< Philemon 1 >
1 Èmi Paulu, ẹni tí a fi sẹ́wọ̀n nítorí pé ó ń wàásù ìyìnrere Jesu Kristi àti Timotiu arákùnrin wa, Sí Filemoni ọ̀rẹ́ wa ọ̀wọ́n àti alábáṣiṣẹ́ wa,
Khritaw Jesuha phäh thawng üng kyumki Pawluh ja mi bena Timoti üngkhyüh — Kami nglawipüi ja khut kami bi püi Philimon ja
2 sí Affia arábìnrin wa, sí Arkippu ẹni tó jẹ́ jagunjagun fún àgbélébùú náà àti sí ìjọ àwọn Kristiani tí ó ń pàdé nínú ilé rẹ:
na ima ngkhämkia sangcim ja mi ci Apphia ja ngtuk mi pawh püi Akhipaha veia ni:
3 Oore-ọ̀fẹ́ fún un yín àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa àti Jesu Kristi.
Mi Pa Pamhnam ja Bawipa Jesuh Khritaw naw bäkhäknak ja dimdeihnak ning pe se.
4 Èmi máa ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nígbà tí mo bá rántí rẹ nínú àdúrà mi,
Ka na Philimon naw ka ktaiyüa kcün naküt üng nang ning süm lü Pamhnam veia jenak ka mthehki.
5 nítorí mo ń gbọ́ nípa ìgbàgbọ́ rẹ nínú Jesu Olúwa àti nípa ìfẹ́ rẹ sí àwọn ènìyàn mímọ́.
Pamhnama khyange na jah mhläkphyanak ja Bawi Jesuh üng na taka jumnak ka ngjaka phäh ni.
6 Èmi ń gbàdúrà pé, bí ìwọ ti ń ṣe alábápín nínú ìgbàgbọ́ rẹ pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn, pé kí ìgbàgbọ́ náà lè mú ọkàn wọn dúró gbọingbọin, gẹ́gẹ́ bí wọn ti rí àwọn ọ̀rọ̀ ohun rere tí ó ń bẹ nínú ayé rẹ, èyí tí ó ti ọ̀dọ̀ Kristi wá.
Ka ktaiyünak ta mi ngkhawteinak üng jumeikia mi kya akba, Khritaw am mi yümmatnak üng vekia dawkyanak naküt cun akdaw mi ksingnak däm däm vaia kyaki.
7 Ìfẹ́ rẹ ti fún mi ní ayọ̀ púpọ̀ àti ìgboyà, nítorí ìwọ, arákùnrin ti tu ọkàn àwọn ènìyàn mímọ́ lára.
Ka na aw, na mhläkphyanak naw na jekyaisak lü ngjuktha na pe ve! Nang naw Pamhnama khyangea mlung jah suhne veki.
8 Nítorí náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nínú Kristi mo ní ìgboyà púpọ̀ láti pàṣẹ ohun ti ó yẹ kí ó ṣe fún ọ,
Ahina phäha Khritaw üng ka ning na akba kei naw yet lü i pawh vai ti hin ngthu ning mtheh veng.
9 síbẹ̀ nítorí ìfẹ́ èmí kúkú bẹ̀ ọ́. Èmi gẹ́gẹ́ bí Paulu, arúgbó, àti nísinsin yìí òǹdè Jesu Kristi.
Isetiakyaküng ning kphya na lü ka ning nghuinak ni. Khritaw Jesuha ngsä, ania phäha tuha kcün üng thawng kyum kei Pawluh naw ka pawh ni.
10 Èmí bẹ̀ ọ́ nítorí ọmọ mi Onesimu, ẹni tí ó di ọmọ nígbà tí mo wà nínú ìdè.
Khritaw üng ka ca, thawng üng ka kyum k'um üng ngmüimkhya lama a na pa naw Onesimasa kcaha ning nghui na veng.
11 Nígbà kan rí, kò wúlò fún ọ, ṣùgbọ́n ní báyìí, ó ti wúlò fún ọ àti fún èmi pàápàá.
Ahlana ani cun ia am ngtäh lüpi atuha nang ja keia phäh ani cun summang vai kya ve.
12 Èmi rán an nísinsin yìí, àní ẹni ọkàn mi padà sí ọ̀dọ̀ rẹ.
Ani am ka mlung ngpüi law lü na veia ka tüih law be ni.
13 Èmi ìbá fẹ́ láti dá a dúró sọ́dọ̀ mi níhìn-ín, kí ó ba à dípò rẹ láti máa ràn mí lọ́wọ́ nígbà tí mo wà nínú ìdè nítorí ìyìnrere
Thangkdawa phäh thawng üng ka kyum üng nanga kcaha na kuei khaia ka hlawnga a ve vai ka täng kyaw.
14 ṣùgbọ́n èmi kò fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀ rárá láìgba ìyọ̀ǹda ní ọwọ́ rẹ, kí oore tí ìwọ bá ṣe má ba à jẹ́ ìfipámúniṣe bí kò ṣe ìfìfẹ́ṣe.
Acunsepi, na na kuei vaia käh ka ning sihling na khai, acuna kthaka na titänga na bilawh vai ni ka täng ve. Nang naw am ä xaki lü i pi am pawh veng.
15 Bóyá ìdí rẹ̀ tí òun fi yẹra kúrò lọ́dọ̀ rẹ fún ìgbà díẹ̀ ni pé kí ìwọ kí ó lè gbà á padà sọ́dọ̀ títí láé. (aiōnios )
Onesimas cun nang üngkhyüh asäng thuk lü a ve hin na hlawnga akcün tä a ve vaia phäh ni. (aiōnios )
16 Kì í wá ṣe bí ẹrú mọ́, ṣùgbọ́n bí ẹni ti ó sàn ju ẹrú lọ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin. Ó ṣọ̀wọ́n fún mi jọjọ, ṣùgbọ́n ó ṣọ̀wọ́n fún ọ jù nípa ti ara àti gẹ́gẹ́ bí arákùnrin nínú Olúwa.
Atuha mpya sawxata am kya lü mpyaa kthak dawki Khritaw üng na mhlänaka na naa kyaki ni. Ani cun keia phäh aktäa daw ve! Nanga phäh pi aktäa daw khai ni. Ani cun mpya ja Bawipa üng na na akba salü daw bawk khai ni!
17 Nítorí náà bí ìwọ bá kà mí sí ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, tẹ́wọ́ gbà á bí ìwọ yóò ti tẹ́wọ́ gbà mí.
Acunakyase, na na püia na ngaih üngta, kei na na dokhama mäiha ani pi dokham bea.
18 Bí ó bá ti ṣe ọ́ ní ibi kan tàbí jẹ ọ́ ní gbèsè ohun kan, kà á sí mi lọ́rùn.
Ani naw a ning thung vai am ani üng a ning mkhyenak üngpi ka ning thung vai ta kawm pi.
19 Èmi Paulu, ni mo fi ọwọ́ ara mi kọ ìwé yìí; èmi yóò san án padà láì tilẹ̀ ní í sọ nípa pé ìwọ pàápàá jẹ mi ní gbèsè ara rẹ.
Kei Pawluh naw ka ning thungkhih khai ti lü ka kut ye am ka yuk law ni: (na sak phäh na je na bä ka ning mtheh vai am hlü khai ni.)
20 Èmi ń fẹ́ arákùnrin, pé kí èmi kí ó lè ni àǹfààní kan láti ọ̀dọ̀ rẹ nínú Olúwa; fi ayọ̀ rẹ kún ọkàn mi nínú Kristi.
Acunakyase, ka na aw, Khritaw üng na bea kba na jesak lü Bawipa phäha ka hmai bük lü ahin hin keia khana pawha.
21 Ìgbẹ́kẹ̀lé ti mo ní pé ìwọ yóò gbọ́rọ̀, ni mo fi kọ ìwé yìí ránṣẹ́ sí ọ. Mo mọ̀ dájú pé ìwọ yóò ṣe ju bí mo ti béèrè lọ.
Ahin ka yuk lawa kba na pawh khaia ka ksingki, ahina kthaka pi na pawh khai tia ka ksingki ni.
22 Ó ku ohun kan, ṣe ìtọ́jú iyàrá àlejò rẹ sílẹ̀ fún mi, nítorí mo ní ìgbàgbọ́ pé a óò tú mi sílẹ̀ fún yín ní ìdáhùn sí àdúrà yín.
Acuna thea, keia phäh akhan na tak pet bä, isetiakyaküng, Pamhnam naw nami vana ktaiyünak ning jah msak lü na veia ka lawnak vai na pe khai tia ka äpeiki ni.
23 Epafira, òǹdè ẹlẹgbẹ́ mi nínú Kristi Jesu kí ọ.
Jesuh Khritawa phäh thawng üng ka kyum püi Epapharah naw ning jah hnukset ve,
24 Marku kí ọ pẹ̀lú Aristarku, Dema àti Luku, àwọn alábáṣiṣẹ́ mi.
khut ka bipüie Makuh, Aristakhas, Demah ja Luhka naw pi ning hnukset ve u.
25 Kí oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa wà pẹ̀lú ẹ̀mí yín.
Bawipa Jesuh Khritawa bäkhäknak nami vana khana ve se.