< Proverbs 10 >

1 Àwọn òwe Solomoni. Ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú baba rẹ̀ dùn, ṣùgbọ́n aṣiwèrè ọmọ ń ba inú ìyá rẹ̀ jẹ́.
Os provérbios de Salomão. Um filho sábio faz um pai feliz; mas um filho tolo traz tristeza para sua mãe.
2 Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè, ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
Os tesouros da maldade não lucram nada, mas a retidão se livra da morte.
3 Olúwa kì í jẹ́ kí ebi máa pa olódodo, ṣùgbọ́n ó ba ète àwọn ènìyàn búburú jẹ́.
Yahweh não vai permitir que a alma dos justos passe fome, mas ele afasta o desejo dos ímpios.
4 Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di tálákà, ṣùgbọ́n ọwọ́ tí ó múra ṣíṣẹ́ a máa sọ ni di ọlọ́rọ̀.
Ele se torna pobre que trabalha com a mão preguiçosa, mas a mão do diligente traz riqueza.
5 Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ ọlọ́gbọ́n ọmọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ó sùn ní àsìkò ìkórè jẹ́ adójútini ọmọ.
Aquele que se reúne no verão é um filho sábio, mas aquele que dorme durante a colheita é um filho que causa vergonha.
6 Ìbùkún ní ó máa ń kún orí olódodo, ṣùgbọ́n ìwà ipá máa ń kún ẹnu ènìyàn búburú.
As bênçãos estão na cabeça dos justos, mas a violência cobre a boca dos malvados.
7 Ìrántí olódodo yóò jẹ́ ìbùkún, ṣùgbọ́n orúkọ ènìyàn búburú yóò jẹrà.
A memória dos justos é abençoada, mas o nome dos ímpios apodrecerá.
8 Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ, ṣùgbọ́n ètè wérewère yóò parun.
Os sábios de coração aceitam os mandamentos, mas um tolo falador vai cair.
9 Ẹni tí ó ń rìn déédé, ń rìn láìléwu, ṣùgbọ́n àṣírí ẹni tí ń rin ọ̀nà pálapàla yóò tú.
Aquele que caminha sem culpa, certamente caminha, mas aquele que perverte seus caminhos será descoberto.
10 Ẹni tí ń ṣẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn, aláìgbọ́n tí ń ṣàròyé kiri yóò parun.
One que pisca com o olho causa tristeza, mas um tolo falador vai cair.
11 Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè, ṣùgbọ́n ìwà ipá ni ó gba gbogbo ẹnu ènìyàn búburú.
A boca dos justos é uma fonte de vida, mas a violência cobre a boca dos malvados.
12 Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ìfẹ́ a máa bo gbogbo àṣìṣe mọ́lẹ̀.
O ódio agita a luta, mas o amor cobre todos os males.
13 Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye, ṣùgbọ́n kùmọ̀ wà fún ẹ̀yìn àwọn aláìlóye.
A sabedoria é encontrada nos lábios daquele que tem discernimento, mas uma vara é para a parte de trás daquele que não tem entendimento.
14 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n a máa ṣokùnfà ìparun.
Os sábios colocam o conhecimento, mas a boca do tolo está perto da ruína.
15 Ọrọ̀ àwọn olódodo ni ìlú olódi wọn, ṣùgbọ́n òsì ni ìparun aláìní.
A riqueza do homem rico é sua cidade forte. A destruição dos pobres é sua pobreza.
16 Èrè olódodo ń mú ìyè wá fún wọn, ṣùgbọ́n èrè ènìyàn búburú ń mú ìjìyà wá fún wọn.
O trabalho dos justos leva à vida. O aumento dos ímpios leva ao pecado.
17 Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn, ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ ìbáwí mú àwọn mìíràn ṣìnà.
He está no caminho da vida quem presta atenção à correção, mas aquele que abandona a repreensão, desvia os outros.
18 Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́ ẹni tí ó sì ń ba ni jẹ́ jẹ́ aláìgbọ́n.
Aquele que esconde o ódio tem lábios mentirosos. Aquele que profere uma calúnia é um tolo.
19 Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
Na multidão de palavras não falta desobediência, mas aquele que refreia seus lábios faz sabiamente.
20 Ètè olódodo jẹ́ ààyò fàdákà, ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú kò níye lórí.
A língua dos justos é como a prata escolhida. O coração dos ímpios tem pouco valor.
21 Ètè olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.
Os lábios dos justos alimentam muitos, mas os tolos morrem por falta de compreensão.
22 Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá, kì í sì í fi ìdààmú sí i.
A bênção de Yahweh traz riqueza, e ele não lhe acrescenta nenhum problema.
23 Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú, ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.
É um prazer tolo fazer a maldade, mas a sabedoria é o prazer de um homem de entendimento.
24 Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a; olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.
O que o medo maligno os ultrapassará, mas o desejo dos justos será concedido.
25 Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ, ṣùgbọ́n olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.
Quando o redemoinho passa, o mal já não é mais; mas os justos permanecem firmes para sempre.
26 Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.
Como vinagre até os dentes e como fumaça até os olhos, Assim é o preguiçoso para aqueles que o enviam.
27 Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá, ṣùgbọ́n a gé ọjọ́ ayé ènìyàn búburú kúrú.
O medo de Yahweh prolonga os dias, mas os anos dos ímpios devem ser encurtados.
28 Ìrètí olódodo ni ayọ̀, ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú jásí òfo.
A perspectiva dos justos é a alegria, mas a esperança dos ímpios perecerá.
29 Ọ̀nà Olúwa jẹ́ ààbò fún olódodo, ṣùgbọ́n ìparun ni ó jẹ́ fún àwọn tí ń ṣe ibi.
O caminho de Yahweh é um refúgio para os verticais, mas é uma destruição para os trabalhadores da iniqüidade.
30 A kì yóò fa olódodo tu láéláé, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kì yóò dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
Os justos nunca serão removidos, mas os ímpios não vão habitar na terra.
31 Ẹnu olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá, ṣùgbọ́n ètè àyípadà ni a ó gé kúrò.
A boca dos justos produz sabedoria, mas a língua perversa será cortada.
32 Ètè olódodo mọ ohun ìtẹ́wọ́gbà, ṣùgbọ́n ètè ènìyàn búburú kò mọ̀ ju èké lọ.
Os lábios dos justos sabem o que é aceitável, mas a boca dos malvados é perversa.

< Proverbs 10 >