< Obadiah 1 >

1 Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
Ovadya'nın görümü. Egemen RAB'bin Edom için söyledikleri: RAB'den bir haber aldık: Uluslara gönderdiği haberci, “Gelin, Edom'la savaşalım!” diyor.
2 “Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Edom'a, “Bak, seni uluslar arasında küçük düşüreceğim, Herkes seni hor görecek” diyor.
3 Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
“Kaya kovuklarında yaşayan, Evini yükseklerde kuran sen! Yüreğindeki gurur seni aldattı. İçinden, ‘Beni kim yere indirebilir?’ diyorsun.
4 Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
Kartal gibi yükselsen de, Yuvanı yıldızlar arasında kursan da, Oradan indireceğim seni” diyor RAB.
5 “Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
“Hırsızlar ya da haydutlar gece sana gelselerdi, Yalnızca gereksindiklerini çalmazlar mıydı? Üzüm toplayanlar bağına girseydi, Birkaç salkım bırakmazlar mıydı? Ama seni ne felaketler bekliyor;
6 Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
Esav'ın her şeyi yağmalanacak, Gizli hazineleri ortaya çıkarılacak.
7 Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
Seninle antlaşma yapanların hepsi Seni toprağından sürecek. Güvendiğin insanlar Seni aldatıp yenilgiye uğratacak, Ekmeğini yiyenler sana tuzak kuracak Ve sen farkına varmayacaksın bile.”
8 Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
RAB diyor ki, “O gün Edom'un bilge adamlarını, Esav'ın dağlarındaki bilgiçleri yok edeceğim.
9 A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
Ey Teman, yiğitlerin öyle bir korkuya kapılacak ki, Esav'ın dağlarında bulunanların hepsi Kıyıma uğrayıp yok olacak.
10 Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
“Yakup soyundan gelen kardeşlerine Yaptığın zorbalıktan ötürü utanca boğulacak Ve sonsuza dek yok olacaksın.
11 Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
Çünkü yabancılar onların malını mülkünü yağmaladıkları gün Uzakta durup seyrettin. Öteki uluslar kapılarından içeri girip Yeruşalim için kura çektiklerinde Sen de onlardan biri gibi davrandın.
12 Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Yahudalı kardeşlerinin o kötü gününden Zevk almamalıydın. Başlarına gelen yıkıma sevinmemeli, Sıkıntılı günlerinde onlarla alay etmemeliydin.
13 Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
Halkım felakete uğradığı gün Kente girmemeliydin, O gün halkımın uğradığı kötülükten zevk almamalı, Malını mülkünü ele geçirmeye kalkmamalıydın.
14 Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Kaçmaya çalışanları öldürmek için Yol ağzında durmamalı, O sıkıntılı günde kurtulanları Düşmana teslim etmemeliydin.”
15 “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
“RAB'bin bütün ulusları yargılayacağı gün yaklaştı. Ey Edom, ne yaptıysan sana da aynısı yapılacak. Yaptıkların kendi başına gelecek.
16 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
Ey Yahudalılar, kutsal dağımda nasıl içtiyseniz, Bütün uluslar da öyle içecekler. İçip içip yok olacaklar, Hiç var olmamış gibi.”
17 Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
“Ama kurtulanlar Siyon Dağı'nda toplanacak Ve orası kutsal olacak. Yakup soyu da mirasına kavuşacak.
18 Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
Yakup soyu ateş, Yusuf soyu alev, Esav soyu anız olacak. Onları yakıp yok edecekler. Esav soyundan kurtulan olmayacak.” RAB böyle diyor.
19 Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
Yahudalılar'dan Negev halkı Esav'ın dağlarını; Şefela halkı Filist bölgesini; Yahudalılar'ın tümü Efrayim ve Samiriye topraklarını; Benyaminliler Gilat'ı mülk edinecekler.
20 Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
Kenan'dan sürülmüş olan İsrailli savaşçılar Sarefat'a kadar uzanan toprakları, Sefarat'taki Yeruşalimli sürgünler de Negev'deki kentleri mülk edinecekler.
21 Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.
Halkı kurtaranlar Esav'ın dağlarını yönetimleri altına almak için Siyon Dağı'na çıkacaklar ve egemenlik RAB'bin olacak.

< Obadiah 1 >