< Numbers 1 >

1 Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní aginjù Sinai nínú àgọ́ àjọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì ní ọdún kejì tí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ó wí pé,
Yahweh falou a Moisés no deserto do Sinai, na Tenda da Reunião, no primeiro dia do segundo mês, no segundo ano depois de terem saído da terra do Egito, dizendo:
2 “Ka gbogbo àgbájọ ènìyàn Israẹli nípa ẹbí wọn, àti nípa ìdílé baba wọn, to orúkọ wọn olúkúlùkù ọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
“Faça um censo de toda a congregação dos filhos de Israel, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número dos nomes, cada homem, um por um,
3 Ìwọ àti Aaroni ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.
a partir de vinte anos de idade, todos os que são capazes de sair para a guerra em Israel. Você e Aarão os contarão por suas divisões.
4 Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láti inú olúkúlùkù ẹ̀yà kí ó sì wá pẹ̀lú yín, kí olúkúlùkù jẹ́ olórí ilé àwọn baba rẹ̀.
Contigo estará um homem de cada tribo, cada um dos chefes da casa de seus pais.
5 “Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí: “Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
Estes são os nomes dos homens que estarão com vocês: De Ruben: Elizur, o filho de Shedeur.
6 Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
De Simeon: Shelumiel, o filho de Zurishaddai.
7 Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
De Judah: Nahshon, o filho de Amminadab.
8 Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Suari.
De Issachar: Nethanel, o filho de Zuar.
9 Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni.
De Zebulun: Eliab, o filho de Helon.
10 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu: láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu. Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri.
Dos filhos de José: de Efraim: Elishama o filho de Ammihud; de Manasseh: Gamaliel, o filho de Pedahzur.
11 Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni.
De Benjamin: Abidan, o filho de Gideoni.
12 Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
De Dan: Ahiezer, o filho de Ammishaddai.
13 Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri.
De Asher: Pagiel, o filho de Ochran.
14 Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli.
De Gad: Eliasaph, o filho de Deuel.
15 Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”
De Naftali: Ahira, o filho de Enan”.
16 Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.
Estes são aqueles que foram chamados da congregação, os príncipes das tribos de seus pais; eles eram os chefes dos milhares de Israel.
17 Mose àti Aaroni mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí
Moisés e Aarão levaram estes homens que são mencionados pelo nome.
18 wọ́n sì pe gbogbo àwùjọ ènìyàn Israẹli jọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì. Àwọn ènìyàn sì dárúkọ baba ńlá wọn nípa ẹbí àti ìdílé wọn. Wọ́n sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọmọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan láti ọmọ ogún ọdún sókè,
Eles reuniram toda a congregação no primeiro dia do segundo mês; e declararam sua ascendência por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número dos nomes, a partir dos vinte anos de idade, um por um.
19 gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose. Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe kà wọ́n nínú aginjù Sinai.
Como Javé ordenou a Moisés, assim ele os contou no deserto do Sinai.
20 Láti ìran Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Israẹli, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn, lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Os filhos de Rúben, o primogênito de Israel, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, um por um, cada homem a partir de vinte anos de idade, todos os que puderam sair à guerra:
21 Àwọn tí a kà ní ẹ̀yà Reubeni jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
those que foram contados deles, da tribo de Rúben, eram quarenta e seis mil e quinhentos.
22 Láti ìran Simeoni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà, wọ́n sì to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de Simeão, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, aqueles que foram contados, de acordo com o número dos nomes, um por um, cada homem a partir de vinte anos, todos os que puderam sair à guerra:
23 Iye àwọn tí á kà nínú ẹ̀yà Simeoni jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
those que foram contados deles, da tribo de Simeão, eram cinqüenta e nove mil e trezentos.
24 Láti ìran Gadi, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de Gad, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, a partir de vinte anos, todos os que puderam sair para a guerra:
25 Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Gadi jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
those que foram contados deles, da tribo de Gad, eram quarenta e cinco mil seiscentos e cinqüenta.
26 Láti ìran Juda, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de Judá, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, a partir de vinte anos, todos os que puderam sair para a guerra:
27 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Juda jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
those que foram contados deles, da tribo de Judá, eram setenta e quatro mil e seiscentos.
28 Láti ìran Isakari, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de Issachar, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, a partir dos vinte anos de idade, todos os que puderam sair para a guerra:
29 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Isakari jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
those que foram contados deles, da tribo de Issachar, eram cinqüenta e quatro mil e quatrocentos.
30 Láti ìran Sebuluni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de Zebulun, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, a partir dos vinte anos de idade, todos os que puderam sair para a guerra:
31 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Sebuluni jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
those que foram contados deles, da tribo de Zebulom, eram cinqüenta e sete mil e quatrocentos.
32 Láti inú àwọn ọmọ Josẹfu. Láti ìran Efraimu, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de José: dos filhos de Efraim, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, a partir dos vinte anos de idade, todos os que puderam sair à guerra:
33 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Efraimu jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
those que foram contados deles, da tribo de Efraim, eram quarenta mil e quinhentos.
34 Láti ìran Manase, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de Manasseh, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, a partir dos vinte anos de idade, todos os que puderam sair para a guerra:
35 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Manase jẹ́ ẹgbàá ẹẹ́rìndínlógún ó lé igba.
those que foram contados deles, da tribo de Manasseh, eram trinta e dois mil e duzentos.
36 Láti ìran Benjamini, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de Benjamin, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, a partir dos vinte anos de idade, todos os que puderam sair para a guerra:
37 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Benjamini jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
those que foram contados deles, da tribo de Benjamin, eram trinta e cinco mil e quatrocentos.
38 Láti ìran Dani, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de Dan, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, a partir dos vinte anos de idade, todos os que puderam sair para a guerra:
39 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Dani jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
those que foram contados deles, da tribo de Dan, eram sessenta e dois mil e setecentos.
40 Láti ìran Aṣeri, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de Asher, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, a partir dos vinte anos de idade, todos os que puderam sair para a guerra:
41 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Aṣeri jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
those que foram contados deles, da tribo de Asher, eram quarenta e um mil e quinhentos.
42 Láti ìran Naftali, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún ó lé, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dos filhos de Naftali, suas gerações, por suas famílias, pela casa de seus pais, de acordo com o número de nomes, a partir dos vinte anos de idade, todos os que puderam sair para a guerra:
43 Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Naftali jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
those que foram contados deles, da tribo de Naftali, eram cinqüenta e três mil e quatrocentos.
44 Wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí Mose àti Aaroni kà, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn olórí méjìlá fún Israẹli, tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ṣojú fún ìdílé rẹ̀.
Estes são os que foram contados, que Moisés e Aarão contaram, e os doze homens que foram príncipes de Israel, cada um para a casa de seus pais.
45 Gbogbo ọmọkùnrin Israẹli tó jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tó sì lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
Portanto, todos aqueles que foram contados dos filhos de Israel pela casa de seus pais, a partir dos vinte anos de idade, todos os que puderam sair para a guerra em Israel -
46 Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
todos os que foram contados foram seiscentos e três mil e quinhentos e cinqüenta.
47 A kò ka àwọn ìdílé ẹ̀yà Lefi mọ́ àwọn ìyókù.
Mas os levitas após a tribo de seus pais não foram contados entre eles.
48 Nítorí Olúwa ti sọ fún Mose pé,
Pois Javé falou a Moisés, dizendo:
49 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ka ẹ̀yà Lefi, tàbí kí o kà wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
“Somente a tribo de Levi não contareis, nem fareis um censo deles entre os filhos de Israel;
50 Dípò èyí yan àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ alábojútó àgọ́ ẹ̀rí, lórí gbogbo ohun èlò àti ohun gbogbo tó jẹ́ ti àgọ́ ẹ̀rí. Àwọn ni yóò máa gbé àgọ́ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, wọn ó máa mójútó o, kí wọn ó sì máa pàgọ́ yí i ká.
mas designai os Levitas sobre o Tabernáculo do Testemunho, e sobre todos os seus móveis, e sobre tudo o que lhe pertence. Eles levarão o tabernáculo e toda sua mobília; e cuidarão dele, e acamparão ao seu redor.
51 Ìgbàkígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, àwọn ọmọ Lefi ni yóò tú palẹ̀, nígbàkígbà tí a bá sì tún pa àgọ́, àwọn ọmọ Lefi náà ni yóò ṣe é. Àlejò tó bá súnmọ́ tòsí ibẹ̀, pípa ni kí ẹ pa á
Quando o tabernáculo tiver que se mover, os Levitas o levarão para baixo; e quando o tabernáculo tiver que ser instalado, os Levitas o instalarão. O estranho que se aproximar será morto.
52 kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn olúkúlùkù ní ibùdó tirẹ̀ lábẹ́ ọ̀págun tirẹ̀.
Os filhos de Israel armarão suas tendas, cada homem por seu próprio acampamento, e cada homem por seu próprio padrão, de acordo com suas divisões.
53 Àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ alábojútó àti olùtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà, kí ìbínú má ba à sí lára ìjọ àwọn ọmọ Israẹli; kí àwọn ọmọ Lefi sì máa ṣe ìtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà.”
Mas os levitas acamparão ao redor do Tabernáculo do Testemunho, para que não haja ira sobre a congregação dos filhos de Israel. Os Levitas serão responsáveis pelo Tabernáculo do Testemunho”.
54 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Assim o fizeram as crianças de Israel. De acordo com tudo o que Javé ordenou a Moisés, assim o fizeram.

< Numbers 1 >