< Proverbs 1 >

1 Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.
Przysłowia Salomona, syna Dawida, króla Izraela;
2 Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́, láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.
Do poznania mądrości i karności, do zrozumienia słów roztropnych;
3 Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo, àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;
Do zdobycia pouczenia w mądrości, w sprawiedliwości, w sądzie i w prawości;
4 láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀, ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.
Do udzielenia prostym rozwagi, a młodemu – wiedzy i roztropności.
5 Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀, sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.
Mądry posłucha i przybędzie mu wiedzy, a rozumny nabędzie rad;
6 Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe, àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.
Aby rozumieć przysłowia i [ich] wykładnię, słowa mądrych i ich zagadki.
7 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.
Bojaźń PANA jest początkiem wiedzy, ale głupcy gardzą mądrością i karnością.
8 Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ, má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.
Synu mój, słuchaj pouczenia swego ojca i nie odrzucaj nauki swojej matki;
9 Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.
Bo one będą wdzięczną ozdobą na twojej głowie i [kosztownym] łańcuchem na szyi.
10 Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́, má ṣe gbà fún wọn.
Synu mój, jeśli grzesznicy cię namawiają, nie pozwalaj.
11 Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa; jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan, jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;
Jeśli mówią: Chodź z nami, czyhajmy na krew, zaczajmy się na niewinnego bez powodu;
12 jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú, àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò; (Sheol h7585)
Pożremy ich żywcem jak grób, całych, jak zstępujących do dołu; (Sheol h7585)
13 a ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa,
Znajdziemy wszelkie kosztowności, napełnimy swoje domy łupem;
14 da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa, a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà,”
Dziel z nami swój los; miejmy wszyscy jedną sakiewkę.
15 ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ, má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn.
Synu mój, nie wyruszaj z nimi w drogę; powstrzymaj swoją nogę od ich ścieżki.
16 Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀, wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.
Ich nogi bowiem biegną do zła i spieszą się do przelania krwi.
17 Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀, ní ojú ẹyẹ!
Na próżno zastawia się sieci na oczach wszelkiego ptactwa.
18 Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn. Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà.
Oni też czyhają na własną krew, czają się na własne życie.
19 Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́; yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.
Takie są ścieżki każdego, który jest chciwy zysku; swojemu właścicielowi [taki zysk] odbiera życie.
20 Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;
Mądrość woła na dworze, podnosi swój głos na ulicach.
21 láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:
Woła w największym zgiełku, u wrót bram, w mieście wygłasza swoje słowa:
22 “Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó? Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó? Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?
Jak długo, prości, będziecie kochać głupotę, szydercy – lubować się w swoim szyderstwie, a głupi – nienawidzić wiedzy?
23 Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni, ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.
Nawróćcie się na moje upomnienie; oto wyleję na was mojego ducha, oznajmię wam moje słowa.
24 Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,
Ponieważ wołałam, a odmawialiście; wyciągałam rękę, a nikt nie zważał;
25 níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi, tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,
Owszem, odrzuciliście całą moją radę i nie chcieliście [przyjąć] mojego upomnienia;
26 Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín; èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.
Dlatego będę się śmiać z waszego nieszczęścia, będę szydzić z was, gdy przyjdzie to, czego się boicie.
27 Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle, nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà, nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.
Gdy nadejdzie jak spustoszenie to, czego się boicie, i [gdy] wasze nieszczęście nadciągnie jak wicher, gdy nadejdzie na was ucisk i cierpienie;
28 “Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn; wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.
Wtedy będą mnie wzywać, a nie wysłucham; będą mnie szukać pilnie, lecz mnie nie znajdą.
29 Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀ tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.
Bo znienawidzili wiedzę i nie wybrali bojaźni PANA;
30 Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,
Ani nie chcieli mojej rady, [ale] gardzili każdym moim upomnieniem.
31 wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún.
Dlatego spożyją owoc swoich dróg i będą nasyceni swymi radami.
32 Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;
Bo odstępstwo prostych zabije ich i szczęście głupich zgubi ich.
33 ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”
[Ale] kto mnie słucha, będzie mieszkać bezpiecznie i będzie wolny od strachu przed złem.

< Proverbs 1 >