< Obadiah 1 >
1 Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
Kĩoneki kĩa Obadia. Mwathani Jehova ekuuga ũũ ũhoro ũkoniĩ Edomu: Nĩtũiguĩte ũhoro uumĩte kũrĩ Jehova. Mũtũmwo nĩatũmirwo kũrĩ ndũrĩrĩ oige atĩrĩ, “Arahũkai, tũthiĩ tũmũũkĩrĩre, tũrũe nake”:
2 “Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
“Atĩrĩrĩ, nĩngakũnyiihia maitho-inĩ ma ndũrĩrĩ; nawe nĩũkameneka biũ.
3 Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
Mwĩtĩĩo wa ngoro yaku nĩũkũheenetie, wee ũtũũraga kũu ngurunga-inĩ cia mahiga, na ũgathondeka gĩikaro gĩaku kũrĩa gũtũũgĩru, o wee wĩĩraga na ngoro atĩrĩ, ‘Nũũ ũngĩhota kũũharũrũkia andehe nginya thĩ?’
4 Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
O na ũngĩkorwo ũmbũkaga na igũrũ ta nderi, na ũgaaka gĩtara gĩaku o kũu njata irĩ, nĩngakũharũrũkia thĩ ngũrute kuo,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
5 “Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
“Ũngĩkorwo nĩ aici, o na kana ũkorwo nĩ atunyani ũtukũ-rĩ, kaĩ mwanangĩko nĩũgwetereire-ĩ! Githĩ matingĩiya o nginya maiganie? Atui a thabibũ mangĩũka gwaku-rĩ, githĩ to matigie tũthabibũ tũnini tũngĩhaarwo?
6 Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
No kaĩ Esaũ nĩakongũrũrio-ĩ, nakĩo kĩgĩĩna gĩake kĩrĩa kĩhithe gĩgĩtahwo-ĩ!
7 Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
Andũ othe arĩa mũgwatanagĩra nao nĩmagakũingata nginya mũhaka-inĩ; arata aku nĩmagakũheenia na magũtoorie; arĩa marĩĩaga irio ciaku nĩmagakũigĩra mũtego, no wee ndũkamenya.”
8 Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
Jehova ekuuga atĩrĩ, “Githĩ mũthenya ũcio ndikaananga andũ arĩa oogĩ a Edomu, na nyanange andũ arĩa marĩ ũmenyo kũu irĩma-inĩ cia Esaũ?
9 A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
Atĩrĩrĩ, wee Temani, njamba ciaku cia ita nĩikaamaka, na andũ othe arĩa matũũraga irĩma-inĩ cia Esaũ mooragwo, maniinwo.
10 Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
Nĩ ũndũ wa ngũĩ ya gũũkĩrĩra mũrũ wa nyũkwa Jakubu, nĩũgaconorithio; nĩũkaniinwo nginya tene.
11 Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
Mũthenya ũrĩa wamũtiganĩirie, rĩrĩa andũ a kũngĩ maatahire ũtonga wake, nao ageni magĩtoonyera ihingo-inĩ ciake, na magĩcuukĩra Jerusalemu mĩtĩ-rĩ, we watariĩ o ta ũmwe wao.
12 Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
No wee ndũngĩanyararire mũrũ wa nyũkwa mũthenya wake wa mũtino, kana ũkenerere andũ a Juda mũthenya ũrĩa maaniinagwo, o na kana wĩtĩĩe mũno mũthenya ũrĩa maarĩ na thĩĩna.
13 Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
Wee ndũngĩatuĩkanĩirie ihingo-inĩ cia andũ akwa mũthenya wao wa mwanangĩko, kana ũmanyarare hĩndĩ ĩrĩa maarĩ na mũnyarirĩko mũthenya wao wa kwanangwo, kana ũtahe ũtonga wao mũthenya ũcio wa mwanangĩko.
14 Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Wee ndwagĩrĩirwo kũmooheria magomano-inĩ ma njĩra nĩguo ũũrage arĩa mooraga, kana ũneane matigari mao mũthenya ũcio maarĩ na thĩĩna.
15 “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
“Mũthenya wa Jehova ũrĩ hakuhĩ gũkinyĩra ndũrĩrĩ ciothe. O ũrĩa wĩkĩte, noguo nawe ũgeekwo; ciĩko ciaku nĩigagũcookerera.
16 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
O ta ũrĩa inyuĩ mwanyuĩrĩire gĩkombe gĩakwa kĩa iherithia kũu kĩrĩma-inĩ gĩakwa gĩtheru-rĩ, ũguo noguo ndũrĩrĩ ciothe igaakĩnyuĩra itegũtigithĩria. Ikaanyua ikĩhũhũte, ininũkio, nacio ihaane ta itarĩ ciakorwo kuo.
17 Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
No rĩrĩ, kũu Kĩrĩma-inĩ gĩa Zayuni nĩgũgakorwo na ũhonokio; nakĩo kĩrĩma kĩu gĩgaakorwo kĩrĩ gĩtheru, nayo nyũmba ya Jakubu nĩĩkegwatĩra igai rĩayo.
18 Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
Nyũmba ya Jakubu ĩgaatuĩka ta mwaki, nayo nyũmba ya Jusufu ĩtuĩke ta rũrĩrĩmbĩ; nayo nyũmba ya Esaũ ĩgaatuĩka ta maragara ma mahuti, na nĩmakamĩmundia mwaki, ũmĩniine biũ. Gũtirĩ mũndũ ũgaatigara wa kuuma nyũmba ya Esaũ.” Jehova nĩwe uugĩte ũguo.
19 Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
Andũ a Negevu nĩmagaikara irĩma-inĩ cia Esaũ, nao andũ arĩa maikaraga magũrũ-inĩ ma tũrĩma megwatĩre bũrũri wa Afilisti. Nĩmagaikara mĩgũnda-inĩ ya Efiraimu, na ya Samaria, nake Benjamini egwatĩre Gileadi.
20 Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
Gĩkundi kĩrĩa gĩatahĩtwo kĩa andũ a Isiraeli kĩrĩa kĩrĩ kũu Kaanani, gĩkeegwatĩra bũrũri ũcio o nginya Zarefathu; nao andũ arĩa maatahirwo kuuma Jerusalemu, acio marĩ kũu Sefaradi, nĩo makegwatĩra matũũra ma Negevu.
21 Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.
Andũ a kũhonokania nĩmakambata Kĩrĩma-inĩ gĩa Zayuni nĩguo maathanage kũu irĩma-inĩ cia Esaũ. Naguo ũthamaki ũgaatuĩka wa Jehova.