< Philippians 4 >
1 Nítorí náà ẹ̀yin ará mi olùfẹ́, ti mo sì ń ṣàfẹ́rí gidigidi, ayọ̀ àti adé mi, ẹ dúró ṣinṣin bẹ́ẹ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olùfẹ́ mi.
Então, meus queridos amigos, permaneçam firmes em sua fé no Senhor. Vocês significam muito para mim e me deixam muito contente! Eu os considero como a minha maior conquista! Eu verdadeiramente os amo e quero muito visitá-los!
2 Èmi ń bẹ̀ Euodia, mo sì ń bẹ Sintike, kí wọn ní inú kan náà nínú Olúwa.
Peço a Evódia e a Síntique que resolvam suas diferenças e cheguem a um acordo no Senhor.
3 Mo sì bẹ̀ yin pẹ̀lú bí alájọru àjàgà mi tòótọ́, ran àwọn obìnrin wọ̀nyí lọ́wọ́, nítorí wọn bá mi ṣiṣẹ́ pọ̀ ní ìfẹ̀gbẹ́-kẹ̀gbẹ́ nínú ìyìnrere, àti Klementi pẹ̀lú, àti àwọn olùbáṣiṣẹ́ mi yòókù pẹ̀lú, orúkọ àwọn tí ń bẹ nínú ìwé ìyè.
E a você, meu fiel companheiro de trabalho, gostaria de lhe pedir que ajude essas duas mulheres. Elas trabalharam comigo para anunciar o evangelho, assim como Clemente e meus outros colaboradores na fé, os nomes dos quais já estão gravados no livro da vida.
4 Ẹ máa yọ̀ nínú Olúwa nígbà gbogbo: mo sì tún wí pé. Ẹ máa yọ̀.
Estejam sempre felizes, unidos com o Senhor. Eu repito: estejam felizes!
5 Ẹ jẹ́ ki ìpamọ́ra yín di mímọ́ fún gbogbo ènìyàn, Olúwa ń bẹ nítòsí.
Que a bondade de vocês se estenda a todas as pessoas. O Senhor virá logo.
6 Ẹ má ṣe ṣe àníyàn ohunkóhun; ṣùgbọ́n nínú ohun gbogbo, nípa àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú ìdúpẹ́, ẹ máa fi ìbéèrè yín hàn fún Ọlọ́run.
Não se preocupem com nada, mas levem tudo a Deus em suas orações, fazendo os seus pedidos a ele e agradecendo por tudo o que recebem.
7 Àti àlàáfíà Ọlọ́run, tí ó ju ìmòye gbogbo lọ, yóò pa ọkàn àti èrò yín mọ nínú Kristi Jesu.
Então, a paz que vem de Deus, que é muito maior do que podemos imaginar, protegerá os seus pensamentos e as suas atitudes, pois vocês estão unidos a Jesus Cristo.
8 Ní àkótán, ará, ohunkóhun tí í ṣe òtítọ́, ohunkóhun tí í ṣe ọ̀wọ̀, ohunkóhun tí í ṣe títọ́ ohunkóhun tí í ṣe mímọ́, ohunkóhun tí í ṣe fífẹ́, ohunkóhun tí ó ni ìròyìn rere, bí ìwà títọ́ kan bá wà, bí ìyìn kan bá sì wà, ẹ máa gba nǹkan wọ̀nyí rò.
E, finalmente, pensem a respeito de tudo que é verdadeiro, respeitável, justo, puro, bonito, admirável; enfim, sobre tudo que é verdadeiramente bom e que mereça ser louvado.
9 Àwọn nǹkan tí ẹ̀yin ti kọ́, tí ẹ̀yin sì ti gbà, tí ẹ̀yin sì ti gbọ́, tí ẹ̀yin sì ti rí lọ́wọ́ mi, ẹ máa ṣe wọ́n: Ọlọ́run àlàáfíà yóò sì wà pẹ̀lú yín.
Coloquem em prática o que vocês aprenderam e receberam de mim, tudo o que me viram fazer e me ouviram dizer. E, assim, o Deus que traz a paz estará com vocês.
10 Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa pé, nísinsin yìí, ẹ̀yin tún ti sọjí nínú àníyàn ọkàn yín sí mi, nítòótọ́ ọkàn yín ń fàmọ́ mi ṣùgbọ́n ẹ kò ní àǹfààní tó.
Estou tão feliz no Senhor, por vocês terem novamente pensado em mim e por perceber que já estavam preocupados comigo! Não estou dizendo que vocês deixaram de cuidar de mim; é que não tiveram a oportunidade de demonstrar esse cuidado.
11 Kì í ṣe pé èmi ń sọ nítorí àìní: nítorí pé ni ipòkípò tí mo bá wà, mo tí kọ́ láti ní ìtẹ́lọ́rùn nínú rẹ̀.
Eu digo isso, não por causa das minhas necessidades, pois já aprendi a me adaptar às situações que enfrento.
12 Mo mọ̀ ohun tí o jẹ láti wa nínú àìní, mo sì mọ ohun tí ó jẹ láti ni lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nínú ohunkóhun àti nínú ohun gbogbo mo ti kọ́ àṣírí láti máa jẹ́ àjẹyó tàbí láti wà ni àìjẹun, láti máa ni ànító àti láti ṣe aláìní.
Eu sei o que é passar necessidade e também sei o que é ter mais do que se precisa. Em toda situação possível, eu aprendi o segredo de lidar com ter muito e com passar fome, de ser rico e de viver na pobreza.
13 Èmi le ṣe ohun gbogbo nínú Kristi ẹni ti ń fi agbára fún mi.
Eu posso fazer qualquer coisa por meio de Cristo, pois ele me fortalece!
14 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ṣeun gidigidi ní ti pé ẹ̀yin ṣe alábápín nínú ìpọ́njú mi.
Mesmo assim, foi muito bom vocês me ajudarem durante as minhas aflições.
15 Ẹ̀yin pàápàá sì mọ̀ pẹ̀lú, ẹ̀yin ará Filipi, pé ni ìbẹ̀rẹ̀ ìyìnrere, nígbà tí mo kúrò ni Makedonia, kò sí ìjọ kan ti ó bá mi ń ṣe alábápín ní ti gbígbà àti fífún ni, bí kò ṣe ẹ̀yin nìkan ṣoṣo.
Filipenses, lembrem-se de que desde o início do anúncio do evangelho, quando eu saí da Macedônia, a sua igreja foi a única que me ajudou financeiramente.
16 Nítorí ní Tẹsalonika ẹ̀yin fi nǹkan ránṣẹ́, lẹ́ẹ̀kan fún àìní mi.
Mesmo quando eu estava em Tessalônica, vocês me ajudaram não apenas uma vez, mas duas.
17 Kì í ṣe nítorí ti èmi ń fẹ́ ẹ̀bùn náà, ṣùgbọ́n èmi ń fẹ́ èso ti yóò máa di púpọ̀ nítorí yín.
Não que eu esteja buscando doações; o que eu quero mesmo é aumentar os “lucros” da “conta” de vocês.
18 Ṣùgbọ́n mo ní ohun gbogbo, mo sì ti di púpọ̀, mo sì tún ni lọ́pọ̀lọ́pọ̀ nígbà ti mo tí gba nǹkan wọ̀nyí lọ́wọ́ Epafiroditu tí a ti rán wá láti lọ́dọ̀ yín, ọrẹ olóòórùn dídùn, ẹbọ ìtẹ́wọ́gbà, tì í ṣe inú dídùn gidigidi sí Ọlọ́run.
Pois eu já tenho tudo, até mesmo mais do que preciso! Agradeço muito tudo o que vocês me mandaram, por meio de Epafrodito. O que enviaram é como um sacrifício de aroma agradável, que satisfaz a Deus e que ele aprova.
19 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run mi yóò pèsè ní kíkún fún gbogbo àìní yín, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ̀ nínú ògo nínú Kristi Jesu.
Meu Deus lhes dará tudo o que vocês precisam, de acordo com a sua gloriosa riqueza, em Cristo Jesus!
20 Ṣùgbọ́n ògo ni fún Ọlọ́run àti Baba wa láé àti láéláé. Àmín. (aiōn )
Glória seja dada a Deus, o Pai, para todo o sempre! Amém! (aiōn )
21 Ẹ kí olúkúlùkù ènìyàn mímọ́ nínú Kristi Jesu. Àwọn ará tí ó wà pẹ̀lú mi kí yín.
Saudações a todos os irmãos e irmãs na fé em Cristo Jesus. Os irmãos que estão aqui comigo enviam saudações.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ kí yín, pàápàá àwọn tí ń ṣe ti agbo ilé Kesari.
Todos os irmãos lhes enviam saudações, especialmente aqueles que se encontram no palácio do imperador.
23 Oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa, kí ó wà pẹ̀lú ẹ̀mí yín. Àmín.
Que a graça do Senhor Jesus Cristo esteja com todos vocês!