< Obadiah 1 >

1 Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
Ko te kite a Oparia. Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa, mo Eroma; Kua tae mai he korero i a Ihowa, kua oti ano he karere te unga ki nga tauiwi, hei mea, Whakatika, kia whakatika atu hoki tatou ki a ia ki te whawhai.
2 “Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Nana, kua oti koe te mea e ahau kia iti i roto i nga tauiwi: nui atu te whakahawea ki a koe.
3 Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
Kua oti koe te tinihanga e te whakapehapeha o tou ngakau, e koe e noho na i nga kapiti o te kamaka, kei runga na tona nohoanga; e mea na i roto i tona ngakau, Ko wai hei whakahoki iho i ahau ki raro ki te whenua?
4 Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
Ahakoa i rite tou kakenga ki to te ekara, ahakoa i hanga e koe tou kohanga ki nga whetu, ka whakahokia iho koe e ahau i reira, e ai ta Ihowa.
5 “Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
Me i tae he kaitahae ki a koe, he kaipahua ranei i te po, taukiri e, tou ngaromanga! e kore ranei ratou e tahae, kia maha ra ano nga mea ma ratou? me i tae he kaiwhawhaki karepe ki a koe, e kore ranei etahi karepe e whakatoea e ratou?
6 Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
Taukiri e, te rapunga atu o nga mea a Ehau! te kimihanga o ana mea ngaro!
7 Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
Ko nga tangata katoa o tau kawenata, kua riro koe i a ratou, tae rawa ki te rohe: ko nga tangata i mau nei ta ratou rongo ki a koe, kua tinihanga ki a koe, a taea ana koe e ratou; ko te hunga i kai i tau taro kua takoto i a ratou he mahanga ki ra ro i a koe: kahore he matauranga i a ia.
8 Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
He teka ianei, e ai ta Ihowa, ka kore i ahau i taua ra nga tangata whakaaro nui i roto i Eroma, me te matauranga o te maunga o Ehau?
9 A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
A ka wehi ou marohirohi, e Temana, he mea e hatepea atu ai nga tangata katoa o te maunga o Ehau, tukituki rawa.
10 Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
Ka taupokina koe e te whakama hei utu mo te mahi tutu ki tou teina, ki a Hakopa, ka hatepea atu ano koe a ake ake.
11 Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
I te ra i tu hangai mai ai koe, i te ra i whakaraua ai ona rawa e nga tautangata, i tapoko ai nga tangata iwi ke ki ona kuwaha, i kokiri nui ai mo Hiruharama, i rite rawa ano koe ki tetahi o ratou.
12 Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Otiia kaua koe e titiro ki te ra o tou teina, i te ra o tona aitua, kaua hoki koe e koa ki nga tama a Hura i te ra o to ratou whakangaromanga; kaua hoki e whakanuia tou mangai i te ra o te raru.
13 Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
Kaua e tomo ki roto ki te kuwaha o taku iwi i te ra o to ratou aitua; ae ra, kaua koe e matakitaki ki to ratou matenga i te ra o to ratou aitua, kaua ano hoki koutou e pa ringaringa ki o ratou rawa i te ra o to ratou raru.
14 Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
A kaua koe e tu ki te pekanga o te ara ki te hatepe i ona morehu e mawhiti; kaua hoki e tukua ona morehu i te ra o te raru.
15 “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
Kua tata hoki te ra o Ihowa ki nga tauiwi katoa; ka rite ki tau i mea ai ka meatia ki a koe; ka hoki tau utu ki runga ki tou mahunga.
16 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
Ka rite hoki ki ta koutou inumanga i runga i toku maunga tapu; ka pena ano te inu a nga tauiwi katoa a ake nei, ake nei; ina, ka inu ratou, ka horomia ano e ratou, a me te mea i kore ratou.
17 Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
Otiia tera ano nga mea ka mawhiti i Maunga Hiona, a ka tapu tera; a ka riro o ratou wahi i te whare o Hakopa.
18 Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
A hei ahi te whare o Hakopa, hei mura ano te whare o Hohepa, hei kakau witi hoki te whare o Ehau: ka ngiha ratou i roto i a ratou, a pau ake, kahore hoki he morehu o te whare o Ehau: na Ihowa nei hoki te kupu.
19 Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
Na ka riro te maunga o Ehau i te hunga o te tonga; me nga Pirihitini i te hunga o te mania; ka riro ano i a ratou nga mara a Eparaima me nga mara o Hamaria; mo Pineamine hoki a Kireara.
20 Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
Na, ko nga whakarau o tenei ope, o nga tama a Iharaira, ko era i roto i nga Kanaani, ka riro i a ratou tae noa ki Harepata; a, ko nga whakarau o Hiruharama, ko era i Teparara, ka riro i a ratou nga pa o te tonga.
21 Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.
A ka tae ake he kaiwhakaora ki Maunga Hiona hei whakawa mo te maunga o Ehau; a ka riro i a Ihowa te kingitanga.

< Obadiah 1 >