< Philippians 2 >

1 Bí ìwọ bá ní ìmúlọ́kànle nítorí pé ìwọ wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú Kristi, bi ìtùnú kan bá wà nínú ìfẹ́ rẹ̀, bí ìdàpọ̀ Ẹ̀mí kan bá wà, bí ìyọ́nú àti ìṣeun bá wà,
Jeźli tedy macie jaką pociechę w Chrystusie, jeźli jaką uciechę miłości, jeźli jaką społeczność ducha, jeźli są jakie wnętrzności i zlitowania w was,
2 síbẹ̀ ẹ mú ayọ̀ mi kún nínú ìṣọ̀kan yín, nípa ìfẹ́ kan náà, wíwà ní ẹ̀mí kan náà àti ète kan náà.
Dopełnijcież wesela mojego, abyście jednoż rozumieli, jednostajną miłość mając, będąc jednomyślni i jednoż rozumiejący;
3 Ẹ má ṣe ohunkóhun nínú ìlépa ara tàbí ògo asán, ṣùgbọ́n ní ìrẹ̀lẹ̀ ọkàn kí olúkúlùkù ro àwọn ẹlòmíràn sí ẹni ti ó sàn ju òun lọ.
Nic nie czyniąc spornie, albo przez próżną chwałę, ale w pokorze jedni drugich mając za wyższych nad się.
4 Kí olúkúlùkù yín má ṣe ro ohun ti ara rẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n ti ẹlòmíràn pẹ̀lú.
Nie upatrujcie każdy tylko, co jest jego, ale każdy też, co jest drugich.
5 Nínú ìbáṣepọ̀ yin pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn, ẹ ni irú ìlépa ọkàn náà bí ti Kristi Jesu.
Tego tedy bądźcie o sobie rozumienia, które było i w Chrystusie Jezusie.
6 Ẹni tí, bí o tilẹ̀ jẹ́ ìrísí Ọlọ́run, kò kà á sí ohun tí ìbá fi ìwọra gbámú láti bá Ọlọ́run dọ́gba.
Który, będąc w kształcie Bożym, nie poczytał sobie tego za drapiestwo równym być Bogu,
7 Ṣùgbọ́n ó bọ́ ògo rẹ̀ sílẹ̀, ó sì mú àwọ̀ ìránṣẹ́, a sì ṣe é ni àwòrán ènìyàn.
Ale wyniszczył samego siebie, przyjąwszy kształt niewolnika, stawszy się podobny ludziom;
8 Ó sì wà ní àwòrán ènìyàn, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, o sì tẹríba títí de ojú ikú, àní ikú lórí àgbélébùú.
I postawą znaleziony jako człowiek, sam się poniżył, będąc posłusznym aż do śmierci, a to śmierci krzyżowej.
9 Nítorí náà, Ọlọ́run ti gbé e ga sí ipele tí ó ga jùlọ, ó sì ti fi orúkọ kan ti ó borí gbogbo orúkọ fún un,
Dlatego też Bóg nader go wywyższył i darował mu imię, które jest nad wszystkie imię;
10 pé ni orúkọ Jesu ni kí gbogbo eékún máa wólẹ̀, ní ọ̀run, àti ní orí ilẹ̀ ayé àti ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
Aby w imieniu Jezusowem wszelkie się kolano skłaniało, tych, którzy są na niebiesiech i tych, którzy są na ziemi, i tych, którzy są pod ziemią.
11 àti pé kí gbogbo ahọ́n jẹ́wọ́ pé, Jesu Kristi ni Olúwa, fún ògo Ọlọ́run Baba.
A wszelki język aby wyznawał, że Jezus Chrystus jest Panem ku chwale Boga Ojca.
12 Nítorí náà ẹ̀yin ará mi, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ń gbọ́rọ̀ nígbà gbogbo, kì í ṣe nígbà ti mo wà lọ́dọ̀ yín nìkan, ṣùgbọ́n pàápàá nísinsin yìí tí èmi kò sí ni àárín yín, ẹ máa ṣiṣẹ́ ìgbàlà yín yọrí pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì,
Przetoż, moi mili! jakoście zawsze posłuszni byli, nie tylko w przytomności mojej, ale teraz daleko więcej w niebytności mojej, z bojaźnią i ze drżeniem zbawienie swoje sprawujcie.
13 nítorí pé Ọlọ́run ni ó n ṣiṣẹ́ nínú yín, láti fẹ́ àti láti ṣiṣẹ́ fún ète rere rẹ̀.
Albowiem Bóg jest, który sprawuje w was chcenie i skuteczne wykonanie według upodobania swego.
14 Ẹ máa ṣe ohun gbogbo láìsí ìkùnsínú àti ìjiyàn.
Wszystko czyńcie bez szemrania i poswarków,
15 Kí ẹ̀yin lè jẹ́ aláìlẹ́gàn àti oníwà mímọ́, ọmọ Ọlọ́run, aláìlábàwọ́n, láàrín oníwà wíwọ́ àti alárékérekè orílẹ̀-èdè láàrín àwọn ẹni tí a ń rí yín bí ìmọ́lẹ̀ ní ayé.
Abyście byli bez nagany i szczeremi dziatkami Bożemi, nienaganionymi w pośrodku narodu złego i przewrotnego, między którymi świecicie jako światła na świecie.
16 Bí ẹ sì ṣe di ọ̀rọ̀ ìyè mú gírígírí, kí èmi lè ṣògo ni ọjọ́ Kristi pé èmi kò sáré lásán, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ṣe làálàá lásán.
Zachowywując słowa żywota ku chlubie mojej w dzień Chrystusowy, żem darmo nie bieżał i darmo nie pracował.
17 Ṣùgbọ́n, bí a tilẹ̀ ń dà mí bí ọtí-ìrúbọ sórí ẹbọ iṣẹ́ ìsìn ìgbàgbọ́ yín, inú mi dùn, mo sì ń bá gbogbo yín yọ̀ pẹ̀lú.
Ale choćbym ofiarowany był dla ofiary i usługi wiary waszej, weselę się i spółweselę się ze wszystkimi wami;
18 Bákan náà ni kí ẹ̀yin máa yọ̀, kí ẹ sì máa bá mi yọ̀ pẹ̀lú.
Z tegoż tedy i wy weselcie się i spółweselcie się ze mną.
19 Mo ni ìrètí nínú Jesu Olúwa, láti rán Timotiu sí yín ni àìpẹ́ yìí, kí èmi pẹ̀lú lè ni ìfọ̀kànbalẹ̀ nígbà tí mo bá gbúròó yín.
A mam nadzieję w Panu Jezusie, iż Tymoteusza w rychle poślę do was, abym się i ja ucieszył, dowiedziawszy się, co się z wami dzieje.
20 Nítorí èmi kò ni ẹlòmíràn tí ó dàbí rẹ̀, tí yóò máa fi tinútinú ṣe àníyàn yín.
Albowiem nie mam nikogo w umyśle jemu równego, który by się uprzejmie o rzeczy wasze starać chciał;
21 Nítorí gbogbo wọn ni ó tọ́jú nǹkan ti ara wọn, kì í ṣe àwọn nǹkan ti Jesu Kristi.
Bo wszyscy swoich rzeczy szukają, a nie tych, które są Jezusa Chrystusa.
22 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin mọ̀ pé Timotiu pegedé, gẹ́gẹ́ bí ọmọ lọ́dọ̀ baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ti ń bá mi ṣiṣẹ́ pọ̀, nínú iṣẹ́ ìyìnrere.
Ale wiecie, iż on jest doświadczonym, a iż jako syn z ojcem ze mną służył w Ewangielii.
23 Nítorí náà, mo ní ìrètí láti rán sí yín ní àìpẹ́ tí mo bá wòye bí yóò ti rí fún mi.
Mam tedy nadzieję, że tego do was poślę, skoro obaczę, co się ze mną dalej dziać będzie;
24 Ṣùgbọ́n mo ní gbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa, pé èmi tìkára mi pẹ̀lú yóò wá ní àìpẹ́.
A mam ufność w Panu, że i sam w rychle do was przyjdę.
25 Mo kà á sí pé n kò lè ṣàìrán Epafiroditu arákùnrin mi sí yín, àti olùbáṣiṣẹ́ pọ̀ mi, àti ọmọ-ogun ẹlẹgbẹ́ mi, ìránṣẹ́ yín pẹ̀lú, tí ẹ rán láti ṣè ránṣẹ́ fún mi nínú àìní mi.
Alem rozumiał rzeczą potrzebną, Epafrodyta, brata i pomocnika i spółbojownika mego, a waszego Apostoła i sługę w potrzebie mojej, posłać do was,
26 Nítorí tí ọkàn rẹ̀ fà sí gbogbo yín, ó sì kún fún ìbànújẹ́, nítorí tí ẹ̀yin gbọ́ pé ó ṣe àìsàn.
Ponieważ pragnął was wszystkich i bardzo się frasował, żeście słyszeli, iż zachorował.
27 Nítòótọ́ ni ó ti ṣe àìsàn títí dé ojú ikú, ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti ṣàánú fún un; kì í sì í ṣe fún òun nìkan, ṣùgbọ́n fún èmi pẹ̀lú kí èmi má ṣe ni ìbànújẹ́ lórí ìbànújẹ́.
Bo wprawdzie chorował mało nie na śmierć; ale się Bóg zmiłował nad nim, a nie tylko nad nim, ale i nade mną, abym nie miał smutku na smutek.
28 Nítorí náà ni mo ṣe ní ìtara láti rán an, pé nígbà tí ẹ̀yin bá sì tún rí i, kí ẹ̀yin lè yọ̀ àti kí ìkáyà sókè mi lè dínkù.
Przetoż tem ochotniej posłałem go, abyście zasię ujrzawszy go, uweselili się, a ja abym miał mniej smutku.
29 Nítorí náà, ẹ fi ayọ̀ púpọ̀ gbà á nínú Olúwa; kí ẹ sì máa bu ọlá fún irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀.
Przyjmijcież go tedy w Panu ze wszystkiem weselem; a takich w poczciwości miejcie;
30 Nítorí iṣẹ́ Kristi ni ó ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú, tí ó sì fi ẹ̀mí ara rẹ̀ wéwu, láti mu àìtó iṣẹ́ ìsìn yín sí mi kún.
Boć dla dzieła Chrystusowego bliskim był śmierci, odważywszy zdrowie swoje, aby dopełnił tego, czego nie dostawało w usłudze waszej przeciwko mnie.

< Philippians 2 >