< Proverbs 10 >
1 Àwọn òwe Solomoni. Ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú baba rẹ̀ dùn, ṣùgbọ́n aṣiwèrè ọmọ ń ba inú ìyá rẹ̀ jẹ́.
Las sentencias de Salomón. EL hijo sabio alegra al padre; y el hijo necio es tristeza de su madre.
2 Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè, ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
Los tesoros de maldad no serán de provecho: mas la justicia libra de muerte.
3 Olúwa kì í jẹ́ kí ebi máa pa olódodo, ṣùgbọ́n ó ba ète àwọn ènìyàn búburú jẹ́.
Jehová no dejará hambrear el alma del justo: mas la iniquidad lanzará á los impíos.
4 Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di tálákà, ṣùgbọ́n ọwọ́ tí ó múra ṣíṣẹ́ a máa sọ ni di ọlọ́rọ̀.
La mano negligente hace pobre: mas la mano de los diligentes enriquece.
5 Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ ọlọ́gbọ́n ọmọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ó sùn ní àsìkò ìkórè jẹ́ adójútini ọmọ.
El que recoge en el estío es hombre entendido: el que duerme en el tiempo de la siega es hombre afrentoso.
6 Ìbùkún ní ó máa ń kún orí olódodo, ṣùgbọ́n ìwà ipá máa ń kún ẹnu ènìyàn búburú.
Bendiciones sobre la cabeza del justo: mas violencia cubrirá la boca de los impíos.
7 Ìrántí olódodo yóò jẹ́ ìbùkún, ṣùgbọ́n orúkọ ènìyàn búburú yóò jẹrà.
La memoria del justo será bendita: mas el nombre de los impíos se pudrirá.
8 Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ, ṣùgbọ́n ètè wérewère yóò parun.
El sabio de corazón recibirá los mandamientos: mas el loco de labios caerá.
9 Ẹni tí ó ń rìn déédé, ń rìn láìléwu, ṣùgbọ́n àṣírí ẹni tí ń rin ọ̀nà pálapàla yóò tú.
El que camina en integridad, anda confiado: mas el que pervierte sus caminos, será quebrantado.
10 Ẹni tí ń ṣẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn, aláìgbọ́n tí ń ṣàròyé kiri yóò parun.
El que guiña del ojo acarrea tristeza; y el loco de labios será castigado.
11 Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè, ṣùgbọ́n ìwà ipá ni ó gba gbogbo ẹnu ènìyàn búburú.
Vena de vida es la boca del justo: mas violencia cubrirá la boca de los impíos.
12 Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ìfẹ́ a máa bo gbogbo àṣìṣe mọ́lẹ̀.
El odio despierta rencillas: mas la caridad cubrirá todas las faltas.
13 Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye, ṣùgbọ́n kùmọ̀ wà fún ẹ̀yìn àwọn aláìlóye.
En los labios del prudente se halla sabiduría: y vara á las espaldas del falto de cordura.
14 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n a máa ṣokùnfà ìparun.
Los sabios guardan la sabiduría: mas la boca del loco es calamidad cercana.
15 Ọrọ̀ àwọn olódodo ni ìlú olódi wọn, ṣùgbọ́n òsì ni ìparun aláìní.
Las riquezas del rico son su ciudad fuerte; y el desmayo de los pobres es su pobreza.
16 Èrè olódodo ń mú ìyè wá fún wọn, ṣùgbọ́n èrè ènìyàn búburú ń mú ìjìyà wá fún wọn.
La obra del justo [es] para vida; mas el fruto del impío [es] para pecado.
17 Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn, ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ ìbáwí mú àwọn mìíràn ṣìnà.
Camino á la vida es guardar la corrección: mas el que deja la reprensión, yerra.
18 Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́ ẹni tí ó sì ń ba ni jẹ́ jẹ́ aláìgbọ́n.
El que encubre el odio es de labios mentirosos; y el que echa mala fama es necio.
19 Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
En las muchas palabras no falta pecado: mas el que refrena sus labios es prudente.
20 Ètè olódodo jẹ́ ààyò fàdákà, ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú kò níye lórí.
Plata escogida es la lengua del justo: mas el entendimiento de los impíos es como nada.
21 Ètè olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.
Los labios del justo apacientan á muchos: mas los necios por falta de entendimiento mueren.
22 Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá, kì í sì í fi ìdààmú sí i.
La bendición de Jehová es la que enriquece, y no añade tristeza con ella.
23 Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú, ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.
Hacer abominación es como risa al insensato: mas el hombre entendido sabe.
24 Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a; olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.
Lo que el impío teme, eso le vendrá: mas á los justos les será dado lo que desean.
25 Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ, ṣùgbọ́n olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.
Como pasa el torbellino, así el malo no permanece: mas el justo, fundado para siempre.
26 Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.
Como el vinagre á los dientes, y como el humo á los ojos, así es el perezoso á los que lo envían.
27 Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá, ṣùgbọ́n a gé ọjọ́ ayé ènìyàn búburú kúrú.
El temor de Jehová aumentará los días: mas los años de los impíos serán acortados.
28 Ìrètí olódodo ni ayọ̀, ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú jásí òfo.
La esperanza de los justos [es] alegría; mas la esperanza de los impíos perecerá.
29 Ọ̀nà Olúwa jẹ́ ààbò fún olódodo, ṣùgbọ́n ìparun ni ó jẹ́ fún àwọn tí ń ṣe ibi.
Fortaleza es al perfecto el camino de Jehová: mas espanto es á los que obran maldad.
30 A kì yóò fa olódodo tu láéláé, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kì yóò dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
El justo eternalmente no será removido: mas los impíos no habitarán la tierra.
31 Ẹnu olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá, ṣùgbọ́n ètè àyípadà ni a ó gé kúrò.
La boca del justo producirá sabiduría: mas la lengua perversa será cortada.
32 Ètè olódodo mọ ohun ìtẹ́wọ́gbà, ṣùgbọ́n ètè ènìyàn búburú kò mọ̀ ju èké lọ.
Los labios del justo conocerán lo que agrada: mas la boca de los impíos [habla] perversidades.