< Numbers 8 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Perwerdigar Musagha söz qilip: —
2 “Bá Aaroni sọ̀rọ̀ kí o wí fún un pé. ‘Nígbà tí ó bá ń to àwọn fìtílà, àwọn fìtílà méjèèje gbọdọ̀ tan ìmọ́lẹ̀ sí àyíká níwájú ọ̀pá fìtílà.’”
Sen Harun’gha: «Sen chiraghlar yaqidighan chaghda yette chiraghning hemmisi chiraghdanning aldini yorutidighan bolsun» dep éytip qoy, — dédi.
3 Aaroni sì ṣe bẹ́ẹ̀; ó to àwọn fìtílà náà tí wọ́n sì fi kojú síwájú lórí ọ̀pá fìtílà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Harun shundaq qildi; u chiraghdan üstidiki chiraghlarning hemmisini yandurup, xuddi Perwerdigarning Musagha éytqinidek, chiragh nurini chiraghdanning aldini yorutidighan qilip qoydi.
4 Bí a ṣe ṣe ọ̀pá fìtílà náà nìyìí, a ṣe é láti ara wúrà lílù: láti ìsàlẹ̀ títí dé ibi ìtànná rẹ̀. Wọ́n ṣe ọ̀pá fìtílà náà gẹ́gẹ́ bí bátànì tí Olúwa fihan Mose.
Chiraghdanning yasilishi mundaq: u altundin bolqa bilen soqup yasalghan, putidin güllirigiche bolqa bilen soqup chiqirilghan. Perwerdigar Musagha körsetken nusxidek, u chiraghdanni shundaq yasatti.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
Perwerdigar Musagha mundaq dédi: —
6 “Yọ àwọn ọmọ Lefi kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, kí o sì wẹ̀ wọ́n mọ́.
Sen Israillarning ichidin Lawiylarni tallap chiqip paklighin.
7 Báyìí ni kí o ṣe wẹ̀ wọ́n mọ́. Wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ sí wọn lára, mú kí wọn ó fá irun ara wọn, kí wọn ó fọ aṣọ wọn, kí wọn ó ba à lè wẹ ara wọn mọ́ nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
Ularni paklash üchün ulargha mundaq qil: «kafaret süyi»ni ularning bedinige chachqin; andin ular özliri pütün bedinini ustura bilen chüshürsun, kiyimlirini yuyup özini pak qilsun.
8 Jẹ́ kí wọn ó mú akọ ọ̀dọ́ màlúù pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ rẹ̀ tí í ṣe ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò, kí ìwọ náà mú akọ ọ̀dọ́ màlúù kejì fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Andin kéyin ular bir torpaq bilen shuninggha qoshup ashliq hediyesini, yeni zeytun méyi ileshtürülgen ésil unni keltürsun; sen gunah qurbanliqi üchün yene bir torpaqni keltür.
9 Ìwọ ó sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú àgọ́ ìpàdé, kí o sì kó gbogbo àpapọ̀ ọmọ Israẹli jọ síbẹ̀ pẹ̀lú.
Sen Lawiylarni jamaet chédirining aldigha keltür we pütün Israil jamaitini yighip kel;
10 Báyìí ni kí o mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa, gbogbo ọmọ Israẹli yóò sì gbọ́wọ́ lé àwọn ọmọ Lefi lórí.
Lawiylarni Perwerdigarning huzurigha hazir qilghin; andin Israillar kélip qollirini ularning üstige qoysun.
11 Aaroni yóò sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli wá, kí wọn lè máa ṣiṣẹ́ Olúwa.
Harun Lawiylarni Israillarning «pulanglatma qurbanliq»i süpitide Perwerdigarning xizmitini qilsun dep, Perwerdigargha hediye qilsun.
12 “Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi bá gbé ọwọ́ wọn lé orí àwọn akọ ọmọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun sí Olúwa, láti ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Lefi.
Lawiylar qollirini héliqi ikki torpaqning béshigha qoysun; sen birini gunah qurbanliqi bolsun, birini köydürme qurbanliq bolsun, Lawiylar üchün kafaret keltürsun dep Perwerdigargha sun’ghin.
13 Mú kí àwọn ọmọ Lefi dúró níwájú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí ó sì gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì sí Olúwa.
Sen andin Lawiylarni Harun bilen uning oghullirining aldida turghuzup, ularni pulanglatma qurbanliq süpitide Perwerdigargha hediye qil.
14 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe ya ọmọ Lefi sọ́tọ̀, kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, àwọn ọmọ Lefi yóò sì jẹ́ tèmi.
Lawiylar Méningki bolsun dep, sen Lawiylarni ene shu teriqide Israillardin ayrip chiq.
15 “Lẹ́yìn tí ó ti wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, tí ó sì ti gbé wọn kalẹ̀ bí ẹbọ fífì nígbà náà ni kí wọn ó lọ máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
Andin Lawiylar kirip jamaet chédirining ishlirini qilsa bolidu; sen ularni paklandur, ularni pulanglatma qurbanliq süpitide hediye qil.
16 Nítorí pé àwọn ni ó jẹ́ ti Èmi pátápátá nínú àwọn ọmọ Israẹli. Mo ti gbà wọ́n fún ara mi dípò àwọn àkọ́bí àní àkọ́bí ọkùnrin gbogbo Israẹli.
Chünki ular Israillar ichide pütünley Manga atalghan; Méning ularni Méningki bolsun dep tallishim ularni Israillarning arisida baliyatquning tunji méwisi ornida qoyghanliqimdur.
17 Nítorí pé gbogbo àkọ́bí ọmọ lọ́kùnrin ní Israẹli jẹ́ tèmi, ti ènìyàn àti ti ẹranko, láti ọjọ́ tí mo ti pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ara mi.
Chünki Israillarning tunjisi, meyli u insan yaki haywan bolsun, pütünley Manga tewedur; Men Misir zéminida barliq tunjilarni öltürgen küni ularni Özümge muqeddes qilip éliwalghanidim.
18 Mo sì ti gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí ọmọ ọkùnrin nínú Israẹli.
Méning Lawiylarni u yol bilen tallishim ularni Israillarning ichidiki tunjilirining ornida qoyushum üchündur.
19 Nínú Israẹli, mo fi àwọn ọmọ Lefi fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn láti máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé fun àwọn ọmọ Israẹli àti láti máa ṣe ètùtù fún wọn kí àjàkálẹ̀-ààrùn má ba à kọlu àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi mímọ́.”
We jamaet chédirida Israillarning xizmitide bolsun we Israillarning [gunahini tilep] kafaret keltürsun, shuningdek Israillar muqeddes jaygha yéqinlashqanda ular arisida bala-qaza chiqmisun dep, Men Israillar ichidin Lawiylarni Harun bilen uning oghullirigha berdim.
20 Mose, Aaroni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Musa, Harun we pütkül Israil jamaiti Lawiylarni shundaq qildi; Perwerdigarning Lawiylar toghruluq Musagha buyrughinidek Israillar hemmisini beja keltürdi.
21 Àwọn ọmọ Lefi wẹ ara wọn mọ́, wọ́n sì fọ aṣọ wọn. Aaroni sì mú wọn wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì níwájú Olúwa, Aaroni sì ṣe ètùtù fún wọn láti wẹ̀ wọ́n mọ́.
Lawiylar shundaq qilip özlirini [gunahtin] paklap, kiyim-kécheklirini yuyup pakizlidi; Harun ularni pulanglatma qurbanliq süpitide Perwerdigargha hediye qildi; Harun yene ularni paklashqa [gunahini tilep] kafaret qildi.
22 Lẹ́yìn èyí àwọn ọmọ Lefi lọ sínú àgọ́ ìpàdé láti lọ máa ṣiṣẹ́ wọn lábẹ́ àbojútó Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Andin kéyin Lawiylar kirip Harunning aldida, shundaqla uning oghullirining aldida, jamaet chédiri ichidiki ishlarni qilishqa kirishti; Perwerdigar Lawiylar toghruluq Musagha qandaq buyrughan bolsa, Israillar uni shu boyiche beja keltürdi.
23 Olúwa sọ fún Mose pé,
Perwerdigar Musagha söz qilip mundaq dédi: —
24 “Èyí ni ohun tó jẹ mọ́ àwọn ọmọ Lefi, láti ọmọ ọdún kẹẹdọ́gbọ̀n tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni kí ó máa kópa nínú iṣẹ́ àgọ́ ìpàdé.
Lawiylarning wezipisi mundaq bolsun: — Yigirme besh yashtin yuqiriliri kirip jamaet chédiri ichidiki ishlarni qilishqa sepke kirsun;
25 Ṣùgbọ́n ẹni tó bá ti pé ọmọ àádọ́ta ọdún gbọdọ̀ ṣíwọ́ nínú iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn nínú àgọ́, kí wọ́n sì má ṣiṣẹ́ mọ́.
ellik yashqa yetkendin kéyin septin chékinip shu xizmetni qilmisun;
26 Wọ́n le máa ran àwọn arákùnrin wọn lọ́wọ́ nínú àgọ́ ìpàdé ṣùgbọ́n àwọn fúnra wọn kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Báyìí ni kí o ṣe pín iṣẹ́ fún àwọn ọmọ Lefi.”
lékin ular jamaet chédiri ichide qérindashlirigha yardemliship, ularning hajetliridin chiqishqa bolidu, emma chédirdiki resmiy wezipide bolmisun. Lawiylarning wezipiliri heqqide ulargha ene shundaq qil.

< Numbers 8 >