< Philippians 3 >
1 Ní àkótán ará, ẹ máa yọ̀ nínú Olúwa wa. Kì í ṣe ìnira fún mi láti kọ̀wé ohun kan náà sí yín, ṣùgbọ́n fún yín ó jẹ́ ohun ààbò.
In conclusion, my brethren, be joyful in the Lord. For me to give you the same warnings as before is not irksome to me, while so far as you are concerned it is a safe precaution.
2 Ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn ajá, ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn oníṣẹ́ búburú, ẹ sì kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn onílà.
Beware of 'the dogs,' the bad workmen, the self-mutilators.
3 Nítorí àwa ni onílà, tí ń sin Ọlọ́run nípa ti Ẹ̀mí, àwa sì ń ṣògo nínú Kristi Jesu, àwa kò sí ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ẹran-ara.
For we are the true circumcision--we who render to God a spiritual worship and make our boast in Christ Jesus and have no confidence in outward ceremonies:
4 Bí èmi tìkára mi pẹ̀lú ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ara. Bí ẹnikẹ́ni bá rò pé òun ni ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ara, tèmi tilẹ̀ pọ̀,
although I myself might have some excuse for confidence in outward ceremonies. If any one else claims a right to trust in them, far more may I:
5 ẹni tí a kọ nílà ní ọjọ́ kẹjọ, láti inú kùkùté Israẹli wá, láti inú ẹ̀yà Benjamini, Heberu láti inú Heberu wá; nítorí, ní ti òfin Farisi ni èmi;
circumcised, as I was, on the eighth day, a member of the race of Israel and of the tribe of Benjamin, a Hebrew sprung from Hebrews; as to the Law a Pharisee;
6 ní ti ìtara, èmi ń ṣe inúnibíni sí ìjọ; ní ti òdodo tí ó wà nínú òfin, mo jẹ́ aláìlẹ́gàn.
as to zeal, a persecutor of the Church; as to the righteousness which comes through Law, blameless.
7 Ṣùgbọ́n ohunkóhun tí ó ti jásí èrè fún mi, àwọn ni mo ti kà sí òfo nítorí Kristi.
Yet all that was gain to me--for Christ's sake I have reckoned it loss.
8 Nítòótọ́ láìṣe àní àní mo sì ka ohun gbogbo sí òfo nítorí ìtayọ ìmọ̀ Kristi Jesu Olúwa mi; nítorí ẹni ti mo ti ṣòfò ohun gbogbo, mo si kà wọn sí ohun tí kò ní èrè, kí èmi lè jèrè Kristi,
Nay, I even reckon all things as pure loss because of the priceless privilege of knowing Christ Jesus my Lord. And for His sake I have suffered the loss of everything, and reckon it all as mere refuse, in order that I may win Christ and be found in union with Him,
9 kí a sì lè bá mi nínú rẹ̀, láìní òdodo tí èmi tìkára mi, tí ó ti inú òfin wá, ṣùgbọ́n èyí tí ó ti inú ìgbàgbọ́ wá nínú Kristi, òdodo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run nípasẹ̀ ìgbàgbọ́.
not having a righteousness of my own, derived from the Law, but that which arises from faith in Christ--the righteousness which comes from God through faith.
10 Èmi mọ̀ ọ́n, àti agbára àjíǹde rẹ̀, àti láti jẹ́ alábápín nínú ìyà rẹ̀ nígbà tí mo bá fi ara mọ́ ọn nínú ikú rẹ̀;
I long to know Christ and the power which is in His resurrection, and to share in His sufferings and die even as He died;
11 nípasẹ̀ bẹ́ẹ̀ kí èmi lè ní àjíǹde kúrò nínú òkú.
in the hope that I may attain to the resurrection from among the dead.
12 Kì í ṣe pé ọwọ́ mi ti tẹ̀ ẹ́ ná, tàbí mo ti di pípé, ṣùgbọ́n èmi ń lépa sí i, bí ọwọ́ mi yóò lè tẹ èrè náà nítorí èyí tí a ti dì mímú pẹ̀lú, láti ọ̀dọ̀ Kristi Jesu wá.
I do not say that I have already won the race or have already reached perfection. But I am pressing on, striving to lay hold of the prize for which also Christ has laid hold of me.
13 Ará, èmi kò kara mi sí ẹni ti ọwọ́ rẹ̀ ti tẹ̀ ẹ́ ná, ṣùgbọ́n ohun kan yìí ni èmi ń ṣe, èmi ń gbàgbé àwọn nǹkan tí ó ti kọjá. Lẹ́yìn náà mo ń nàgà wo àwọn nǹkan tí ó wà níwájú.
Brethren, I do not imagine that I have yet laid hold of it. But this one thing I do--forgetting everything which is past and stretching forward to what lies in front of me,
14 Èmi ń lépa láti dé òpin eré ìje náà fún èrè ìpè gíga Ọlọ́run nínú Kristi Jesu.
with my eyes fixed on the goal I push on to secure the prize of God's heavenward call in Christ Jesus.
15 Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí àwa tí a dàgbà nípa ti ẹ̀mí ni èrò yìí; bí ẹ̀yin bá sì ní èrò mìíràn nínú ohunkóhun, èyí náà pẹ̀lú ni Ọlọ́run yóò fihàn yín.
Therefore let all of us who are mature believers cherish these thoughts; and if in any respect you think differently, that also God will make clear to you.
16 Kìkì pé, ki a ma gbe ìgbé ayé gẹ́gẹ́ bi èyí ti a ri gba.
But whatever be the point that we have already reached, let us persevere in the same course.
17 Ará, ẹ jùmọ̀ ṣe àfarawé mi, ẹ ṣe àkíyèsí àwọn tí ń rìn bẹ́ẹ̀, àní bí ẹ ti ní wa fún àpẹẹrẹ.
Brethren, vie with one another in imitating me, and carefully observe those who follow the example which we have set you.
18 Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní ń rìn, nípasẹ̀ àwọn ẹni tí mo ti ń wí fún yín nígbàkígbà, àní, tí mo sì ń sọkún bí mo ti ń wí fún yín nísinsin yìí, pé, ọ̀tá àgbélébùú Kristi ni wọ́n.
For there are many whom I have often described to you, and I now even with tears describe them, as being enemies to the Cross of Christ.
19 Ìgbẹ̀yìn wọn ni ìparun, ikùn wọn sì ni Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń ṣògo nínú ìtìjú wọn, àwọn ẹni tí ń tọ́jú ohun ti ayé.
Their end is destruction, their bellies are their God, their glory is in their shame, and their minds are devoted to earthly things.
20 Nítorí ìlú ìbílẹ̀ wá ń bẹ̀ ní ọ̀run, láti ibi ti àwa pẹ̀lú gbé ń fojúsọ́nà fún Olùgbàlà, Jesu Kristi Olúwa.
We, however, are free citizens of Heaven, and we are waiting with longing expectation for the coming from Heaven of a Saviour, the Lord Jesus Christ,
21 Ẹni tí yóò sọ ara ìrẹ̀lẹ̀ wa di ọ̀tún kí ó lè bá ara ògo rẹ̀ mu, nípa agbára tí ó mú kí ó ṣe é ṣe fún un láti tẹ orí ohun gbogbo bá fún ara rẹ̀.
who, in the exercise of the power which He has even to subject all things to Himself, will transform this body of our humiliation until it resembles His own glorious body.