< Proverbs 1 >

1 Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.
Przypowieści Salomona, syna Dawidowego, króla Izraelskiego,
2 Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́, láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.
Dla poznania mądrości i ćwiczenia, ku wyrozumieniu powieści roztropnych;
3 Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo, àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;
Dla pojęcia ćwiczenia w rozumie, w sprawiedliwości, w sądzie i w prawości;
4 láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀, ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.
Dla podania prostakom ostrożności, młodemu umiejętności, i opatrzności.
5 Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀, sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.
Tych gdy mądry słuchać będzie, przybędzie mu nauki, a roztropny w radach opatrzniejszy będzie,
6 Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe, àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.
Aby zrozumiał przypowieści, i wykłady ich, słowa mądrych i zagadki ich.
7 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.
Bojaźń Pańska jest początkiem umiejętności; ale głupi mądrością i ćwiczeniem gardzą.
8 Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ, má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.
Słuchaj, synu mój! ćwiczenia ojca twego, a nie opuszczaj nauki matki twojej.
9 Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.
Bo to przyda wdzięczności głowie twojej, i będzie łańcuchem kosztownym szyi twojej.
10 Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́, má ṣe gbà fún wọn.
Synu mój! jeżliby cię namawiali grzesznicy, nie przyzwalaj.
11 Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa; jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan, jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;
Jeźlićby rzekli: Pójdź z nami, czyhajmy na krew, zasadźmy się na niewinnego bez przyczyny;
12 jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú, àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò; (Sheol h7585)
Pożremyż ich żywo, jako grób, a całkiem, jako zstępujących w dół; (Sheol h7585)
13 a ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa,
Wszelkiej majętności kosztownej nabędziemy, napełnimy domy nasze korzyścią;
14 da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa, a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà,”
Rzuć między nas los twój; mieszek jeden wszyscy mieć będziemy.
15 ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ, má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn.
Synu mójâ nie chodźże z nimi w drogę; zawściągnij nogi twojej od ścieżek ich.
16 Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀, wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.
Albowiem nogi ich ku złemu bieżą, i spieszą się na wylanie krwi.
17 Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀, ní ojú ẹyẹ!
Bo jako próżno zastawiają sieci przed oczyma wszelkiego ptaka skrzydlastego:
18 Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn. Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà.
Tak i ci na krew swoję czyhają, a zasadzają się na duszę swoję.
19 Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́; yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.
Takieć są ścieszki każdego czyhającego na zysk, który duszę pana swego odbiera.
20 Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;
Mądrość na dworzu woła, głos swój na ulicach wydaje.
21 láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:
W największym zgiełku woła, u wrót bram, w miastach powieści swoje opowiada, mówiąc:
22 “Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó? Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó? Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?
Prostacy! dokądże się kochać będziecie w prostocie? a naśmiewcy pośmiewisko miłować będziecie? a głupi nienawidzieć umiejętności będziecie?
23 Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni, ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.
Nawróćcież się na karanie moje; oto wam wydam ducha mojego, a podam wam do znajomości słowa moje.
24 Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,
Ponieważem wołała, a nie chcieliście; wyciągałam rękę moję, a nie był, ktoby uważał;
25 níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi, tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,
Owszem odrzuciliście wszystkę radę moję, a karności mojej nie chcieliście przyjąć;
26 Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín; èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.
Przetoż ja w zginieniu waszem śmiać się będę, będę z was szydziła, gdy przyjdzie, czego się strachacie.
27 Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle, nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà, nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.
Gdy przyjdzie jako spustoszenie, czego się strachacie, i gdy zginienie wasze przypadnie jako wicher, gdy przyjdzie na was ucisk i utrapienie;
28 “Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn; wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.
Tedy mię wzywać będą, a nie nie wysłucham; szukać mię będą z poranku, a nie znajdą mię.
29 Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀ tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.
Przeto, iż mieli w nienawiści umiejętność, a bojaźni Pańskiej nie obrali sobie,
30 Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,
Ani przestawali na radzie mijej, ale gardzili wszelką karnością moją:
31 wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún.
Przetoż będą używać owocu dróg swoich, a radami swemi nasyceni będą.
32 Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;
Bo odwrócenie prostaków pozabija ich, a szczęście głupich wytraci ich.
33 ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”
Ale kto mię słucha, bezpiecznie mieszkać będzie, a będzie wolny od strachu złych rzeczy.

< Proverbs 1 >