< Numbers 8 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yavé habló a Moisés:
2 “Bá Aaroni sọ̀rọ̀ kí o wí fún un pé. ‘Nígbà tí ó bá ń to àwọn fìtílà, àwọn fìtílà méjèèje gbọdọ̀ tan ìmọ́lẹ̀ sí àyíká níwájú ọ̀pá fìtílà.’”
Habla a Aarón: Cuando enciendas las lámparas, las siete lámparas deberán alumbrar hacia adelante del candelabro.
3 Aaroni sì ṣe bẹ́ẹ̀; ó to àwọn fìtílà náà tí wọ́n sì fi kojú síwájú lórí ọ̀pá fìtílà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Así lo hizo Aarón. Encendió las lámparas para alumbrar hacia adelante del candelabro, como Yavé ordenó a Moisés.
4 Bí a ṣe ṣe ọ̀pá fìtílà náà nìyìí, a ṣe é láti ara wúrà lílù: láti ìsàlẹ̀ títí dé ibi ìtànná rẹ̀. Wọ́n ṣe ọ̀pá fìtílà náà gẹ́gẹ́ bí bátànì tí Olúwa fihan Mose.
El candelabro de oro era labrado a martillo desde su basa hasta sus flores. Hizo el candelabro según el modelo que Yavé mostró a Moisés.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yavé habló a Moisés:
6 “Yọ àwọn ọmọ Lefi kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, kí o sì wẹ̀ wọ́n mọ́.
Toma a los levitas de entre los hijos de Israel y purifícalos.
7 Báyìí ni kí o ṣe wẹ̀ wọ́n mọ́. Wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ sí wọn lára, mú kí wọn ó fá irun ara wọn, kí wọn ó fọ aṣọ wọn, kí wọn ó ba à lè wẹ ara wọn mọ́ nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
Para purificarlos harás con ellos esto: Rocía sobre ellos agua purificadora, que ellos pasen una navaja sobre todo su cuerpo y laven sus ropas. Quedarán puros.
8 Jẹ́ kí wọn ó mú akọ ọ̀dọ́ màlúù pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ rẹ̀ tí í ṣe ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò, kí ìwọ náà mú akọ ọ̀dọ́ màlúù kejì fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Luego tomarán un buey con su ofrenda vegetal de flor de harina amasada con aceite. Y tú tomarás otro buey para el sacrificio por el pecado.
9 Ìwọ ó sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú àgọ́ ìpàdé, kí o sì kó gbogbo àpapọ̀ ọmọ Israẹli jọ síbẹ̀ pẹ̀lú.
Harás que los levitas se presenten al Tabernáculo de Reunión, y harás que se congregue toda la asamblea de los hijos de Israel.
10 Báyìí ni kí o mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa, gbogbo ọmọ Israẹli yóò sì gbọ́wọ́ lé àwọn ọmọ Lefi lórí.
Presentarás a los levitas delante de Yavé. Los hijos de Israel impondrán sus manos sobre ellos.
11 Aaroni yóò sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli wá, kí wọn lè máa ṣiṣẹ́ Olúwa.
Después Aarón presentará a los levitas delante de Yavé como ofrenda mecida de los hijos de Israel para que queden calificados para el servicio a Yavé.
12 “Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi bá gbé ọwọ́ wọn lé orí àwọn akọ ọmọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun sí Olúwa, láti ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Lefi.
Luego los levitas pondrán sus manos sobre las cabezas de los becerros y ofrecerás uno como sacrificio por el pecado, y otro como holocausto a Yavé, para hacer sacrificio que apacigua a favor de los levitas.
13 Mú kí àwọn ọmọ Lefi dúró níwájú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí ó sì gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì sí Olúwa.
Inmediatamente mantendrás a los levitas en pie ante Aarón y sus hijos para presentarlos como ofrenda mecida a Yavé.
14 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe ya ọmọ Lefi sọ́tọ̀, kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, àwọn ọmọ Lefi yóò sì jẹ́ tèmi.
Así separarás a los levitas de entre los hijos de Israel. Los levitas serán míos.
15 “Lẹ́yìn tí ó ti wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, tí ó sì ti gbé wọn kalẹ̀ bí ẹbọ fífì nígbà náà ni kí wọn ó lọ máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
Después de esto, cuando los hayas purificado y presentado como ofrenda mecida, los levitas entrarán para cumplir el servicio en el Tabernáculo de Reunión,
16 Nítorí pé àwọn ni ó jẹ́ ti Èmi pátápátá nínú àwọn ọmọ Israẹli. Mo ti gbà wọ́n fún ara mi dípò àwọn àkọ́bí àní àkọ́bí ọkùnrin gbogbo Israẹli.
porque los levitas son entregados completamente a Mí de entre los hijos de Israel. Yo los tomé para Mí en sustitución de todo el que abre matriz, es decir, de todo primogénito entre los hijos de Israel.
17 Nítorí pé gbogbo àkọ́bí ọmọ lọ́kùnrin ní Israẹli jẹ́ tèmi, ti ènìyàn àti ti ẹranko, láti ọjọ́ tí mo ti pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ara mi.
Porque mío es todo primogénito de los hijos de Israel, tanto de hombre como de animal. Desde el día cuando quité la vida a todo primogénito en la tierra de Egipto los consagré para Mí.
18 Mo sì ti gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí ọmọ ọkùnrin nínú Israẹli.
Pero tomé a los levitas en sustitución de todos los primogénitos de los hijos de Israel.
19 Nínú Israẹli, mo fi àwọn ọmọ Lefi fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn láti máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé fun àwọn ọmọ Israẹli àti láti máa ṣe ètùtù fún wọn kí àjàkálẹ̀-ààrùn má ba à kọlu àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi mímọ́.”
Entregué a los levitas como dones para Aarón y sus hijos de entre los hijos de Israel, para que sirvan en representación de los hijos de Israel en el Tabernáculo de Reunión y hagan sacrificio que apacigua a favor de los hijos de Israel. Así no habrá mortandad entre los hijos de Israel cuando se acerquen al Santuario.
20 Mose, Aaroni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Entonces Moisés, Aarón y toda la asamblea de los hijos de Israel hicieron con los levitas conforme a todo lo que Yavé ordenó a Moisés con respecto a los levitas. Así los hijos de Israel hicieron con ellos.
21 Àwọn ọmọ Lefi wẹ ara wọn mọ́, wọ́n sì fọ aṣọ wọn. Aaroni sì mú wọn wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì níwájú Olúwa, Aaroni sì ṣe ètùtù fún wọn láti wẹ̀ wọ́n mọ́.
Los levitas se purificaron de pecado y lavaron sus ropas. Luego Aarón los presentó como ofrenda mecida ante Yavé e hizo sacrificio que apacigua a favor de ellos para purificarlos.
22 Lẹ́yìn èyí àwọn ọmọ Lefi lọ sínú àgọ́ ìpàdé láti lọ máa ṣiṣẹ́ wọn lábẹ́ àbojútó Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Después de esto, los levitas entraron para ejercer su ministerio en el Tabernáculo de Reunión delante de Aarón y de sus hijos. De la manera como Yavé ordenó a Moisés con respecto a los levitas, así hicieron con ellos.
23 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yavé habló a Moisés:
24 “Èyí ni ohun tó jẹ mọ́ àwọn ọmọ Lefi, láti ọmọ ọdún kẹẹdọ́gbọ̀n tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni kí ó máa kópa nínú iṣẹ́ àgọ́ ìpàdé.
Esto es lo relacionado con los levitas: Desde la edad de 25 años para arriba, entrarán para servir en el Tabernáculo de Reunión,
25 Ṣùgbọ́n ẹni tó bá ti pé ọmọ àádọ́ta ọdún gbọdọ̀ ṣíwọ́ nínú iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn nínú àgọ́, kí wọ́n sì má ṣiṣẹ́ mọ́.
y a los 50 años se retirarán de su servicio, y nunca más lo ejercerán.
26 Wọ́n le máa ran àwọn arákùnrin wọn lọ́wọ́ nínú àgọ́ ìpàdé ṣùgbọ́n àwọn fúnra wọn kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Báyìí ni kí o ṣe pín iṣẹ́ fún àwọn ọmọ Lefi.”
Servirán con sus hermanos en el Tabernáculo de Reunión para hacer guardia, pero no servirán en el ministerio. Así harás con los levitas en cuanto a sus obligaciones.

< Numbers 8 >