< Proverbs 10 >

1 Àwọn òwe Solomoni. Ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú baba rẹ̀ dùn, ṣùgbọ́n aṣiwèrè ọmọ ń ba inú ìyá rẹ̀ jẹ́.
Przysłowia Salomona. Mądry syn sprawia ojcu radość, a głupi syn [jest] zgryzotą swojej matki.
2 Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè, ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
Skarby niegodziwości nie przynoszą pożytku, lecz sprawiedliwość uwalnia od śmierci.
3 Olúwa kì í jẹ́ kí ebi máa pa olódodo, ṣùgbọ́n ó ba ète àwọn ènìyàn búburú jẹ́.
PAN nie pozwoli, by dusza sprawiedliwego cierpiała głód, a rozproszy majątek niegodziwych.
4 Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di tálákà, ṣùgbọ́n ọwọ́ tí ó múra ṣíṣẹ́ a máa sọ ni di ọlọ́rọ̀.
Leniwa ręka prowadzi do nędzy, a ręka pracowita ubogaca.
5 Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ ọlọ́gbọ́n ọmọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ó sùn ní àsìkò ìkórè jẹ́ adójútini ọmọ.
Kto zbiera w lecie, jest synem roztropnym; syn, który śpi w czasie żniwa, przynosi hańbę.
6 Ìbùkún ní ó máa ń kún orí olódodo, ṣùgbọ́n ìwà ipá máa ń kún ẹnu ènìyàn búburú.
Błogosławieństwa [są] na głowie sprawiedliwego, a usta niegodziwych kryją nieprawość.
7 Ìrántí olódodo yóò jẹ́ ìbùkún, ṣùgbọ́n orúkọ ènìyàn búburú yóò jẹrà.
Pamięć sprawiedliwego jest błogosławiona, a imię niegodziwych zgnije.
8 Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ, ṣùgbọ́n ètè wérewère yóò parun.
[Człowiek] mądrego serca przyjmuje przykazania, a gadatliwy głupiec upadnie.
9 Ẹni tí ó ń rìn déédé, ń rìn láìléwu, ṣùgbọ́n àṣírí ẹni tí ń rin ọ̀nà pálapàla yóò tú.
Kto postępuje uczciwie, postępuje bezpiecznie, a kto jest przewrotny w swoich drogach, zostanie ujawniony.
10 Ẹni tí ń ṣẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn, aláìgbọ́n tí ń ṣàròyé kiri yóò parun.
Kto mruga okiem, przynosi cierpienie, a gadatliwy głupiec upadnie.
11 Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè, ṣùgbọ́n ìwà ipá ni ó gba gbogbo ẹnu ènìyàn búburú.
Usta sprawiedliwego są źródłem życia, a usta niegodziwych kryją nieprawość.
12 Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ìfẹ́ a máa bo gbogbo àṣìṣe mọ́lẹ̀.
Nienawiść wznieca kłótnie, a miłość zakrywa wszystkie grzechy.
13 Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye, ṣùgbọ́n kùmọ̀ wà fún ẹ̀yìn àwọn aláìlóye.
Na wargach rozumnego znajduje się mądrość, a kij na grzbiecie nierozumnego.
14 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n a máa ṣokùnfà ìparun.
Mądrzy gromadzą wiedzę, a usta głupiego grożą zniszczeniem.
15 Ọrọ̀ àwọn olódodo ni ìlú olódi wọn, ṣùgbọ́n òsì ni ìparun aláìní.
Majątek bogacza [jest] jego warownym miastem, a zniszczeniem ubogich jest ich nędza.
16 Èrè olódodo ń mú ìyè wá fún wọn, ṣùgbọ́n èrè ènìyàn búburú ń mú ìjìyà wá fún wọn.
Praca sprawiedliwego [prowadzi] do życia, a dochód niegodziwych do grzechu.
17 Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn, ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ ìbáwí mú àwọn mìíràn ṣìnà.
Kto przestrzega karności, [idzie] ścieżką życia, a kto gardzi upomnieniem, błądzi.
18 Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́ ẹni tí ó sì ń ba ni jẹ́ jẹ́ aláìgbọ́n.
Kto kryje nienawiść kłamliwymi wargami i kto rozgłasza oszczerstwo, jest głupcem.
19 Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
Wielomówność nie bywa bez grzechu, a kto powściąga swoje wargi, jest roztropny.
20 Ètè olódodo jẹ́ ààyò fàdákà, ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú kò níye lórí.
Język sprawiedliwego jest wybornym srebrem, [a] serce niegodziwych jest mało warte.
21 Ètè olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.
Wargi sprawiedliwego żywią wielu, a głupi umierają przez brak rozumu.
22 Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá, kì í sì í fi ìdààmú sí i.
Błogosławieństwo PANA wzbogaca i nie przynosi z sobą zmartwień.
23 Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú, ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.
Dla głupiego popełnić haniebny czyn to zabawa, a człowiek roztropny [trzyma się] mądrości.
24 Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a; olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.
Niegodziwego spotka to, czego się boi, a sprawiedliwym [Bóg] daje to, czego pragną.
25 Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ, ṣùgbọ́n olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.
Jak wicher przemija, [tak] niegodziwy [nie przetrwa], a sprawiedliwy [ma] wieczny fundament.
26 Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.
Czym ocet dla zębów i dym dla oczu, tym [jest] leniwy dla tych, którzy go posyłają.
27 Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá, ṣùgbọ́n a gé ọjọ́ ayé ènìyàn búburú kúrú.
Bojaźń PANA przedłuża dni, a lata niegodziwego będą skrócone.
28 Ìrètí olódodo ni ayọ̀, ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú jásí òfo.
Oczekiwanie sprawiedliwych przynosi radość, a nadzieja niegodziwych zginie.
29 Ọ̀nà Olúwa jẹ́ ààbò fún olódodo, ṣùgbọ́n ìparun ni ó jẹ́ fún àwọn tí ń ṣe ibi.
Droga PANA jest mocą dla prawego, a zgubą dla czyniących nieprawość.
30 A kì yóò fa olódodo tu láéláé, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kì yóò dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
Sprawiedliwy nigdy się nie zachwieje, a niegodziwi nie będą mieszkać na ziemi.
31 Ẹnu olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá, ṣùgbọ́n ètè àyípadà ni a ó gé kúrò.
Usta sprawiedliwego wydają mądrość, a język przewrotny będzie wycięty.
32 Ètè olódodo mọ ohun ìtẹ́wọ́gbà, ṣùgbọ́n ètè ènìyàn búburú kò mọ̀ ju èké lọ.
Wargi sprawiedliwego wiedzą, co wypada, a usta niegodziwych są przewrotne.

< Proverbs 10 >