< Obadiah 1 >

1 Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
Vidění Abdiášovo. Takto praví Panovník Hospodin o zemi Idumejské: Pověst jsme slyšeli od Hospodina, a legáta k národům vyslaného: Nuže, povstaňmež k boji proti ní.
2 “Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Aj, způsobím to, abys byl nejšpatnější mezi národy, a abys byl v náramném pohrdání.
3 Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
Pýcha srdce tvého zklamá tě, ó ty, kterýž bydlíš v rozsedlinách skalních, v převysokém obydlí svém, říkaje v srdci svém: Kdož by mne strhl na zem?
4 Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
Bys pak vysoko udělal jako orlice, nýbrž bys mezi hvězdami položil hnízdo své, i odtud strhnu tě, praví Hospodin.
5 “Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
Kterak jsi popléněn? Zdali zloději přišli na tebe? Zdali loupežníci noční? Zdaliž by kradli přes spotřebu svou? Kdyby ti, kteříž zbírají víno, přišli na tebe, zdaž by nepozůstavili aspoň paběrků?
6 Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
Jakť jsou vystiženy věci Ezau, vyhledáni pokladové jeho!
7 Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
Až ku pomezí vystrčí tě všickni, s kterýmiž smlouvu máš; podvedou tě, zmocní se tebe ti, s nimiž pokoj máš; náchlebníci tvoji udělajíť ránu zrádně, již nebude lze vyrozuměti.
8 Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
Zdaliž v ten den, praví Hospodin, nevyhladím moudrých z země Idumejské, a rozumných s hory Ezau?
9 A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
I budou se děsiti udatní tvoji, ó Temane, proto, že poraženi jsouce, vypléněni budou všickni s hory Ezau.
10 Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
Pro nátisk bratru tvému Jákobovi činěný přikryje tě hanba, a vypléněn budeš na věčnost.
11 Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
Stál jsi v ten den naproti, a když zajímali cizí vojsko jeho, a když cizozemci vcházeli do bran jeho, a o Jeruzalém metali losy, ty jsi také byl jako jeden z nich.
12 Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Nedívejž se tedy na den bratra svého, na den zajetí jeho, aniž se vesel nad syny Judskými v den zahynutí jejich, aniž pyšně mluv ústy svými v den uzkosti.
13 Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
Nevcházej do brány lidu mého v den bídy jejich, aniž se dívej trápení jeho v den bídy jeho, a nechtěj sahati na statek jeho v den bídy jeho.
14 Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Aniž stůj při mezeře, abys hubil ty, kteříž z nich ucházejí, aniž vydávej nepříteli v moc těch, kteříž z nich pozůstali v den úzkosti.
15 “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
Nebo blízko jest den Hospodinův proti všechněm těm národům. Jakž jsi činil, tak se stane tobě, odplata tvá navrátí se na hlavu tvou.
16 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
Nebo poněvadž vy na mé hoře svaté píti bedete, nadtoť píti budou všickni národové ustavičně. Píti, pravím, a požírati budou, až budou, jako by jich nebylo.
17 Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
Na hoře pak Sion bude vysvobození, a bude svatá, a tak dědičně držeti bude dům Jákobův dědictví svá.
18 Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
I bude dům Jákobův oheň, a dům Jozefův plamen, dům pak Ezau plevy, i rozpálí se na ně a sehltí je, aniž kdo pozůstane z domu Ezau; nebo Hospodin mluvil.
19 Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
A tak děditi budou v krajině polední s horou Ezau, i v rovině s Filistinskými; vládnouti také budou krajinou Efraimovou i krajinou Samařskou, a Beniaminovou i Galádskou.
20 Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
I zajaté vojsko toto synů Izraelských v tom, což bylo Kananejských až do Sarepty, zajatí pak Jeruzalémští v tom, což jest na konci panství, děditi budou s městy na poledne.
21 Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.
I vstoupí vysvoboditelé na horu Sion, aby soudili horu Ezau, a tak bude Hospodinovo království.

< Obadiah 1 >