< Proverbs 11 >

1 Olúwa kórìíra òsùwọ̀n èké, ṣùgbọ́n òsùwọ̀n òtítọ́ jẹ́ inú dídùn un rẹ̀.
Fałszywa waga budzi odrazę w PANU, ale podobają mu się uczciwe odważniki.
2 Nígbà tí ìgbéraga bá dé, nígbà náà ni ìdójútì dé, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrẹ̀lẹ̀ ni ọgbọ́n ń wá.
Za pychą przychodzi hańba, a u pokornych jest mądrość.
3 Òtítọ́ inú ẹni dídúró ṣinṣin ń ṣe amọ̀nà rẹ̀, ṣùgbọ́n aláìṣòótọ́ yóò parun nípasẹ̀ àìṣòótọ́ wọn.
Uczciwość prawych poprowadzi ich, lecz grzeszników zgubi ich przewrotność.
4 Ọ̀rọ̀ kò níláárí ní ọjọ́ ìbínú, ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
Bogactwa nie pomogą w dniu gniewu, ale sprawiedliwość ocala od śmierci.
5 Òdodo aláìlẹ́gàn ṣe ọ̀nà tààrà fún wọn, ṣùgbọ́n ìwà búburú ènìyàn búburú yóò fà á lulẹ̀.
Sprawiedliwość nienagannego toruje mu drogę, a niegodziwy upadnie przez swoją niegodziwość.
6 Òdodo ẹni ìdúró ṣinṣin gbà wọ́n là, ṣùgbọ́n ìdẹ̀kùn ètè búburú mú aláìṣòótọ́.
Sprawiedliwość prawych ocali ich, a przewrotni będą schwytani w swojej przewrotności.
7 Nígbà tí ènìyàn búburú bá kú, ìrètí rẹ̀ a parun; gbogbo ohun tó ń fojú ṣọ́nà fún nípa agbára rẹ̀ já ṣófo.
Gdy umiera niegodziwy, ginie [jego] nadzieja, a oczekiwanie niesprawiedliwych znika.
8 A gba olódodo kúrò lọ́wọ́ ibi dípò o rẹ̀, ibi wá sórí ènìyàn búburú.
Sprawiedliwy bywa wybawiony z ucisku, a na jego miejsce przychodzi niegodziwy.
9 Aláìmọ Ọlọ́run fi ẹnu rẹ̀ ba aládùúgbò rẹ̀ jẹ́, ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ìmọ̀ olódodo sá àsálà.
Obłudnik ustami niszczy swego bliźniego, a sprawiedliwi bywają wybawieni dzięki wiedzy.
10 Nígbà tí olódodo ń gbèrú, ìlú a yọ̀; nígbà tí ènìyàn búburú parun, ariwo ayọ̀ gba ìlú kan.
Gdy sprawiedliwym się powodzi, miasto się cieszy, a gdy giną niegodziwi, panuje radość.
11 Nípasẹ̀ ìbùkún, olódodo a gbé ìlú ga: ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ẹnu ènìyàn búburú, a pa ìlú run.
Dzięki błogosławieństwu prawych wznosi się miasto, a usta niegodziwych je burzą.
12 Ẹni tí kò gbọ́n fojú kékeré wo aládùúgbò rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó ní òye pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Nierozumny gardzi swym bliźnim, a człowiek roztropny milczy.
13 Olófòófó tú àṣírí ìkọ̀kọ̀ ṣùgbọ́n ẹni tó ṣe é gbẹ́kẹ̀lé a pa àṣírí mọ́.
Plotkarz wyjawia tajemnice, ale człowiek wiernego serca ukrywa [powierzoną] sprawę.
14 Nítorí àìní ìtọ́sọ́nà orílẹ̀-èdè ṣubú ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn ìṣẹ́gun dájú.
Gdzie nie ma dobrej rady, lud upada, a gdzie wielu radców, tam jest wybawienie.
15 Ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ fún àlejò yóò rí ìyọnu, ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kọ̀ láti ṣe onígbọ̀wọ́ yóò wà láìléwu.
Bardzo sobie szkodzi, kto ręczy za obcego, a kto nienawidzi poręki, jest bezpieczny.
16 Obìnrin oníwà rere gba ìyìn ṣùgbọ́n alágbára aláìbìkítà ènìyàn gba ọrọ̀ nìkan.
Miła kobieta dostępuje chwały, a mocarze zdobywają bogactwa.
17 Ènìyàn rere ń ṣe ara rẹ̀ lóore ṣùgbọ́n ènìyàn ìkà ń mú ìyọnu wá sórí ara rẹ̀.
Człowiek miłosierny czyni dobrze swej duszy, a okrutnik dręczy własne ciało.
18 Ènìyàn búburú gba èrè ìtànjẹ ṣùgbọ́n ẹni tó fúnrúgbìn òdodo yóò gba èrè tó dájú.
Niegodziwy czyni zwodnicze dzieło, a kto sieje sprawiedliwość, [ma] zapłatę pewną.
19 Olódodo tòótọ́ rí ìyè ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa ibi lé e sí ibi ikú ara rẹ̀.
Jak sprawiedliwość [prowadzi] do życia, tak do śmierci [zmierza] ten, kto naśladuje zło.
20 Olúwa kórìíra àwọn ènìyàn ọlọ́kàn búburú ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn tí ọ̀nà wọn kò lábùkù.
Ludzie przewrotnego serca budzą odrazę w PANU, a podobają mu się ci, których droga jest prawa.
21 Mọ èyí dájú pé, ènìyàn búburú kì yóò lọ láìjìyà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo yóò lọ láìjìyà.
Zły nie uniknie kary, choćby [innych] wezwał na pomoc, a potomstwo sprawiedliwych będzie ocalone.
22 Bí òrùka wúrà ní imú ẹlẹ́dẹ̀ ni arẹwà obìnrin tí kò lọ́gbọ́n.
[Czym] złoty kolczyk w ryju świni, [tym] piękna kobieta pozbawiona roztropności.
23 Ìfẹ́ inú olódodo yóò yọrí sí ohun rere ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú yóò yọrí sí ìbínú.
Pragnieniem sprawiedliwych jest tylko dobro, oczekiwaniem zaś niegodziwych – gniew.
24 Ènìyàn kan ń fún ni lọ́fẹ̀ẹ́, síbẹ̀ ó ń ní sí i; òmíràn ń háwọ́ ju bí ó ti yẹ ṣùgbọ́n ó di aláìní.
Jeden hojnie rozdaje, a jednak mu przybywa, [drugi] nad miarę skąpi, a ubożeje.
25 Ẹni tí ń ṣoore yóò máa gbèrú sí i; ẹni tí ó tu ẹlòmíràn lára yóò ní ìtura.
Człowiek szczodry będzie bogatszy, a kto [innych] syci, sam też będzie nasycony.
26 Àwọn ènìyàn a ṣẹ́ èpè lé ènìyàn tí ń kó oúnjẹ pamọ́ ṣùgbọ́n ìbùkún a máa wá sórí ẹni tí ó ṣetán láti tà.
Kto zatrzymuje zboże, tego lud przeklnie, a błogosławieństwo [będzie] nad głową tego, który je sprzedaje.
27 Ẹni tí ń lépa ohun rere yóò rí ohun rere ṣùgbọ́n ibi yóò dé bá ẹni tí ń lépa ibi.
Kto pilnie szuka dobrego, zdobędzie przychylność, lecz kto szuka zła, przyjdzie ono na niego.
28 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ yóò ṣubú; ṣùgbọ́n olódodo yóò gbilẹ̀ bí i koríko tútù.
Kto ufność pokłada w swych bogactwach, ten upadnie, a sprawiedliwi będą zielenić się jak latorośl.
29 Ẹni tí ó ń mú ìdààmú dé bá ìdílé rẹ̀ yóò jogún afẹ́fẹ́ lásán aláìgbọ́n yóò sì máa ṣe ìránṣẹ́ fún ọlọ́gbọ́n.
Kto niepokoi swój dom, odziedziczy wiatr, a głupi będzie sługą mądrego.
30 Èso òdodo ni igi ìyè ẹni tí ó sì jèrè ọkàn jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
Owoc sprawiedliwego [jest] drzewem życia; a kto zyskuje dusze, jest mądry.
31 Bí àwọn olódodo bá gba ìpín wọn lórí ilẹ̀ ayé mélòó mélòó ni ènìyàn búburú àti àwọn tó dẹ́ṣẹ̀!
[Jeśli] sprawiedliwy otrzyma zapłatę na ziemi, to tym bardziej niegodziwy i grzesznik.

< Proverbs 11 >