< Numbers 9 >

1 Olúwa sọ fún Mose nínú aginjù Sinai ní oṣù kìn-ín-ní ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti wí pé,
Nake Jehova akĩarĩria Musa kũu Werũ-inĩ wa Sinai mweri-inĩ wa mbere wa mwaka wa keerĩ thuutha wa andũ a Isiraeli kuuma bũrũri wa Misiri, akĩmwĩra atĩrĩ,
2 “Mú kí àwọn ọmọ Israẹli máa pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní àsìkò rẹ̀.
“Ĩra andũ a Isiraeli makũngũyagĩre Gĩathĩ-kĩa-Bathaka ihinda rĩrĩa rĩtuĩtwo.
3 Ẹ ṣe é ní àsìkò rẹ̀ gan an ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí ní ìbámu pẹ̀lú àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀.”
Kũngũyagĩrai gĩathĩ kĩu ihinda rĩrĩa rĩtuĩtwo, hwaĩ-inĩ wa mũthenya wa ikũmi na ĩna wa mweri ũyũ, kũringana na mawatho makĩo mothe na mũtabarĩre wakĩo.”
4 Mose sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọ́n máa pa àjọ ìrékọjá mọ́.
Nĩ ũndũ ũcio Musa akĩĩra andũ a Isiraeli makũngũĩre Gĩathĩ-kĩa-Bathaka.
5 Wọ́n sì ṣe àjọ ìrékọjá ní aginjù Sinai ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní. Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo nǹkan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Nao magĩĩka o ro ũguo kũu Werũ-inĩ wa Sinai hwaĩ-inĩ wa mũthenya wa ikũmi na ĩna wa mweri wa mbere. Andũ a Isiraeli magĩĩka maũndũ mothe o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
6 Àwọn díẹ̀ nínú wọn kò lè ṣe àjọ ìrékọjá lọ́jọ́ náà nítorí pé wọ́n di aláìmọ́ nítorí òkú ènìyàn. Nítorí èyí wọ́n wá sọ́dọ̀ Mose àti Aaroni lọ́jọ́ náà.
No amwe ao matingĩakũngũĩire Gĩathĩ-kĩa-Bathaka mũthenya ũcio nĩ ũndũ nĩmagwatĩtwo nĩ thaahu nĩ ũndũ wa kũhutania na kĩimba kĩa mũndũ. Nĩ ũndũ ũcio magĩũka kũrĩ Musa na Harũni mũthenya o ro ũcio
7 Wọ́n sọ fún Mose pé, “A di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn, ṣùgbọ́n kí ló dé tí a kò fi ní í le è fi ọrẹ wa fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ará Israẹli yòókù ní àsìkò tí a ti yàn.”
makĩĩra Musa atĩrĩ, “Nĩ tũnyiitĩtwo nĩ thaahu nĩ ũndũ wa kũhutania na kĩimba kĩa mũndũ, no nĩ kĩĩ gĩgũtũma tũgirio kũneana indo cia kũrutĩra Jehova tũrĩ hamwe na andũ a Isiraeli arĩa angĩ ihinda rĩrĩa rĩtuĩtwo?”
8 Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ dúró kí n ba lè mọ ohun tí Olúwa yóò pàṣẹ nípa yín.”
Musa akĩmacookeria atĩrĩ, “Etererai nyambe nduĩrie ũhoro wa ũrĩa Jehova egwathana ũhoro wanyu.”
9 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
Jehova agĩcooka akĩĩra Musa atĩrĩ,
10 “Sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘Bí ẹnìkan nínú yín tàbí nínú ìran yín bá di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn tàbí bí ó bá lọ sí ìrìnàjò síbẹ̀ yóò pa àjọ ìrékọjá Olúwa mọ́.
“Ĩra andũ a Isiraeli atĩrĩ: ‘Rĩrĩa mũndũ wanyu o na ũrĩkũ kana njiaro cianyu marĩ na thaahu nĩ ũndũ wa kũhutania na kĩimba kĩa mũndũ, kana akorwo arĩ rũgendo-inĩ-rĩ, mũndũ ũcio o nake no akũngũĩre Gĩathĩ-kĩa-Bathaka ya Jehova.
11 Wọn yóò ṣe tiwọn ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì. Wọn yóò jẹ ẹran náà, pẹ̀lú àkàrà aláìwú àti ewúro.
Marĩkũngũyagĩra gĩathĩ kĩu hwaĩ-inĩ wa mũthenya wa ikũmi na ĩna wa mweri wa keerĩ. Marĩrĩĩaga gatũrũme na mĩgate ĩtarĩ mĩĩkĩre ndawa ya kũimbia na nyeni ndũrũ.
12 Wọn kò gbọdọ̀ ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀, wọn kò sì gbọdọ̀ ṣẹ́ eegun rẹ̀. Wọ́n gbọdọ̀ tẹ̀lé gbogbo ìlànà fún ṣíṣe àjọ ìrékọjá.
Matikanatigie gacunjĩ o na kamwe karaare nginya rũciinĩ kana moine ihĩndĩ rĩako o na rĩmwe. Rĩrĩa megũkũngũĩra Gĩathĩ-kĩa-Bathaka ĩyo no nginya marũmagĩrĩre mũtabarĩre wakĩo wothe.
13 Ṣùgbọ́n bí ẹnìkan tó wà ní mímọ́ tí kò sì lọ sí ìrìnàjò bá kọ̀ láti pa àjọ ìrékọjá mọ́, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí pé kò mú ọrẹ Olúwa wá ní àsìkò tí ó yẹ. Ẹni náà yóò sì ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
No mũndũ angĩkorwo ndarĩ na thaahu, na ndathiĩte rũgendo, na aage gũkũngũĩra Gĩathĩ-kĩa-Bathaka, mũndũ ũcio nĩakaingatwo athengio kuuma kũrĩ andũ ao, nĩ ũndũ ndaareheire Jehova indo iria arutagĩrwo ihinda rĩrĩa rĩtuĩtwo. Mũndũ ũcio nĩagacookererwo nĩ mehia make mwene.
14 “‘Bí àlejò tí ń gbé láàrín yín bá fẹ́ ṣe àjọ ìrékọjá Olúwa, ó gbọdọ̀ pa á mọ́ ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà àti òfin rẹ̀. Ìlànà kan náà ni kí ẹ ní fún àlejò àti àwọn ọmọ bíbí ilẹ̀ yín.’”
“‘Mũgeni ũikaranĩtie na inyuĩ na ende gũkũngũĩra Gĩathĩ-kĩa-Bathaka ya Jehova-rĩ, no nginya eke ũguo kũringana na watho na mũtabarĩre wakĩo. No nginya mũgĩage na mĩtabarĩre ya mũthemba ũmwe kũrĩ mũgeni na kũrĩ mũndũ ũrĩa ũciarĩirwo bũrũri wanyu.’”
15 Ní ọjọ́ tí wọ́n gbé àgọ́ ró, èyí tí í ṣe àgọ́ ẹ̀rí, dúró, ìkùùkuu àwọsánmọ̀ bò ó mọ́lẹ̀. Ìkùùkuu náà sì dàbí iná ní orí àgọ́ láti ìrọ̀lẹ́ títí di òwúrọ̀.
Mũthenya ũrĩa Hema-ĩrĩa-Nyamũre, o Hema-ĩyo-ya-Ũira yaambirwo-rĩ, itu rĩkĩmĩhumbĩra. Kuuma hwaĩ-inĩ nginya rũciinĩ itu rĩu rĩarĩ igũrũ rĩa Hema-ĩyo-Nyamũre na itu rĩu rĩkoonagwo rĩhaana ta mwaki.
16 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí nígbà gbogbo; ìkùùkuu bò ó, àti pé ní alẹ́ ìrísí rẹ̀ sì dàbí iná.
Ũguo nĩguo gwathiire na mbere gũikara; itu rĩkamĩhumbĩra ũtukũ na rĩkoonagwo rĩhaana ta mwaki.
17 Nígbàkígbà tí ìkùùkuu yìí bá ká sókè kúrò lórí àgọ́ ni àwọn ọmọ Israẹli yóò dìde láti máa lọ; ibikíbi tí ìkùùkuu náà bá dúró sí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò pa ibùdó wọn sí.
Hĩndĩ ĩrĩa yothe itu rĩu rĩeheraga kuuma harĩ hema ĩyo, andũ a Isiraeli makoimagara magathiĩ; na rĩrĩ, itu rĩu rĩarũgamĩra handũ, andũ a Isiraeli makaamba hema ciao ho.
18 Nípa àṣẹ Olúwa ni àwọn ọmọ Israẹli ń jáde lọ, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń pa ibùdó wọn. Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́, àwọn náà yóò dúró sí ibùdó.
Jehova aathana-rĩ, andũ a Isiraeli makoimagara magathiĩ, na aathana rĩngĩ makaamba hema ciao. Hĩndĩ ĩrĩa yothe itu rĩu rĩaikara igũrũ rĩa Hema-ĩyo-Nyamũre, maikaraga o hau kambĩ.
19 Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́ fún ìgbà pípẹ́, síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa wọn kò sì ní gbéra láti lọ.
Hĩndĩ ĩrĩa itu rĩaikara igũrũ rĩa Hema-ĩyo-Nyamũre kahinda karaaya-rĩ, andũ a Isiraeli magaathĩkĩra Jehova na makaaga kuumagara.
20 Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè wà lórí àgọ́ fún ọjọ́ díẹ̀; síbẹ̀ ní àṣẹ Olúwa, wọn yóò dúró ní ibùdó, bí ó sì tún yá, ní àṣẹ rẹ̀ náà ni wọn yóò gbéra.
Mahinda mamwe itu rĩu rĩaikaraga igũrũ rĩa Hema-ĩyo-Nyamũre o matukũ manini; no Jehova aathana makaamba hema, na ningĩ aathana, makoimagara magathiĩ.
21 Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè dúró láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀, nígbà tó bá ṣí kúrò ní àárọ̀, wọn ó gbéra. Ìbá à ṣe ní ọ̀sán tàbí òru, ìgbàkígbà tí ìkùùkuu bá tó kúrò náà ni wọn ó tó gbéra.
Mahinda mamwe itu rĩu rĩaikaraga o kuuma hwaĩ-inĩ nginya rũciinĩ, na itu rĩehera rũciinĩ-rĩ, makoimagara magathiĩ. Kana nĩ mũthenya kana nĩ ũtukũ, hĩndĩ o yothe itu rĩu rĩehera nao makoimagara magathiĩ.
22 Ìbá à ṣe fún ọjọ́ méjì, oṣù kan tàbí ọdún kan ni ìkùùkuu fi dúró sórí àgọ́, àwọn ọmọ Israẹli yóò dúró ní ibùdó wọn, wọn kò ní gbéra; ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá lọ sókè ni wọn ó tó o gbéra.
Itu rĩu rĩngĩaikarire igũrũ rĩa hema ĩyo mĩthenya ĩĩrĩ, kana mweri, kana mwaka, andũ a Isiraeli maikaraga kũu kambĩ, na matingĩoimagarire mathiĩ, no itu rĩu rĩehera makoimagara magathiĩ.
23 Nípa àṣẹ Olúwa ni wọ́n ń pa ibùdó wọn, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń gbéra. Wọ́n gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa ní ìbámu pẹ̀lú àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
Jehova aathana makaamba hema, na ningĩ Jehova aathana makoimagara magathiĩ. Maathĩkagĩra watho wa Jehova kũringana na ũrĩa aathaga Musa.

< Numbers 9 >