< Proverbs 11 >
1 Olúwa kórìíra òsùwọ̀n èké, ṣùgbọ́n òsùwọ̀n òtítọ́ jẹ́ inú dídùn un rẹ̀.
Неточни везни са мерзост Господу; А точни грамове са угодни Нему.
2 Nígbà tí ìgbéraga bá dé, nígbà náà ni ìdójútì dé, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrẹ̀lẹ̀ ni ọgbọ́n ń wá.
Дойде ли гордост, дохожда и срам. А мъдростта е със смирените.
3 Òtítọ́ inú ẹni dídúró ṣinṣin ń ṣe amọ̀nà rẹ̀, ṣùgbọ́n aláìṣòótọ́ yóò parun nípasẹ̀ àìṣòótọ́ wọn.
Незлобието на справедливите ще ги ръководи, А извратеността на коварните ще ги погуби.
4 Ọ̀rọ̀ kò níláárí ní ọjọ́ ìbínú, ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
В ден на гняв богатството не ползува, А правдата избавя от смърт.
5 Òdodo aláìlẹ́gàn ṣe ọ̀nà tààrà fún wọn, ṣùgbọ́n ìwà búburú ènìyàn búburú yóò fà á lulẹ̀.
Правдата на непорочния ще оправя пътя му, А нечестивият ще падне чрез своето нечестие.
6 Òdodo ẹni ìdúró ṣinṣin gbà wọ́n là, ṣùgbọ́n ìdẹ̀kùn ètè búburú mú aláìṣòótọ́.
Правдата на справедливите ще ги избави, А коварните ще се хванат в злобата си.
7 Nígbà tí ènìyàn búburú bá kú, ìrètí rẹ̀ a parun; gbogbo ohun tó ń fojú ṣọ́nà fún nípa agbára rẹ̀ já ṣófo.
Като умира нечестивият, ожиданото от него загива; Така загива надеждата на насилниците.
8 A gba olódodo kúrò lọ́wọ́ ibi dípò o rẹ̀, ibi wá sórí ènìyàn búburú.
Праведният се отървава от беда, А вместо него изпада в нея нечестивият.
9 Aláìmọ Ọlọ́run fi ẹnu rẹ̀ ba aládùúgbò rẹ̀ jẹ́, ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ìmọ̀ olódodo sá àsálà.
Безбожният погубва ближния си с устата си. Но чрез знанието на праведните ще се избави.
10 Nígbà tí olódodo ń gbèrú, ìlú a yọ̀; nígbà tí ènìyàn búburú parun, ariwo ayọ̀ gba ìlú kan.
Когато благоденствуват праведните, градът се весели; И когато погиват нечестивите става тържество.
11 Nípasẹ̀ ìbùkún, olódodo a gbé ìlú ga: ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ẹnu ènìyàn búburú, a pa ìlú run.
Чрез благословението върху праведните градът се въздига, А чрез устата на нечестивите се съсипва.
12 Ẹni tí kò gbọ́n fojú kékeré wo aládùúgbò rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó ní òye pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Който презира ближния си е скудоумен; А благоразумният човек мълчи.
13 Olófòófó tú àṣírí ìkọ̀kọ̀ ṣùgbọ́n ẹni tó ṣe é gbẹ́kẹ̀lé a pa àṣírí mọ́.
Одумникът обхожда и открива тайните, А верният духом потайва работата.
14 Nítorí àìní ìtọ́sọ́nà orílẹ̀-èdè ṣubú ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn ìṣẹ́gun dájú.
Дето няма мъдро ръководене народът пропада, А в многото съветници има безопасност.
15 Ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ fún àlejò yóò rí ìyọnu, ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kọ̀ láti ṣe onígbọ̀wọ́ yóò wà láìléwu.
Който поръчителствува за чужд човек, зле ще пострада, А който мрази поръчителството е в безопасност.
16 Obìnrin oníwà rere gba ìyìn ṣùgbọ́n alágbára aláìbìkítà ènìyàn gba ọrọ̀ nìkan.
Благодатната жена придобива чест; И насилниците придобиват богатство.
17 Ènìyàn rere ń ṣe ara rẹ̀ lóore ṣùgbọ́n ènìyàn ìkà ń mú ìyọnu wá sórí ara rẹ̀.
Милостивият човек струва добро на себе си, А жестокият смущава своето тяло.
18 Ènìyàn búburú gba èrè ìtànjẹ ṣùgbọ́n ẹni tó fúnrúgbìn òdodo yóò gba èrè tó dájú.
Нечестивият придобива измамлива печалба, А който сее правда има сигурна награда.
19 Olódodo tòótọ́ rí ìyè ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa ibi lé e sí ibi ikú ara rẹ̀.
Който е утвърден в правдата, ще стане живот, А който се стреми към злото съдействува за своята смърт.
20 Olúwa kórìíra àwọn ènìyàn ọlọ́kàn búburú ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn tí ọ̀nà wọn kò lábùkù.
Развратените в сърце са мерзост Господу, А непорочните в пътя си са угодни Нему,
21 Mọ èyí dájú pé, ènìyàn búburú kì yóò lọ láìjìyà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo yóò lọ láìjìyà.
Даже ръка с ръка да се съедини пак нечестивият няма да остане ненаказан., А потомството на праведните ще се избави.
22 Bí òrùka wúrà ní imú ẹlẹ́dẹ̀ ni arẹwà obìnrin tí kò lọ́gbọ́n.
Както е златна халка на носа на свиня, Така е красивата, но безразсъдна жена.
23 Ìfẹ́ inú olódodo yóò yọrí sí ohun rere ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú yóò yọrí sí ìbínú.
Желаното от праведните е само добро, А ожиданото от нечестивите е надменност.
24 Ènìyàn kan ń fún ni lọ́fẹ̀ẹ́, síbẹ̀ ó ń ní sí i; òmíràn ń háwọ́ ju bí ó ti yẹ ṣùgbọ́n ó di aláìní.
Един разпръсва щедро, но пак има повече изобилие, А друг се скъпи без мяра, но пак стига до немотия,
25 Ẹni tí ń ṣoore yóò máa gbèrú sí i; ẹni tí ó tu ẹlòmíràn lára yóò ní ìtura.
Благотворната душа ще бъде наситена; И който пои, сам ще бъде напоен.
26 Àwọn ènìyàn a ṣẹ́ èpè lé ènìyàn tí ń kó oúnjẹ pamọ́ ṣùgbọ́n ìbùkún a máa wá sórí ẹni tí ó ṣetán láti tà.
Който задържа жито ще бъде прокълнат от народа, А който продава, благословение ще почива на главата му.
27 Ẹni tí ń lépa ohun rere yóò rí ohun rere ṣùgbọ́n ibi yóò dé bá ẹni tí ń lépa ibi.
Който усърдно търси доброто, търси и благоволение, А който търси злото, то ще дойде и върху него.
28 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ yóò ṣubú; ṣùgbọ́n olódodo yóò gbilẹ̀ bí i koríko tútù.
Който уповава на богатството си, ще падне, А праведните ще цъфтят като зелен лист.
29 Ẹni tí ó ń mú ìdààmú dé bá ìdílé rẹ̀ yóò jogún afẹ́fẹ́ lásán aláìgbọ́n yóò sì máa ṣe ìránṣẹ́ fún ọlọ́gbọ́n.
Който смущава своя си дом ще наследи вятър; И безумният ще стане слуга на мъдрия по сърце.
30 Èso òdodo ni igi ìyè ẹni tí ó sì jèrè ọkàn jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
Плодът на праведния е дърво на живот; И който е мъдър придобива души.
31 Bí àwọn olódodo bá gba ìpín wọn lórí ilẹ̀ ayé mélòó mélòó ni ènìyàn búburú àti àwọn tó dẹ́ṣẹ̀!
Ето, и на праведния се въздава на земята, - Колко повече на нечестивия и на грешния!