< Numbers 9 >

1 Olúwa sọ fún Mose nínú aginjù Sinai ní oṣù kìn-ín-ní ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti wí pé,
И глагола Господь к Моисею в пустыни Синайстей, во второе лето изшедшым им из земли Египетския, в первый месяц, глаголя:
2 “Mú kí àwọn ọmọ Israẹli máa pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní àsìkò rẹ̀.
рцы да сотворят сынове Израилстии Пасху во время ея,
3 Ẹ ṣe é ní àsìkò rẹ̀ gan an ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí ní ìbámu pẹ̀lú àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀.”
в четвертыйнадесять день месяца перваго к вечеру, и сотвориши ю во время ея: по закону ея и по уставу ея сотвориши ю.
4 Mose sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọ́n máa pa àjọ ìrékọjá mọ́.
И рече Моисей сыном Израилтеским сотворити Пасху.
5 Wọ́n sì ṣe àjọ ìrékọjá ní aginjù Sinai ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní. Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo nǹkan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
И сотвориша Пасху, начинающуся первому месяцу в четвертыйнадесять день в пустыни Синайстей: якоже повеле Господь Моисею, тако сотвориша сынове Израилевы.
6 Àwọn díẹ̀ nínú wọn kò lè ṣe àjọ ìrékọjá lọ́jọ́ náà nítorí pé wọ́n di aláìmọ́ nítorí òkú ènìyàn. Nítorí èyí wọ́n wá sọ́dọ̀ Mose àti Aaroni lọ́jọ́ náà.
И приидоша мужие, иже бяху нечисти о души человечи, и не можаху сотворити Пасхи в той день: и приидоша пред Моисеа и Аарона в той день.
7 Wọ́n sọ fún Mose pé, “A di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn, ṣùgbọ́n kí ló dé tí a kò fi ní í le è fi ọrẹ wa fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ará Israẹli yòókù ní àsìkò tí a ti yàn.”
И рекоша мужие Онии к нему: мы нечисти есмы о души человечи: еда убо лишимся принести дар Господу во время свое посреде сынов Израилевых?
8 Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ dúró kí n ba lè mọ ohun tí Olúwa yóò pàṣẹ nípa yín.”
И рече Моисей к ним: станите ту, да яслышу, что повелит Господь о вас.
9 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
И рече Господь к Моисею, глаголя:
10 “Sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘Bí ẹnìkan nínú yín tàbí nínú ìran yín bá di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn tàbí bí ó bá lọ sí ìrìnàjò síbẹ̀ yóò pa àjọ ìrékọjá Olúwa mọ́.
рцы сыном Израилевым, глаголя: человек человек, иже аще будет нечист о души человечи, или на пути далече, или в вас, или в родех ваших, и да сотворит Пасху Господу,
11 Wọn yóò ṣe tiwọn ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì. Wọn yóò jẹ ẹran náà, pẹ̀lú àkàrà aláìwú àti ewúro.
в месяц вторый, в четвертыйнадесять день (месяца) к вечеру да сотворят ю, со опресноки и с горьким зелием да снедят ю:
12 Wọn kò gbọdọ̀ ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀, wọn kò sì gbọdọ̀ ṣẹ́ eegun rẹ̀. Wọ́n gbọdọ̀ tẹ̀lé gbogbo ìlànà fún ṣíṣe àjọ ìrékọjá.
да не оставят от нея на утрие, и кости да не сокрушат от нея, по всему закону Пасхи да сотворят ю.
13 Ṣùgbọ́n bí ẹnìkan tó wà ní mímọ́ tí kò sì lọ sí ìrìnàjò bá kọ̀ láti pa àjọ ìrékọjá mọ́, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí pé kò mú ọrẹ Olúwa wá ní àsìkò tí ó yẹ. Ẹni náà yóò sì ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
И человек, иже аще чист будет, и на пути далече несть, и оставит сотворити Пасху, потребится душа та от людий своих: яко дара Господви не принесе во время свое, грех свой приимет человек той.
14 “‘Bí àlejò tí ń gbé láàrín yín bá fẹ́ ṣe àjọ ìrékọjá Olúwa, ó gbọdọ̀ pa á mọ́ ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà àti òfin rẹ̀. Ìlànà kan náà ni kí ẹ ní fún àlejò àti àwọn ọmọ bíbí ilẹ̀ yín.’”
Аще же приидет к вам пришлец в землю вашу и сотворит Пасху Господу, по закону Пасхи и по чину ея, тако сотворит ю: закон един да будет вам и пришелцу и туземцу.
15 Ní ọjọ́ tí wọ́n gbé àgọ́ ró, èyí tí í ṣe àgọ́ ẹ̀rí, dúró, ìkùùkuu àwọsánmọ̀ bò ó mọ́lẹ̀. Ìkùùkuu náà sì dàbí iná ní orí àgọ́ láti ìrọ̀lẹ́ títí di òwúrọ̀.
И в день, в оньже поставися скиния, покры облак скинию и дом свидения: от вечера же бяше над скиниею аки вид огнен до заутрия:
16 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí nígbà gbogbo; ìkùùkuu bò ó, àti pé ní alẹ́ ìrísí rẹ̀ sì dàbí iná.
тако бываше всегда: облак покрываше ю в день, и вид огнен нощию: ,
17 Nígbàkígbà tí ìkùùkuu yìí bá ká sókè kúrò lórí àgọ́ ni àwọn ọmọ Israẹli yóò dìde láti máa lọ; ibikíbi tí ìkùùkuu náà bá dúró sí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò pa ibùdó wọn sí.
и егда восхождаше облак от скинии, и по сих воздвизахуся сынове Израилтестии: и на месте, на немже стояше облак, тамо ополчахуся сынове Израилевы.
18 Nípa àṣẹ Olúwa ni àwọn ọmọ Israẹli ń jáde lọ, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń pa ibùdó wọn. Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́, àwọn náà yóò dúró sí ibùdó.
По повелению Господню да ополчаются сынове Израилевы и повелением Господним да воздвизаются: во вся дни, в няже осеняет облак над скиниею, да ополчаются сынове Израилевы:
19 Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́ fún ìgbà pípẹ́, síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa wọn kò sì ní gbéra láti lọ.
и егда премедлит облак над скиниею дни многи, да стрегут сынове Израилтестии стражу Господню и да не воздвижутся:
20 Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè wà lórí àgọ́ fún ọjọ́ díẹ̀; síbẹ̀ ní àṣẹ Olúwa, wọn yóò dúró ní ibùdó, bí ó sì tún yá, ní àṣẹ rẹ̀ náà ni wọn yóò gbéra.
и будет егда покрыет облак дни числа над скиниею, глаголголом Господним да ополчаются и повелением Господним да воздвижутся:
21 Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè dúró láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀, nígbà tó bá ṣí kúrò ní àárọ̀, wọn ó gbéra. Ìbá à ṣe ní ọ̀sán tàbí òru, ìgbàkígbà tí ìkùùkuu bá tó kúrò náà ni wọn ó tó gbéra.
и будет егда пребудет облак от вечера до заутрия, и аще воздвигнется облак заутра, да воздвигнутся днем или нощию,
22 Ìbá à ṣe fún ọjọ́ méjì, oṣù kan tàbí ọdún kan ni ìkùùkuu fi dúró sórí àgọ́, àwọn ọmọ Israẹli yóò dúró ní ibùdó wọn, wọn kò ní gbéra; ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá lọ sókè ni wọn ó tó o gbéra.
и аще воздвигнется облак, да пойдут: или день или месяц дний умножит облак осеняющь над нею, да ополчатся сынове Израилевы, и да не воздвизаются: во отступлении его, воздвизахуся:
23 Nípa àṣẹ Olúwa ni wọ́n ń pa ibùdó wọn, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń gbéra. Wọ́n gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa ní ìbámu pẹ̀lú àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
яко повелением Господним да ополчаются и повелением Господним да воздвизаются: стражу Господню стрежаху по повелению Господню рукою Моисеовою.

< Numbers 9 >