< Philippians 1 >
1 Paulu àti Timotiu, àwọn ìránṣẹ́ Jesu Kristi, Sí gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ nínú Kristi Jesu tí ó wà ní Filipi, pẹ̀lú àwọn alábojútó àti àwọn díákónì:
Əysa Mǝsiⱨning ⱪulliri bolƣan Pawlus wǝ Timotiydin, Filippida turuwatⱪan, Mǝsiⱨ Əysada bolƣan barliⱪ muⱪǝddǝs bǝndilǝrgǝ, yetǝkqilǝr wǝ hizmǝtqilǝrgǝ salam!
2 Oore-ọ̀fẹ́ sí yín, àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa, àti Olúwa wa Jesu Kristi.
Silǝrgǝ Huda’Atimiz wǝ Rǝb Əysa Mǝsiⱨtin meⱨir-xǝpⱪǝt wǝ hatirjǝmlik ata ⱪilinƣay!
3 Mo ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run mi ní gbogbo ìgbà tí mo bá rántí yín.
Ⱨǝrⱪetim silǝrni ǝsliginimdǝ mǝn Hudayimƣa tǝxǝkkür eytimǝn,
4 Nínú gbogbo àdúrà mi fún un yín, èmi ń fi ayọ̀ gbàdúrà,
ⱨǝrⱪetim dua ⱪilƣinimda, silǝrning birinqi künidin tartip bügüngǝ ⱪǝdǝr hux hǝwǝr hizmitigǝ bolƣan ⱨǝmkarliⱪinglar tüpǝylidin tohtimay xad-huramliⱪ bilǝn silǝrgǝ dua-tilawǝt ⱪiliwatimǝn;
5 nítorí ìdàpọ̀ yín nínú ìyìnrere láti ọjọ́ kìn-ín-ní wá títí di ìsinsin yìí.
6 Ohun kan yìí sá à dá mi lójú pé, ẹni tí ó ti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere nínú yín, yóò ṣe àṣepé rẹ̀ títí di ọjọ́ náà tí Jesu Kristi yóò dé.
qünki mening dǝl xuningƣa ixǝnqim kamilki, silǝrdǝ yahxi ixni Baxliƣuqi bu ixni taki Əysa Mǝsiⱨning künigiqǝ kamalǝtkǝ yǝtküzüp tamamlaydu;
7 Gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ fún mi láti ro èyí nípa gbogbo yín, nítorí tí mo fi yín sọ́kàn, bí mo tilẹ̀ wà nínú ìdè tàbí ìdáhùn ẹjọ́, àti ìfẹsẹ̀múlẹ̀ ìyìnrere, gbogbo yín jẹ́ alábápín oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run pẹ̀lú mi.
mening ⱨǝmminglar toƣruluⱪ xundaⱪ oylixim toƣridur; qünki mǝn ⱪǝlbinglardidurmǝn; mǝn zindanda zǝnjirlǝnginimdimu wǝ hux hǝwǝrni aⱪliƣinimdimu, dǝlilliginimdimu [Huda manga yǝtküzgǝn] meⱨir-xǝpⱪǝttin silǝrmu ortaⱪ bǝⱨrimǝn bolisilǝr.
8 Nítorí Ọlọ́run ni ẹlẹ́rìí mi, bí mo ti ń ṣàfẹ́rí yín gidigidi nínú ìfẹ́ Jesu Kristi.
Mening Mǝsiⱨ Əysaning iq-baƣrida bolup silǝrni xunqilik tǝlpünüp seƣinƣanliⱪimƣa Huda Ɵzi guwaⱨqidur.
9 Èyí sì ni àdúrà mi: pé kí ìfẹ́ yín lè máa pọ̀ síwájú àti síwájú sí i nínú ìfẹ́ àti ìmọ̀ ìjìnlẹ̀,
Mening dua-tilawitim bolsa, silǝrning muⱨǝbbitinglarning ⱨǝrtǝrǝplimǝ bilim wǝ ǝtrapliⱪ sawat bilǝn yorutulup tehimu exip taxⱪayki,
10 kí ẹ̀yin kí ó lè ní òye ohun tí ó dára jùlọ; kí ó sì jásí òdodo àti aláìjẹ́ ohun ìkọ̀sẹ̀ títí di ọjọ́ dídé Jesu Kristi,
silǝr nemǝ ixlarning ǝwzǝl ikǝnlikini pǝrⱪ etǝlǝydiƣan bolup, Mǝsiⱨning künidǝ pak-diyanǝtlik, ǝyibsiz bolisilǝr
11 lẹ́yìn ìgbà ti ẹ ti kún fún àwọn ìwà òdodo láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, fún ògo àti ìyìn Ọlọ́run.
ⱨǝmdǝ Əysa Mǝsiⱨ arⱪiliⱪ bolƣan, Hudaning xan-xǝripi ⱨǝm mǝdⱨiyisini elip kelidiƣan ⱨǝⱪⱪaniyliⱪning mewisi bilǝn toldurulisilǝr.
12 Ǹjẹ́ èmi fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó mọ̀, ará, pé ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí mi jásí àtẹ̀gùn sí ìlọsíwájú ìyìnrere.
Biraⱪ silǝrgǝ xuni hǝwǝrlǝndürmǝkqimǝnki, i ⱪerindaxlar, mening bu ǝⱨwalim ǝmǝliyǝttǝ hux hǝwǝrning tehimu kǝng tarⱪilixi üqün türtkǝ boldi;
13 Nítorí ìdí èyí, ó ti hàn gbangba sí gbogbo àwọn ẹ̀ṣọ́ ààfin àti sí àwọn ẹlòmíràn wí pé mo wà nínú ìdè fún Kristi.
Qünki mening ⱪamilixim Mǝsiⱨ üqün ikǝnliki imperator ordisidiki ⱪarawulhanidikilǝrgǝ wǝ baxⱪa ⱨǝmmǝylǝngǝ ayan boldi.
14 Nítorí ìdè mi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ará nínú Olúwa ni a ti mú lọ́kàn le láti sọ̀rọ̀ Ọlọ́run sí i pẹ̀lú ìgboyà àti láìbẹ̀rù.
Xuning bilǝn ⱪerindaxlarning kɵpinqisi mening ⱪamilixim tüpǝylidin Rǝbgǝ tayinip [Hudaning] sɵz-kalamini ⱪorⱪmay sɵzlǝxkǝ tehimu jür’ǝtlik boldi;
15 Òtítọ́ ni pé àwọn ẹlòmíràn tilẹ̀ ń fi ìjà àti ìlara wàásù Kristi, ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn sì ń fi inú rere ṣe é.
dǝrwǝⱪǝ, bǝziliri ⱨǝsǝt ⱪilip yaki riⱪabǝtlixip, bǝziliri aⱪ kɵngüllük bilǝn Mǝsiⱨni jakarlaydu;
16 Àwọn kan ń fi ìjà wàásù Kristi, kì í ṣe pẹ̀lú òtítọ́ inú, wọ́n ń gbèrò láti fi ìpọ́njú kún ìdè mi.
keyinkiliri bolsa bǝrⱨǝⱪ muⱨǝbbǝttin, mening hux hǝwǝrni aⱪlap ispatlixim üqün muxu yǝrgǝ ⱪoyulƣanliⱪimni bilgǝnlikidin xundaⱪ ⱪilmaⱪta;
17 Àwọn kan ẹ̀wẹ̀ si ń fi ìfẹ́ ṣe é, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé a gbé mi dìde láti dá ààbò bo iṣẹ́ ìyìnrere.
Aldinⱪiliri bolsa qin kɵnglidin ǝmǝs, bǝlki xǝhsiyǝtqilikidin, mening zǝnjirlǝngǝn dǝrdimgǝ dǝrd ⱪoxmaⱪqi bolup xundaⱪ ⱪilmaⱪta.
18 Kí ló tún kù? Kìkì í pé níbi gbogbo, ìbá à ní ìfẹ̀tànṣe tàbí ni ti òtítọ́ a sá à n wàásù Kristi, èmi sì ń yọ̀ nítorí èyí. Nítòótọ́, èmi ó sì máa yọ̀,
Əmdi bularƣa nemǝ degülük? Ⱪandaⱪla bolmisun, toƣra niyǝttin bolsun sahtiliⱪtin bolsun, ohxaxla Mǝsiⱨ jakarlinidu; mǝn xuningƣa xadlinimǝn; bǝrⱨǝⱪ, dawamliⱪ xadliniwerimǝn.
19 nítorí tí mo mọ̀ pé èyí ni yóò yọrí sí ìgbàlà fún mi láti inú àdúrà yín wá, àti ìfikún ẹ̀mí Jesu Kristi.
Qünki dualiringlar wǝ Mǝsiⱨ Əysaning Roⱨining ⱪuwwǝtlixi arⱪiliⱪ bu ixlar nijat-ⱪutⱪuzuluxumƣa mǝdǝt bolidu dǝp bilimǝn,
20 Gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn àti ìrètí mi pé kí ojú kí ó má ṣe ti mi ní ohunkóhun, ṣùgbọ́n kí èmi kí ó le máa ni ìgboyà ní ìgbà gbogbo àti nísinsin yìí, kí a lè ti ipasẹ̀ mi gbé Kristi ga lára mi, ìbá à ṣe pé mo wà láààyè, tàbí mo kú.
— demǝk, tǝⱪǝzzaliⱪim wǝ ümid-istikim boyiqǝ ⱨeq ixta hijalǝtqiliktǝ ⱪalmastin, tirik yaki ɵlük bolay, ⱨǝrdaim bolƣinidǝk ⱨazirmu toluⱪ jasarǝt bilǝn Mǝsiⱨ tenimdǝ uluƣlansun!
21 Nítorí, ní ti èmi, láti wa láààyè jẹ́ Kristi, láti kú pẹ̀lú sì jẹ́ èrè fún mi.
Qünki manga nisbǝtǝn ⱨayatimning ɵzi Mǝsiⱨdur, ɵlüx bolsa tehimu paydiliⱪtur.
22 Ṣùgbọ́n bí èmi bá le è ṣe iṣẹ́ ti ó ni àpẹẹrẹ nípa wíwà láààyè nínú ara, ṣùgbọ́n ohun ti èmi ó yàn, èmi kò mọ̀.
Jenim tenimdǝ ⱪalsa, ǝmdi nesiwǝm yǝnǝ mewilik hizmǝt bolidu; lekin ⱪaysisini ǝwzǝl bilip talliweliximni bilmǝywatimǝn;
23 Ṣùgbọ́n èmi n ṣiyèméjì, nítorí ti èmi fẹ́ láti lọ kúrò nínú ayé yìí, láti wà lọ́dọ̀ Kristi; nítorí ó dára púpọ̀ jù:
mǝn ⱨayat bilǝn mamat otturisida ⱪisilip ⱪaldim; qünki bu dunyadin ayrilip, Mǝsiⱨ bilǝn billǝ boluxⱪa intizarmǝn — bu ix ziyadǝ ǝwzǝldur;
24 síbẹ̀ láti wà láààyè jẹ́ àǹfààní nítorí tiyín.
ǝmma silǝr üqün jenimning tenimdǝ ⱪelixi tehimu zɵrürƣu dǝymǝn.
25 Bí èyí sì ti dá mi lójú, mo mọ̀ pé èmi ó dúró, èmi ó sì máa wà pẹ̀lú yín fún ìtẹ̀síwájú àti ayọ̀ yín nínú ìgbàgbọ́,
Əmdi buningƣa ixǝnqim kamil bolup, silǝrning etiⱪadta alƣa ilgirilixinglar ⱨǝm xad-huram boluxunglar üqün mǝn silǝr bilǝn billǝ ⱪelip dawamliⱪ turimǝn dǝp bilimǝn;
26 kí ìṣògo yín kí ó lè di púpọ̀ gidigidi nínú Jesu Kristi, àti nínú mi nípa ìpadà wá mi sọ́dọ̀ yín.
xuning bilǝn mening silǝrgǝ yǝnǝ ⱨǝmraⱨ bolƣinim wǝjidin mǝn arⱪiliⱪ Mǝsiⱨ Əysada pǝhirlinip tǝntǝnǝ ⱪilixinglar tehimu ziyadilixidu!
27 Ohun yówù kó ṣẹlẹ̀, ẹ jẹ́ kí ìgbé ayé yín ri gẹ́gẹ́ bí ìyìnrere Kristi: pé yálà bi mo tilẹ̀ wá wò yín, tàbí bí èmi kò wá, kí èmi kí ó lè máa gbúròó bí ẹ ti ń ṣe, pé ẹ̀yin dúró ṣinṣin nínú Ẹ̀mí kan, ẹ̀yin jùmọ̀ jìjàkadì nítorí ìgbàgbọ́ ìyìnrere, pẹ̀lú ọkàn kan.
Pǝⱪǝt ɵzünglarni Mǝsiⱨning hux hǝwirigǝ layiⱪ tutunglarki, mǝn yeninglarƣa berip silǝr bilǝn didarlaxⱪandimu, silǝrdin ayrilƣandimu, ixliringlardin anglaydiƣinim silǝrning bir roⱨ bir janda bolup qing dǝssǝp turup, hux hǝwǝrdiki etiⱪadning yolida kürǝxkǝ intiliwatⱪininglar,
28 Kí ẹ má sì jẹ́ ki àwọn ọ̀tá dẹ́rùbà yin ni ohunkóhun: èyí tí í ṣe àmì tí ó dájú pé a ó pa wọ́n run, ṣùgbọ́n Ọlọ́run tìkára rẹ̀ ni yóò gbà yin là.
xundaⱪla ⱪarxi qiⱪⱪuqilarning ⱨeqⱪandaⱪ wǝⱨimiliridin patiparaⱪ bolup kǝtmigininglar bolsun; silǝrdiki bu ƣǝyrǝt, ularƣa ⱨalakǝtning bǝlgisi, silǝrgǝ bolsa ⱪutⱪuzuluxunglarning alamiti, xuningdǝk alayitǝn Hudadin kǝlgǝn bir alamǝttur;
29 Nítorí tí a ti fún yin ni àǹfààní, kì í ṣe láti gba Kristi gbọ́ nìkan, ṣùgbọ́n láti jìyà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú.
Qünki Mǝsiⱨning yolida silǝrgǝ pǝⱪǝt Uningƣa ixinixnila ǝmǝs, yǝnǝ Uning üqün horluⱪⱪa uqraxmu nesiwǝ ⱪilinƣandur.
30 Ẹ sì máa ja ìjà kan náà, èyí ti ẹ̀yin ti ri, ti ẹ sì ti gbọ́ pé èmi n jà pẹ̀lú.
Qünki silǝr ilgiri mǝndǝ kɵrgininglardǝk wǝ xuningdǝk ⱨazir angliƣininglardǝk mǝn yoluⱪⱪan kürǝxkǝ silǝrmu yoluⱪmaⱪtisilǝr.