< Obadiah 1 >

1 Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
Widzenie Abdiasza. Tak mówi Pan BÓG o Edomie: Usłyszeliśmy wieść od PANA, a posłaniec został wysłany do narodów: Powstańcie, wyruszmy przeciwko niemu do bitwy.
2 “Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Oto uczyniłem cię małym wśród narodów, jesteś bardzo wzgardzony.
3 Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
Pycha twego serca zwiodła cię, ty, który mieszkasz w rozpadlinach skalnych, [masz] swoje mieszkanie na wysokości; [ty], który mówisz w swoim sercu: Któż mnie ściągnie na ziemię?
4 Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
Choćbyś wywyższył się jak orzeł, choćbyś założył swoje gniazdo wśród gwiazd, stamtąd cię strącę, mówi PAN.
5 “Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
Jakże jesteś zniszczony! Gdyby złodzieje przyszli do ciebie, gdyby rabusie [zjawili się] w nocy, czy nie kradliby [tyle, ile] potrzebują? Gdyby przyszli do ciebie zbieracze winogron, czy nie zostawiliby trochę winogron?
6 Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
Jakże przeszukane są skarby Ezawa, a przetrząśnięte jego skryte rzeczy!
7 Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
Aż do granicy wypchnęli cię wszyscy twoi sprzymierzeńcy. Ci, z którymi miałeś pokój, zdradzili cię i pokonali; ci, którzy [jedli] twój chleb, zranili cię zdradliwie. Nie ma zrozumienia u niego.
8 Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
Czyż w owym dniu – mówi PAN – nie wytracę mędrców z Edomu, a rozumu – z góry Ezawa?
9 A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
I tak się zlękną twoi mocarze, Temanie, że wszyscy z góry Ezawa zostaną wycięci.
10 Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
Z powodu przemocy wobec twego brata Jakuba okryje cię hańba i zostaniesz wykorzeniony na wieki.
11 Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
W dniu, gdy stałeś naprzeciwko, w dniu, gdy obcy brali do niewoli jego wojsko i gdy cudzoziemcy wchodzili w jego bramy i o Jerozolimę rzucali losy, to ty [byłeś] też jak jeden z nich.
12 Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Nie powinieneś był patrzeć na dzień swego brata, w dniu jego pojmania, ani cieszyć się z powodu synów Judy w dniu ich zniszczenia, ani mówić zuchwale w dniu ucisku.
13 Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
Nie powinieneś był wchodzić w bramę mojego ludu w dniu jego klęski ani patrzeć na jego nieszczęście w dniu jego klęski, ani wyciągać swej [ręki] po jego mienie w dniu jego klęski;
14 Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Nie powinieneś był stać na rozstaju dróg, aby wytracić tych, którzy uciekali, ani wydać tych, którzy pozostali spośród nich w dniu ucisku.
15 “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
Bliski bowiem [jest] dzień PANA dla wszystkich narodów. Jak ty postępowałeś, tak postąpią z tobą. Twoja odpłata spadnie na twoją głowę.
16 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
Bo jak wy piliście na mojej świętej górze, tak będą stale pić wszystkie narody; będą pić i pochłaniać, aż będzie z nimi tak, jakby ich [nigdy] nie było.
17 Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
A na górze Syjon będzie wybawienie i będzie ona święta, a dom Jakuba posiądzie swoje posiadłości.
18 Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
Dom Jakuba stanie się ogniem, a dom Józefa płomieniem, dom Ezawa zaś ścierniskiem. Podpalą go i strawią, i nikt nie pozostanie z domu Ezawa, bo PAN to powiedział.
19 Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
Ci z krainy południa odziedziczą górę Ezawa, ci z równiny – Filistynów. Posiądą też krainę Efraima i krainę Samarii, a Beniamin [posiądzie] Gilead.
20 Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
A wygnańcy tego wojska z synów Izraela [posiądą] to, co należało do Kananejczyków aż do Sarepty; wygnańcy zaś z Jerozolimy, którzy są w Sefarad, posiądą miasta na południu.
21 Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.
I wstąpią wybawiciele na górę Syjon, aby sądzić górę Ezawa. I królestwo będzie [należeć do] PANA.

< Obadiah 1 >