< Proverbs 1 >
1 Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.
Israel sangpahrang David a capa Solomon ak awicyih taw;
2 Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́, láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.
Cyihnaak ingkaw cawngpyinaak, zaaksimnaak thaikhqi siimsak ham,
3 Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo, àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;
Dyngnaak, awitlyknaak, pekbonaak a awm kaana hawnaak thai ham ingkaw cawngpyinaak ak thym pawmnaak thai ham;
4 láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀, ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.
Khawk hangkhqi khawsimnaak taaksak ham ingkaw, cacoenkhqi khawkpoek thainaak taaksak ham;
5 Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀, sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.
Thlakcyikhqi ing siim unawh a mi cyihnaak a pungnaak khqoet nawh, khawkpoek thaikhqi ing khawkpoeknaak thai a mi taaknaak khqoet hamna,
6 Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe, àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.
Awicyih ingkaw ak kqawncaihnaakkhqi, thlakcyi ak awi ingkaw a mik awih kqawn zaaksimnaak thai nace awm hy.
7 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.
Bawipa kqihchahnaak taw cyihnaak a kungpyina awm nawh; Cehlai, thlakqawkhqi ingtaw cyihnaak ingkaw cawngpyinaak husit uhy.
8 Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ, má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.
Ka capa, na pa cawngpyinaak ce ngai nawh, na nu cawngpyinaak ce koeh hoet.
9 Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.
Na lu hamna khqaipai leek soeihna awm nawh, na hawng hamna aawi hun leek soeihna awm kaw.
10 Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́, má ṣe gbà fún wọn.
Ka capa, thlakchekhqi ing a ni zoek awh koeh ngai kawp ti.
11 Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa; jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan, jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;
“Kami venna law lah, thlang a thi lawng sak lah usih, thlakche ak qeenkhqi ce qym khqi lah usih;
12 jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú, àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò; (Sheol )
Ceikhui amyihna a hqingpumna daih khqi lah usih, phyi khui amyihna. (Sheol )
13 a ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa,
A phuk tlotlokhqi ni ham kawm saw, thlang a theem ni qawtkhqi ing ni im ce nik bee kaw.
14 da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa, a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà,”
“Kami venawh bang lawlawt nawh taw, tangka bawm ni qup haih kawm uh,” a mi ti awh,
15 ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ, má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn.
Ka capa, a ming lakawh koeh boei nawh, a mi lam awhkawng phleng qu kawp ti.
16 Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀, wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.
A mi khaw ce thawlhnaak lam benna kaan unawh, thi ak lawngsak hamna a ming hqii tawn sak uhy.
17 Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀, ní ojú ẹyẹ!
Lawk ce ak chaap maina zan ni, kawmyih phaa a haiawh awm.
18 Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn. Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà.
Cekkhqi taw a mimah thi ce lawngsak unawh a mi hqingnaak ak plamsakkhqi ni.
19 Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́; yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.
Ceamyihna ni, a mak thymna ak kamvaakhqi lam taw; ami boei a hqingnaak ce lawh pe uhy.
20 Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;
Chawmkeeng awh cyihnaak ce khawteh na khyy nawh, Chawmkeeng tung keengawh ce khyy hy;
21 láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:
Thlang khawzah ang cunnaak ang lungkil awh ce khyy nawh, khawkkhui lutnaak vawng chawmkeeng awhce khyy hy.
22 “Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó? Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó? Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?
Nangmih khawk hangkhqi aw, i qyt dy nu khaw na mi hang hly? I qyt dy nu a nik husit khqi huhsitnaak khuiawh na mi awm hly, thlakqawkhqi ing cyihnaak na mi maa hly?
23 Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni, ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.
Ka ni toelnaakkhqi benna voei law uh: Ngai lah uh, na mik khanawh kang myihla theeh kawng nyng saw, kak awi zaaksimnaak ni pekkhqi kawng.
24 Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,
Nik khykhqi nyng, ni maa uhyk ti, ka kut soeng nyng, uca ingawm am do uhyk ti;
25 níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi, tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,
Ka khawkhannaakkhqi boeih ikawna am ngai unawh, ka ni toelnaakkhqi boeih ce hooet uhyk ti.
26 Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín; èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.
Ceamyihna awmsaw, kai ingawm na mi zoseet nyn awh ni qaih nak khqi kawng nyng saw, kyinaak na mi sawng lawawh ni qaih nak khqi kawng nyng.
27 Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle, nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà, nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.
Na mi lynak hlinu amyihna a thoeng law nawh, na mi zoseetnaak tym ing a pha lawawh, kyinaak ingkaw ngaihangnaak namik khanawh a pha law awh.
28 “Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn; wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.
Chawh ce, nik khy kawm uh tik saw, cesei-awm am nim hlat khqi kawng: mymcang hii awh ni sui kawm uk tik saw, ceseiawm am ni hu kawm uk ti;
29 Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀ tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.
Cyihnaak maa unawh, Bawipa kqihchahnaak ce ama mik tyhnaak ak caming.
30 Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,
Ka khawkhannaak pynoet ca mai awm am ngaih unawh, ka toelthamnaak boeih ce a mi huhsit caming.
31 wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún.
Ceamyihna awmsaw a mi khawsak ak thaih qah ce aii kawm usaw, a mik poeknaak ing qoh kawm uh.
32 Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;
Thlakchekhqi hu benna nawngnaak ing a mimah him khqi kawm saw, ak qawkhqi ang ngaihdingnaak ing amimah moeng sak khqi kaw.
33 ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”
Kak awi ak haanaak taw ak ding cana khaw sa kawm usaw, zoseetnaak khuiawh awm ngaiqeep cana khawsa kawm uh.