< Philippians 2 >

1 Bí ìwọ bá ní ìmúlọ́kànle nítorí pé ìwọ wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú Kristi, bi ìtùnú kan bá wà nínú ìfẹ́ rẹ̀, bí ìdàpọ̀ Ẹ̀mí kan bá wà, bí ìyọ́nú àti ìṣeun bá wà,
کھْرِیشْٹادْ یَدِ کِمَپِ سانْتْوَنَں کَشْچِتْ پْریمَجاتو ہَرْشَح کِنْچِدْ آتْمَنَح سَمَبھاگِتْوَں کاچِدْ اَنُکَمْپا کرِپا وا جایَتے تَرْہِ یُویَں مَماہْلادَں پُورَیَنْتَ
2 síbẹ̀ ẹ mú ayọ̀ mi kún nínú ìṣọ̀kan yín, nípa ìfẹ́ kan náà, wíwà ní ẹ̀mí kan náà àti ète kan náà.
ایکَبھاوا ایکَپْریمانَ ایکَمَنَسَ ایکَچیشْٹاشْچَ بھَوَتَ۔
3 Ẹ má ṣe ohunkóhun nínú ìlépa ara tàbí ògo asán, ṣùgbọ́n ní ìrẹ̀lẹ̀ ọkàn kí olúkúlùkù ro àwọn ẹlòmíràn sí ẹni ti ó sàn ju òun lọ.
وِرودھادْ دَرْپادْ وا کِمَپِ ما کُرُتَ کِنْتُ نَمْرَتَیا سْویبھْیوپَرانْ وِشِشْٹانْ مَنْیَدھْوَں۔
4 Kí olúkúlùkù yín má ṣe ro ohun ti ara rẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n ti ẹlòmíràn pẹ̀lú.
کیوَلَمْ آتْمَہِتایَ نَ چیشْٹَماناح پَرَہِتایاپِ چیشْٹَدھْوَں۔
5 Nínú ìbáṣepọ̀ yin pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn, ẹ ni irú ìlépa ọkàn náà bí ti Kristi Jesu.
کھْرِیشْٹَسْیَ یِیشو رْیادرِشَح سْوَبھاوو یُشْماکَمْ اَپِ تادرِشو بھَوَتُ۔
6 Ẹni tí, bí o tilẹ̀ jẹ́ ìrísí Ọlọ́run, kò kà á sí ohun tí ìbá fi ìwọra gbámú láti bá Ọlọ́run dọ́gba.
سَ اِیشْوَرَرُوپِی سَنْ سْوَکِییامْ اِیشْوَرَتُلْیَتاں شْلاگھاسْپَدَں نامَنْیَتَ،
7 Ṣùgbọ́n ó bọ́ ògo rẹ̀ sílẹ̀, ó sì mú àwọ̀ ìránṣẹ́, a sì ṣe é ni àwòrán ènìyàn.
کِنْتُ سْوَں شُونْیَں کرِتْوا داسَرُوپِی بَبھُووَ نَراکرِتِں لیبھے چَ۔
8 Ó sì wà ní àwòrán ènìyàn, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, o sì tẹríba títí de ojú ikú, àní ikú lórí àgbélébùú.
اِتّھَں نَرَمُورْتِّمْ آشْرِتْیَ نَمْرَتاں سْوِیکرِتْیَ مرِتْیورَرْتھَتَح کْرُشِییَمرِتْیوریوَ بھوگایاجْناگْراہِی بَبھُووَ۔
9 Nítorí náà, Ọlọ́run ti gbé e ga sí ipele tí ó ga jùlọ, ó sì ti fi orúkọ kan ti ó borí gbogbo orúkọ fún un,
تَتْکارَنادْ اِیشْوَروپِ تَں سَرْوّونَّتَں چَکارَ یَچَّ نامَ سَرْوّیشاں نامْناں شْریشْٹھَں تَدیوَ تَسْمَے دَدَو،
10 pé ni orúkọ Jesu ni kí gbogbo eékún máa wólẹ̀, ní ọ̀run, àti ní orí ilẹ̀ ayé àti ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
تَتَسْتَسْمَے یِیشُنامْنے سْوَرْگَمَرْتْیَپاتالَسْتھِتَیح سَرْوَّے رْجانُپاتَح کَرْتَّوْیَح،
11 àti pé kí gbogbo ahọ́n jẹ́wọ́ pé, Jesu Kristi ni Olúwa, fún ògo Ọlọ́run Baba.
تاتَسْتھیشْوَرَسْیَ مَہِمْنے چَ یِیشُکھْرِیشْٹَح پْرَبھُرِتِ جِہْوابھِح سْوِیکَرْتَّوْیَں۔
12 Nítorí náà ẹ̀yin ará mi, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ń gbọ́rọ̀ nígbà gbogbo, kì í ṣe nígbà ti mo wà lọ́dọ̀ yín nìkan, ṣùgbọ́n pàápàá nísinsin yìí tí èmi kò sí ni àárín yín, ẹ máa ṣiṣẹ́ ìgbàlà yín yọrí pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì,
اَتو ہے پْرِیَتَماح، یُشْمابھِ رْیَدْوَتْ سَرْوَّدا کْرِیَتے تَدْوَتْ کیوَلے مَموپَسْتھِتِکالے تَنَّہِ کِنْتْوِدانِیمْ اَنُپَسْتھِتےپِ مَیِ بَہُتَرَیَتْنیناجْناں گرِہِیتْوا بھَیَکَمْپابھْیاں سْوَسْوَپَرِتْرانَں سادھْیَتاں۔
13 nítorí pé Ọlọ́run ni ó n ṣiṣẹ́ nínú yín, láti fẹ́ àti láti ṣiṣẹ́ fún ète rere rẹ̀.
یَتَ اِیشْوَرَ ایوَ سْوَکِییانُرودھادْ یُشْمَنْمَدھْیے مَنَسْکامَناں کَرْمَّسِدّھِنْچَ وِدَدھاتِ۔
14 Ẹ máa ṣe ohun gbogbo láìsí ìkùnsínú àti ìjiyàn.
یُویَں کَلَہَوِوادَرْوِجَتَمْ آچارَں کُرْوَّنْتونِنْدَنِییا اَکُٹِلا
15 Kí ẹ̀yin lè jẹ́ aláìlẹ́gàn àti oníwà mímọ́, ọmọ Ọlọ́run, aláìlábàwọ́n, láàrín oníwà wíwọ́ àti alárékérekè orílẹ̀-èdè láàrín àwọn ẹni tí a ń rí yín bí ìmọ́lẹ̀ ní ayé.
اِیشْوَرَسْیَ نِشْکَلَنْکاشْچَ سَنْتانااِوَ وَکْرَبھاواناں کُٹِلاچارِنانْچَ لوکاناں مَدھْیے تِشْٹھَتَ،
16 Bí ẹ sì ṣe di ọ̀rọ̀ ìyè mú gírígírí, kí èmi lè ṣògo ni ọjọ́ Kristi pé èmi kò sáré lásán, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ṣe làálàá lásán.
یَتَسْتیشاں مَدھْیے یُویَں جِیوَنَواکْیَں دھارَیَنْتو جَگَتو دِیپَکا اِوَ دِیپْیَدھْوے۔ یُشْمابھِسْتَتھا کرِتے مَمَ یَتْنَح پَرِشْرَمو وا نَ نِشْپھَلو جاتَ اِتْیَہَں کھْرِیشْٹَسْیَ دِنے شْلاگھاں کَرْتُّں شَکْشْیامِ۔
17 Ṣùgbọ́n, bí a tilẹ̀ ń dà mí bí ọtí-ìrúbọ sórí ẹbọ iṣẹ́ ìsìn ìgbàgbọ́ yín, inú mi dùn, mo sì ń bá gbogbo yín yọ̀ pẹ̀lú.
یُشْماکَں وِشْواسارْتھَکایَ بَلِدانایَ سیوَنایَ چَ یَدْیَپْیَہَں نِویدِتَوْیو بھَوییَں تَتھاپِ تینانَنْدامِ سَرْوّیشاں یُشْماکَمْ آنَنْدَسْیاںشِی بھَوامِ چَ۔
18 Bákan náà ni kí ẹ̀yin máa yọ̀, kí ẹ sì máa bá mi yọ̀ pẹ̀lú.
تَدْوَدْ یُویَمَپْیانَنْدَتَ مَدِییانَنْدَسْیاںشِنو بھَوَتَ چَ۔
19 Mo ni ìrètí nínú Jesu Olúwa, láti rán Timotiu sí yín ni àìpẹ́ yìí, kí èmi pẹ̀lú lè ni ìfọ̀kànbalẹ̀ nígbà tí mo bá gbúròó yín.
یُشْماکَمْ اَوَسْتھامْ اَوَگَتْیاہَمَپِ یَتْ سانْتْوَناں پْراپْنُیاں تَدَرْتھَں تِیمَتھِیَں تْوَرَیا یُشْمَتْسَمِیپَں پْریشَیِشْیامِیتِ پْرَبھَو پْرَتْیاشاں کُرْوّے۔
20 Nítorí èmi kò ni ẹlòmíràn tí ó dàbí rẹ̀, tí yóò máa fi tinútinú ṣe àníyàn yín.
یَح سَتْیَرُوپینَ یُشْماکَں ہِتَں چِنْتَیَتِ تادرِشَ ایکَبھاوَسْتَسْمادَنْیَح کوپِ مَمَ سَنِّدھَو ناسْتِ۔
21 Nítorí gbogbo wọn ni ó tọ́jú nǹkan ti ara wọn, kì í ṣe àwọn nǹkan ti Jesu Kristi.
یَتوپَرے سَرْوّے یِیشوح کھْرِیشْٹَسْیَ وِشَیانْ نَ چِنْتَیَنْتَ آتْمَوِشَیانْ چِنْتَیَنْتِ۔
22 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin mọ̀ pé Timotiu pegedé, gẹ́gẹ́ bí ọmọ lọ́dọ̀ baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ti ń bá mi ṣiṣẹ́ pọ̀, nínú iṣẹ́ ìyìnrere.
کِنْتُ تَسْیَ پَرِیکْشِتَتْوَں یُشْمابھِ رْجْنایَتے یَتَح پُتْرو یادرِکْ پِتُح سَہَکارِی بھَوَتِ تَتھَیوَ سُسَںوادَسْیَ پَرِچَرْیّایاں سَ مَمَ سَہَکارِی جاتَح۔
23 Nítorí náà, mo ní ìrètí láti rán sí yín ní àìpẹ́ tí mo bá wòye bí yóò ti rí fún mi.
اَتَایوَ مَمَ بھاوِدَشاں جْناتْوا تَتْکْشَناتْ تَمیوَ پْریشَیِتُں پْرَتْیاشاں کُرْوّی
24 Ṣùgbọ́n mo ní gbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa, pé èmi tìkára mi pẹ̀lú yóò wá ní àìpẹ́.
سْوَیَمْ اَہَمَپِ تُورْنَں یُشْمَتْسَمِیپَں گَمِشْیامِیتْیاشاں پْرَبھُنا کُرْوّے۔
25 Mo kà á sí pé n kò lè ṣàìrán Epafiroditu arákùnrin mi sí yín, àti olùbáṣiṣẹ́ pọ̀ mi, àti ọmọ-ogun ẹlẹgbẹ́ mi, ìránṣẹ́ yín pẹ̀lú, tí ẹ rán láti ṣè ránṣẹ́ fún mi nínú àìní mi.
اَپَرَں یَ اِپاپھْرَدِیتو مَمَ بھْراتا کَرْمَّیُدّھابھْیاں مَمَ سَہایَشْچَ یُشْماکَں دُوتو مَدِییوپَکارایَ پْرَتِنِدھِشْچاسْتِ یُشْمَتْسَمِیپے تَسْیَ پْریشَنَمْ آوَشْیَکَمْ اَمَنْیے۔
26 Nítorí tí ọkàn rẹ̀ fà sí gbogbo yín, ó sì kún fún ìbànújẹ́, nítorí tí ẹ̀yin gbọ́ pé ó ṣe àìsàn.
یَتَح سَ یُشْمانْ سَرْوّانْ اَکانْکْشَتَ یُشْمابھِسْتَسْیَ روگَسْیَ وارْتّاشْراوِیتِ بُدّھوا پَرْیَّشوچَچَّ۔
27 Nítòótọ́ ni ó ti ṣe àìsàn títí dé ojú ikú, ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti ṣàánú fún un; kì í sì í ṣe fún òun nìkan, ṣùgbọ́n fún èmi pẹ̀lú kí èmi má ṣe ni ìbànújẹ́ lórí ìbànújẹ́.
سَ پِیڈَیا مرِتَکَلْپوبھَوَدِتِ سَتْیَں کِنْتْوِیشْوَرَسْتَں دَیِتَوانْ مَمَ چَ دُحکھاتْ پَرَں پُنَرْدُحکھَں یَنَّ بھَویتْ تَدَرْتھَں کیوَلَں تَں نَ دَیِتْوا مامَپِ دَیِتَوانْ۔
28 Nítorí náà ni mo ṣe ní ìtara láti rán an, pé nígbà tí ẹ̀yin bá sì tún rí i, kí ẹ̀yin lè yọ̀ àti kí ìkáyà sókè mi lè dínkù.
اَتَایوَ یُویَں تَں وِلوکْیَ یَتْ پُنَرانَنْدیتَ مَماپِ دُحکھَسْیَ ہْراسو یَدْ بھَویتْ تَدَرْتھَمْ اَہَں تْوَرَیا تَمْ اَپْریشَیَں۔
29 Nítorí náà, ẹ fi ayọ̀ púpọ̀ gbà á nínú Olúwa; kí ẹ sì máa bu ọlá fún irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀.
اَتو یُویَں پْرَبھوح کرِتے سَمْپُورْنینانَنْدینَ تَں گرِہْلِیتَ تادرِشانْ لوکاںشْچادَرَنِییانْ مَنْیَدھْوَں۔
30 Nítorí iṣẹ́ Kristi ni ó ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú, tí ó sì fi ẹ̀mí ara rẹ̀ wéwu, láti mu àìtó iṣẹ́ ìsìn yín sí mi kún.
یَتو مَمَ سیوَنے یُشْماکَں تْرُٹِں پُورَیِتُں سَ پْرانانْ پَنِیکرِتْیَ کھْرِیشْٹَسْیَ کارْیّارْتھَں مرِتَپْرایےبھَوَتْ۔

< Philippians 2 >