̀nà èrú kójọ yóò ṣí lọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ń kó owó jọ díẹ̀díẹ̀ yóò pọ̀ sí i.
Łatwo zdobyte bogactwo zmniejsza się, a kto je gromadzi [swą] ręką, pomnaża je.
12 Ìrètí tí ń falẹ̀ máa ń mú kí ọkàn ṣàárẹ̀ ṣùgbọ́n ìrètí tí a rí gbà jẹ́ igi ìyè.
Przedłużająca się nadzieja sprawia ból sercu, a spełnione pragnienie [jest] drzewem życia.
13 Ẹni tí ó kẹ́gàn ẹ̀kọ́ yóò jìyà rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa àṣẹ mọ́ gba èrè rẹ̀.
Kto gardzi słowem [Bożym], ten zginie, a kto się boi przykazania, dostanie nagrodę.
14 Ìkọ́ni ọlọ́gbọ́n jẹ́ orísun ìyè, tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìdẹ̀kùn ikú.
Prawo mądrego jest źródłem życia, by uniknąć sideł śmierci.
15 Òye pípé ń mú ni rí ojúrere, ṣùgbọ́n ọ̀nà aláìṣòótọ́ kì í tọ́jọ́.
Prawdziwy rozum daje łaskę, a droga przewrotnych jest ciężka.
16 Gbogbo olóye ènìyàn máa ń hùwà pẹ̀lú ìmọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n a fi ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ hàn.
Każdy roztropny postępuje rozważnie, a głupi ujawnia głupotę.
17 Ìránṣẹ́ búburú bọ́ sínú ìdààmú ṣùgbọ́n aṣojú olóòtítọ́ mú ìwòsàn wá.
Niegodziwy posłaniec popada w zło, a wierny wysłannik jest lekarstwem.
18 Ẹni tí ó kọ ìbáwí yóò di tálákà yóò sì rí ìtìjú, ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí ni yóò rí ọlá.
Ubóstwo i hańba [spadną na] tego, który odrzuca karność, a kto szanuje upomnienia, dozna czci.
19 Ìfẹ́ tí a mú ṣẹ dùn mọ́ ọkàn ṣùgbọ́n ìríra ni fún aṣiwèrè láti kúrò nínú ibi.
Spełnione pragnienie jest słodkie dla duszy, a odwrócenie się od zła budzi odrazę w głupcach.
20 Ẹni tí ó ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n ṣùgbọ́n ẹni tí ń bá aláìgbọ́n kẹ́gbẹ́ ń pa ara rẹ̀ lára.
Kto przestaje z mądrymi, będzie mądry, a towarzysz głupców będzie zniszczony.
21 Òsì a máa ta ẹlẹ́ṣẹ̀, ṣùgbọ́n ọrọ̀ ni èrè fún olódodo.
Nieszczęście ściga grzeszników, a sprawiedliwych [Bóg] nagrodzi dobrem.
22 Ènìyàn rere a máa fi ogún sílẹ̀ fún àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀, ṣùgbọ́n, a kó ọrọ̀ àwọn tó dẹ́ṣẹ̀ pamọ́ fún àwọn olódodo.
Dobry [człowiek] zostawia dziedzictwo dzieciom [swoich] dzieci, a majątek grzesznika jest zachowany dla sprawiedliwego.
23 Ilẹ̀ ẹ tálákà le è mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìre oko wá ṣùgbọ́n àìṣòdodo gbá gbogbo rẹ̀ lọ.
Obfita żywność jest na roli ubogich, lecz i ta może niszczeć przez nieroztropność.
24 Ẹni tí ó fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kórìíra ọmọ rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó fẹ́ràn ọmọ rẹ̀ yóò máa bá a wí.
Kto oszczędza swą rózgę, nienawidzi swego syna, a kto go kocha, karze w porę.
25 Olódodo jẹ́wọ́ títí ó fi tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ikùn ènìyàn búburú.
Sprawiedliwy je i syci swoją duszę, a żołądek niegodziwych cierpi niedostatek.

< Proverbs 13 >