< Obadiah 1 >

1 Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
Umbono kaObhadiya. Itsho njalo iNkosi uJehova mayelana leEdoma: Sizwile umbiko ovela eNkosini, njalo kuthunywe isithunywa phakathi kwezizwe: Sukumani, kasimvukele empini!
2 “Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Khangela, ngikwenze waba mncinyane phakathi kwezizwe, udelelwe kakhulu.
3 Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
Ukuziqhenya kwenhliziyo yakho kukukhohlisile, wena ohlala ezingoxweni zamadwala, ondawo yakhe yokuhlala iphakeme, othi enhliziyweni yakhe: Ngubani ozangehlisela emhlabathini?
4 Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
Loba uphakeme njengokhozi, njalo loba ubeka isidleke sakho phakathi kwezinkanyezi, ngizakwethula khona, itsho iNkosi.
5 “Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
Uba amasela efika kuwe, loba abaphangi ebusuku (uqunywe kangakanani!) bebengayikuntshontsha baze banele yini? Uba abavuni bezithelo zevini bebengafika kuwe, bebengayikutshiya umkhothozo yini?
6 Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
Yeka ukuhlolwa kwezinto zikaEsawu, ukudingisiswa kokuligugu kwakhe okufihliweyo!
7 Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
Wonke amadoda esivumelwano sakho akuthumele emngceleni; amadoda okuthula kwakho akukhohlisile, akwehlule, adla isinkwa sakho abeke imbule ngaphansi kwakho; kakukho ukuqedisisa kuye.
8 Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
Kakuyikuba njalo yini ngalolosuku, itsho iNkosi, ukuthi ngizachitha abahlakaniphileyo eEdoma lokuqedisisa entabeni kaEsawu.
9 A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
Lamaqhawe akho azatshaywa luvalo, Themani, ukuze ngulowo lalowo aqunywe entabeni kaEsawu ngokubulawa.
10 Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
Ngenxa yodlakela lwakho umelene lomfowenu uJakobe inhloni zizakusibekela, uqunywe kuze kube phakade.
11 Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
Ngosuku owema ngalo uqondene labo, ngosuku abezizweni abathumba ngalo amabutho akhe, abezizwe abangena emasangweni akhe, abenza inkatho yokuphosa ngeJerusalema, lawe wawunjengomunye wabo.
12 Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Kodwa wawungafanelanga ukukhangela ngosuku lomfowenu ngosuku lwenhlupheko yakhe; njalo wawungafanelanga uthokoze ngabantwana bakoJuda ngosuku lokuchitheka kwabo; njalo wawungafanelanga ukhulume ngokuziqhenya ngosuku lokuhlupheka.
13 Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
Ngabe kawungenanga ngesango labantu bami osukwini lwenhlupheko yabo; ngabe kawukhangelanga, lawe, ebubini babo osukwini lwenhlupheko yabo; njalo ngabe kawelulelanga isandla sakho enothweni yabo osukwini lwenhlupheko yabo.
14 Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Ngabe kawumanga emehlukanweni endlela ukuquma abaphunyukayo bakhe; njalo ngabe kawunikelanga abasalayo bakhe osukwini losizi.
15 “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
Ngoba usuku lweNkosi lusondele ezizweni zonke. Njengokwenza kwakho kuzakwenziwa kuwe; umvuzo wakho uzabuyela ekhanda lakho.
16 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
Ngoba njengoba linathile entabeni yami engcwele, ngokunjalo zonke izizwe zizanatha njalonjalo, yebo, zizanatha, ziginye, zibe kungathi kazizanga zibe khona.
17 Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
Kodwa entabeni yeZiyoni kuzakuba khona ukuphunyuka, kube lobungcwele; lendlu kaJakobe izakudla ilifa lamafa ayo.
18 Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
Lendlu kaJakobe izakuba ngumlilo, lendlu kaJosefa ibe lilangabi, lendlu kaEsawu ibe libibi; njalo bazazitshisa bazidle; njalo kakuyikuba khona oseleyo endlini kaEsawu; ngoba iNkosi ikhulumile.
19 Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
Labeningizimu bazakudla ilifa lentaba kaEsawu, lalabo abemagcekeni amaFilisti, yebo bazakudla ilifa lensimu yakoEfrayimi lensimu yeSamariya, loBhenjamini iGileyadi.
20 Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
Labathunjiweyo bale inqaba yabantwana bakoIsrayeli bazakudla ilifa elalingelamaKhanani, kuze kufike eZarefathi; labathunjiweyo beJerusalema abaseSefaredi bazakudla ilifa lemizi yeningizimu.
21 Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.
Labasindisi bakhwele entabeni yeZiyoni ukwahlulela intaba kaEsawu; lombuso uzakuba ngoweNkosi.

< Obadiah 1 >