< Numbers 8 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
2 “Bá Aaroni sọ̀rọ̀ kí o wí fún un pé. ‘Nígbà tí ó bá ń to àwọn fìtílà, àwọn fìtílà méjèèje gbọdọ̀ tan ìmọ́lẹ̀ sí àyíká níwájú ọ̀pá fìtílà.’”
Vorbește lui Aaron și spune-i: Când aprinzi lămpile, cele șapte lămpi să dea lumină în fața sfeșnicului.
3 Aaroni sì ṣe bẹ́ẹ̀; ó to àwọn fìtílà náà tí wọ́n sì fi kojú síwájú lórí ọ̀pá fìtílà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Și Aaron a făcut astfel; a aprins lămpile în fața sfeșnicului, precum DOMNUL i-a poruncit lui Moise.
4 Bí a ṣe ṣe ọ̀pá fìtílà náà nìyìí, a ṣe é láti ara wúrà lílù: láti ìsàlẹ̀ títí dé ibi ìtànná rẹ̀. Wọ́n ṣe ọ̀pá fìtílà náà gẹ́gẹ́ bí bátànì tí Olúwa fihan Mose.
Și această lucrare a sfeșnicului era din aur bătut, până la stâlpul lui, până la florile lui, era lucrare bătută, conform modelului pe care DOMNUL îl arătase lui Moise, astfel a făcut el sfeșnicul.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
6 “Yọ àwọn ọmọ Lefi kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, kí o sì wẹ̀ wọ́n mọ́.
Ia pe leviți dintre copiii lui Israel și curăță-i.
7 Báyìí ni kí o ṣe wẹ̀ wọ́n mọ́. Wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ sí wọn lára, mú kí wọn ó fá irun ara wọn, kí wọn ó fọ aṣọ wọn, kí wọn ó ba à lè wẹ ara wọn mọ́ nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
Și astfel să le faci ca să îi cureți: Stropește apa curățirii peste ei, iar ei să își bărbierească toată carnea lor și să își spele hainele și astfel să se curețe.
8 Jẹ́ kí wọn ó mú akọ ọ̀dọ́ màlúù pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ rẹ̀ tí í ṣe ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò, kí ìwọ náà mú akọ ọ̀dọ́ màlúù kejì fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Apoi să ia un taur tânăr cu darul lui de mâncare, floarea făinii amestecată cu untdelemn și un alt taur tânăr să îl iei tu ca ofrandă pentru păcat.
9 Ìwọ ó sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú àgọ́ ìpàdé, kí o sì kó gbogbo àpapọ̀ ọmọ Israẹli jọ síbẹ̀ pẹ̀lú.
Și să aduci pe leviți înaintea tabernacolului întâlnirii și să aduni întreaga adunare a copiilor lui Israel la un loc;
10 Báyìí ni kí o mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa, gbogbo ọmọ Israẹli yóò sì gbọ́wọ́ lé àwọn ọmọ Lefi lórí.
Și să aduci pe leviți înaintea DOMNULUI și copiii lui Israel să își pună mâinile peste leviți;
11 Aaroni yóò sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli wá, kí wọn lè máa ṣiṣẹ́ Olúwa.
Și Aaron să ofere pe leviți înaintea DOMNULUI ca o ofrandă a copiilor lui Israel, ca ei să facă serviciul DOMNULUI.
12 “Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi bá gbé ọwọ́ wọn lé orí àwọn akọ ọmọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun sí Olúwa, láti ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Lefi.
Și leviții să își pună mâinile pe capetele taurilor și tu să aduci pe unul ca ofrandă pentru păcat și pe altul ca ofrandă arsă, DOMNULUI, pentru a face ispășire pentru leviți.
13 Mú kí àwọn ọmọ Lefi dúró níwájú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí ó sì gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì sí Olúwa.
Și să îi pui să stea pe leviți înaintea lui Aaron și înaintea fiilor săi și să îi aduci ca o ofrandă DOMNULUI.
14 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe ya ọmọ Lefi sọ́tọ̀, kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, àwọn ọmọ Lefi yóò sì jẹ́ tèmi.
Astfel să îi separi pe leviți dintre copiii lui Israel și leviții vor fi ai mei.
15 “Lẹ́yìn tí ó ti wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, tí ó sì ti gbé wọn kalẹ̀ bí ẹbọ fífì nígbà náà ni kí wọn ó lọ máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
Și după aceea leviții să intre să facă serviciul tabernacolului întâlnirii și tu să îi cureți și să îi aduci ca ofrandă.
16 Nítorí pé àwọn ni ó jẹ́ ti Èmi pátápátá nínú àwọn ọmọ Israẹli. Mo ti gbà wọ́n fún ara mi dípò àwọn àkọ́bí àní àkọ́bí ọkùnrin gbogbo Israẹli.
Pentru că ei sunt în întregime dați mie dintre copiii lui Israel; în locul celor ce deschid fiecare pântece, a întâilor născuți ai tuturor copiilor lui Israel, i-am luat la mine.
17 Nítorí pé gbogbo àkọ́bí ọmọ lọ́kùnrin ní Israẹli jẹ́ tèmi, ti ènìyàn àti ti ẹranko, láti ọjọ́ tí mo ti pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ara mi.
Pentru că toți întâii născuți ai copiilor lui Israel sunt ai mei, deopotrivă om și animal, din ziua în care am lovit pe fiecare întâi născut în țara Egiptului, i-am sfințit pentru mine.
18 Mo sì ti gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí ọmọ ọkùnrin nínú Israẹli.
Și am luat pe leviți în locul tuturor întâilor născuți ai copiilor lui Israel.
19 Nínú Israẹli, mo fi àwọn ọmọ Lefi fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn láti máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé fun àwọn ọmọ Israẹli àti láti máa ṣe ètùtù fún wọn kí àjàkálẹ̀-ààrùn má ba à kọlu àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi mímọ́.”
Și din mijlocul copiilor lui Israel am dat pe leviți în dar lui Aaron și fiilor săi, pentru a face serviciul copiilor lui Israel în tabernacolul întâlnirii și pentru a face ispășire pentru copiii lui Israel, ca să nu fie nicio plagă printre copiii lui Israel, când copiii lui Israel se apropie de sanctuar.
20 Mose, Aaroni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Și Moise și Aaron și toată adunarea copiilor lui Israel, a făcut leviților conform cu tot ceea ce DOMNUL i-a poruncit lui Moise referitor la leviți, astfel le-au făcut copiii lui Israel.
21 Àwọn ọmọ Lefi wẹ ara wọn mọ́, wọ́n sì fọ aṣọ wọn. Aaroni sì mú wọn wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì níwájú Olúwa, Aaroni sì ṣe ètùtù fún wọn láti wẹ̀ wọ́n mọ́.
Și leviții au fost purificați și și-au spălat hainele; și Aaron i-a adus ca ofrandă înaintea DOMNULUI; și Aaron a făcut ispășire pentru ei ca să îi curețe.
22 Lẹ́yìn èyí àwọn ọmọ Lefi lọ sínú àgọ́ ìpàdé láti lọ máa ṣiṣẹ́ wọn lábẹ́ àbojútó Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Și după aceea leviții au intrat să facă serviciul în tabernacolul întâlnirii înaintea lui Aaron și înaintea fiilor săi, precum DOMNUL îi poruncise lui Moise referitor la leviți, astfel le-au făcut.
23 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
24 “Èyí ni ohun tó jẹ mọ́ àwọn ọmọ Lefi, láti ọmọ ọdún kẹẹdọ́gbọ̀n tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni kí ó máa kópa nínú iṣẹ́ àgọ́ ìpàdé.
Aceasta este ceea ce aparține leviților, de la vârsta de douăzeci și cinci de ani în sus, ei să intre pentru a servi în serviciul tabernacolului întâlnirii,
25 Ṣùgbọ́n ẹni tó bá ti pé ọmọ àádọ́ta ọdún gbọdọ̀ ṣíwọ́ nínú iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn nínú àgọ́, kí wọ́n sì má ṣiṣẹ́ mọ́.
Și de la vârsta de cincizeci de ani să înceteze să servească în serviciul acesta și să nu mai servească;
26 Wọ́n le máa ran àwọn arákùnrin wọn lọ́wọ́ nínú àgọ́ ìpàdé ṣùgbọ́n àwọn fúnra wọn kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Báyìí ni kí o ṣe pín iṣẹ́ fún àwọn ọmọ Lefi.”
Ci să servească cu frații lor în tabernacolul întâlnirii, pentru a păzi însărcinarea și să nu facă niciun serviciu. Astfel să le faci leviților referitor la porunca lor.

< Numbers 8 >