< Obadiah 1 >
1 Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
Obadias's Syn. Saa har den Herre, Herre sagt om Edom. Vi have hørt et Rygte fra Herren, og et Bud er sendt ud iblandt Folkene: Staar op, og lader os staa op imod det til Krig!
2 “Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Se, jeg har gjort dig liden iblandt Folkene, du er saare foragtet.
3 Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
Dit Hjertes Hovmod har bedraget dig, du, som bor i Klippekløfter, i din høje Bolig, du, som siger i dit Hjerte: Hvo vil kaste mig ned til Jorden?
4 Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
Om du end farer saa højt op som Ørnen, og om end din Rede er sat iblandt Stjernerne, vil jeg dog kaste dig ned derfra, siger Herren.
5 “Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
Hvis Tyve vare komne over dig, eller de, som anrette Ødelæggelse om Natten — ak, hvor er du dog tilintetgjort! — mon de da ikke vilde stjæle saa meget, som var dem nok? hvis Vinhøstere vare komne over dig, mon de da ikke vilde lade en Efterhøst blive tilovers?
6 Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
Hvor er dog Esau bleven gennemsøgt? hans skjulte Liggendefæ opsporet?
7 Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
Alle dine Forbundsfæller have ledsaget dig til Grænsen, de, som havde Fred med dig, have bedraget dig, de have faaet Overmagt over dig; dit Brød gøre de til en Byld under dig, — der er ingen Forstand i ham!
8 Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
Mon jeg ikke paa den Dag, siger Herren, skal lade de vise forsvinde fra Edom og Forstand fra Esaus Bjerg?
9 A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
Og dine vældige, o Theman! skulle lammes af Skræk, paa det enhver maa blive udryddet fra Esaus Bjerg ved Mord.
10 Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
For Vold imod din Broder Jakob skal Skam bedække dig, og du skal udryddes evindelig.
11 Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
Paa den Dag, da du stod lige overfor, paa den Dag, da fremmede bortførte hans Gods, og Udlændinge gik ind ad hans Porte og kastede Lod over Jerusalem, har ogsaa du været som en af dem.
12 Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Og se ej med Lyst paa din Broders Dag paa hans Ulykkesdag, og glæd dig ej over Judas Børn paa deres Undergangsdag; og tal ej hovmodigt med din Mund paa Trængselsdagen.
13 Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
Drag ej ind ad mit Folks Port paa deres Nøds Dag, se ej ogsaa du paa dets Ulykke paa dets Nøds Dag, og ræk ej efter dets Gode paa dets Nøds Dag!
14 Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
Og staa ej paa Vejskellet for at ødelægge dem, som ere undkomne derfra, og udlever ej de overblevne deraf paa Trængselsdagen!
15 “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
Thi Herrens Dag er nær over alle Hedningerne; ligesom du har gjort, skal dig ske; Gengældelsen skal komme over dit Hoved.
16 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
Thi ligesom I have drukket paa mit hellige Bjerg, saa skulle alle Hedningerne drikke stedse, ja, de skulle drikke og drikke ud og vorde som de, der ikke have været.
17 Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
Men paa Zions Bjerg skal der være nogle, som undkomme, og det skal være en Helligdom; og Jakobs Hus skal eje deres Ejendom.
18 Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
Og Jakobs Hus skal være en Ild og Josefs Hus en Lue, men Esaus Hus skal være til Halm, og hine skulle antænde disse og fortære dem; og der skal ingen overbleven være for Esaus Hus; thi Herren har talt det.
19 Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
Og de, som bo i Sydlandet, skulle eje Esaus Bjerg, og de, som bo i Lavlandet, skulle eje Filisterne, og de skulle eje Efraims Mark og Samarias Mark, og Benjamin skal eje Gilead.
20 Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
Og de bortførte af denne Hær af Israels Børn skulle eje det, som tilhører Kajaaniterne indtil Zarepta, og de bortførte af Jerusalem, som ere i Sefarad, de skulle eje Stæderne i Sydlandet.
21 Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.
Og Frelsere skulle drage op paa Zions Bjerg for at dømme Esaus Bjerg; og Riget skal høre Herren til.