< Numbers 9 >

1 Olúwa sọ fún Mose nínú aginjù Sinai ní oṣù kìn-ín-ní ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti wí pé,
Gospod je spregovoril Mojzesu v Sinajski divjini, v prvem mesecu drugega leta, potem ko so prišli iz egiptovske dežele, rekoč:
2 “Mú kí àwọn ọmọ Israẹli máa pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní àsìkò rẹ̀.
»Naj Izraelovi otroci tudi pasho praznujejo ob njenem določenemu času.
3 Ẹ ṣe é ní àsìkò rẹ̀ gan an ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí ní ìbámu pẹ̀lú àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀.”
Na štirinajsti dan tega meseca, zvečer, jo boste praznovali ob določenem času, glede na vse njene zakone in glede na vse njene ceremonije, jo boste praznovali.«
4 Mose sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọ́n máa pa àjọ ìrékọjá mọ́.
In Mojzes je govoril Izraelovim otrokom, da naj praznujejo pasho.
5 Wọ́n sì ṣe àjọ ìrékọjá ní aginjù Sinai ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní. Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo nǹkan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Pasho so praznovali na štirinajsti dan prvega meseca zvečer v Sinajski divjini. Glede na vse, kar je Gospod zapovedal Mojzesu, tako so Izraelovi otroci storili.
6 Àwọn díẹ̀ nínú wọn kò lè ṣe àjọ ìrékọjá lọ́jọ́ náà nítorí pé wọ́n di aláìmọ́ nítorí òkú ènìyàn. Nítorí èyí wọ́n wá sọ́dọ̀ Mose àti Aaroni lọ́jọ́ náà.
Tam pa so bili neki možje, ki so se omadeževali pri človeškem truplu, da na ta dan niso mogli praznovati pashe in na ta dan so prišli pred Mojzesa in pred Arona
7 Wọ́n sọ fún Mose pé, “A di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn, ṣùgbọ́n kí ló dé tí a kò fi ní í le è fi ọrẹ wa fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ará Israẹli yòókù ní àsìkò tí a ti yàn.”
in ti možje so mu rekli: »Omadeževani smo s človeškim truplom. Zakaj smo zadržani, da ne moremo darovati Gospodove daritve ob določenem času med Izraelovimi otroki?«
8 Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ dúró kí n ba lè mọ ohun tí Olúwa yóò pàṣẹ nípa yín.”
Mojzes jim je rekel: »Mirno stojte, jaz pa bom poslušal, kaj bo glede vas zapovedal Gospod.«
9 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
Gospod je spregovoril Mojzesu, rekoč:
10 “Sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘Bí ẹnìkan nínú yín tàbí nínú ìran yín bá di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn tàbí bí ó bá lọ sí ìrìnàjò síbẹ̀ yóò pa àjọ ìrékọjá Olúwa mọ́.
»Govori Izraelovim otrokom, rekoč: ›Če bo katerikoli moški izmed vas ali izmed vašega potomstva postal nečist zaradi razloga trupla, ali bo na potovanju daleč stran, bo vendar praznoval pasho Gospodu.
11 Wọn yóò ṣe tiwọn ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì. Wọn yóò jẹ ẹran náà, pẹ̀lú àkàrà aláìwú àti ewúro.
Štirinajsti dan drugega meseca zvečer jo bodo praznovali in jo jedli z nekvašenim kruhom in grenkimi zelišči.
12 Wọn kò gbọdọ̀ ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀, wọn kò sì gbọdọ̀ ṣẹ́ eegun rẹ̀. Wọ́n gbọdọ̀ tẹ̀lé gbogbo ìlànà fún ṣíṣe àjọ ìrékọjá.
Od tega ne bodo ničesar pustili do jutra niti zlomili nobene njegove kosti. Glede na vse odredbe pashe jo bodo praznovali.
13 Ṣùgbọ́n bí ẹnìkan tó wà ní mímọ́ tí kò sì lọ sí ìrìnàjò bá kọ̀ láti pa àjọ ìrékọjá mọ́, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí pé kò mú ọrẹ Olúwa wá ní àsìkò tí ó yẹ. Ẹni náà yóò sì ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
Toda mož, ki je čist in ni na potovanju in se ogiba praznovati pasho, celo ista duša bo iztrebljena izmed svojega ljudstva. Ker ob določenem času ni prinesel daru Gospodu, bo ta mož nosil svoj greh.
14 “‘Bí àlejò tí ń gbé láàrín yín bá fẹ́ ṣe àjọ ìrékọjá Olúwa, ó gbọdọ̀ pa á mọ́ ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà àti òfin rẹ̀. Ìlànà kan náà ni kí ẹ ní fún àlejò àti àwọn ọmọ bíbí ilẹ̀ yín.’”
Če bo tujec začasno prebival med vami in bo praznoval pasho Gospodu, bo tako storil glede na odredbe pashe in glede na njen določeni način. Imeli boste eno odredbo, tako za tujca kakor za tistega, ki je bil rojen v deželi.‹«
15 Ní ọjọ́ tí wọ́n gbé àgọ́ ró, èyí tí í ṣe àgọ́ ẹ̀rí, dúró, ìkùùkuu àwọsánmọ̀ bò ó mọ́lẹ̀. Ìkùùkuu náà sì dàbí iná ní orí àgọ́ láti ìrọ̀lẹ́ títí di òwúrọ̀.
Na dan, ko je bilo šotorsko svetišče vzdignjeno, je oblak pokril šotorsko svetišče, namreč šotor pričevanja in zvečer je bilo nad šotorskim svetiščem kakor bi bil to videz ognja do jutra.
16 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí nígbà gbogbo; ìkùùkuu bò ó, àti pé ní alẹ́ ìrísí rẹ̀ sì dàbí iná.
Vedno je bilo tako; oblak ga je pokrival podnevi in videz ognja ponoči.
17 Nígbàkígbà tí ìkùùkuu yìí bá ká sókè kúrò lórí àgọ́ ni àwọn ọmọ Israẹli yóò dìde láti máa lọ; ibikíbi tí ìkùùkuu náà bá dúró sí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò pa ibùdó wọn sí.
Ko je bil oblak dvignjen od šotorskega svetišča, so za tem Izraelovi otroci odpotovali in na kraju, kjer je oblak obstal, tam so Izraelovi otroci postavili svoje šotore.
18 Nípa àṣẹ Olúwa ni àwọn ọmọ Israẹli ń jáde lọ, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń pa ibùdó wọn. Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́, àwọn náà yóò dúró sí ibùdó.
Na Gospodovo zapoved so Izraelovi otroci odpotovali in na Gospodovo zapoved so se utaborili. Kolikor dolgo je oblak ostajal nad šotorskim svetiščem, so počivali v svojih šotorih.
19 Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́ fún ìgbà pípẹ́, síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa wọn kò sì ní gbéra láti lọ.
Ko se je oblak mnogo dni zadrževal nad šotorskim svetiščem, potem so Izraelovi otroci pazili na Gospodovo naročilo in niso odpotovali.
20 Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè wà lórí àgọ́ fún ọjọ́ díẹ̀; síbẹ̀ ní àṣẹ Olúwa, wọn yóò dúró ní ibùdó, bí ó sì tún yá, ní àṣẹ rẹ̀ náà ni wọn yóò gbéra.
In bilo je, ko je bil oblak malo dni nad šotorskim svetiščem; glede na Gospodovo zapoved, so ostajali v svojih šotorih in glede na Gospodovo zapoved so odpotovali.
21 Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè dúró láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀, nígbà tó bá ṣí kúrò ní àárọ̀, wọn ó gbéra. Ìbá à ṣe ní ọ̀sán tàbí òru, ìgbàkígbà tí ìkùùkuu bá tó kúrò náà ni wọn ó tó gbéra.
In bilo je, ko je oblak ostajal od večera celo do jutra in da se je oblak zjutraj dvignil, potem so odpotovali, bodisi je bilo to podnevi ali ponoči, ko se je oblak dvignil, so odpotovali.
22 Ìbá à ṣe fún ọjọ́ méjì, oṣù kan tàbí ọdún kan ni ìkùùkuu fi dúró sórí àgọ́, àwọn ọmọ Israẹli yóò dúró ní ibùdó wọn, wọn kò ní gbéra; ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá lọ sókè ni wọn ó tó o gbéra.
Ali če je bilo to dva dni ali mesec ali leto, da je oblak ostajal nad šotorskim svetiščem, ostajajoč nad njim, so Izraelovi otroci ostali v svojih šotorih in niso odpotovali, toda ko je bil ta dvignjen, so odpotovali.
23 Nípa àṣẹ Olúwa ni wọ́n ń pa ibùdó wọn, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń gbéra. Wọ́n gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa ní ìbámu pẹ̀lú àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
Na Gospodovo zapoved so počivali v šotorih in na Gospodovo zapoved so odpotovali; pazili so na Gospodovo naročilo, na Gospodovo zapoved, po Mojzesovi roki.

< Numbers 9 >