< Numbers 8 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
خداوند به موسی فرمود:
2 “Bá Aaroni sọ̀rọ̀ kí o wí fún un pé. ‘Nígbà tí ó bá ń to àwọn fìtílà, àwọn fìtílà méjèèje gbọdọ̀ tan ìmọ́lẹ̀ sí àyíká níwájú ọ̀pá fìtílà.’”
«به هارون بگو که وقتی چراغها را در چراغدان می‌گذارد طوری باشد که نور هفت چراغ، جلوی چراغدان بتابد.»
3 Aaroni sì ṣe bẹ́ẹ̀; ó to àwọn fìtílà náà tí wọ́n sì fi kojú síwájú lórí ọ̀pá fìtílà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
پس هارون همین کار را کرد. او چراغها را طوری کار گذاشت که نور آنها جلوی چراغدان بتابد، همان‌طور که خداوند به موسی فرمان داده بود.
4 Bí a ṣe ṣe ọ̀pá fìtílà náà nìyìí, a ṣe é láti ara wúrà lílù: láti ìsàlẹ̀ títí dé ibi ìtànná rẹ̀. Wọ́n ṣe ọ̀pá fìtílà náà gẹ́gẹ́ bí bátànì tí Olúwa fihan Mose.
چراغدان از تزیینات پایه گرفته تا شاخه‌هایش تمام از طلا ساخته شده بود. این چراغدان دقیقاً طبق همان طرحی ساخته شده بود که خداوند به موسی نشان داده بود.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
سپس خداوند به موسی فرمود:
6 “Yọ àwọn ọmọ Lefi kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, kí o sì wẹ̀ wọ́n mọ́.
«اکنون لاویان را از بقیهٔ قوم اسرائیل جدا کن و آنها را تطهیر نما.
7 Báyìí ni kí o ṣe wẹ̀ wọ́n mọ́. Wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ sí wọn lára, mú kí wọn ó fá irun ara wọn, kí wọn ó fọ aṣọ wọn, kí wọn ó ba à lè wẹ ara wọn mọ́ nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
این عمل را با پاشیدن آب طهارت بر آنها شروع نموده، سپس به آنان بگو که تمام موی بدن خود را تراشیده، لباسهایشان را بشویند و این‌گونه خود را تطهیر کنند.
8 Jẹ́ kí wọn ó mú akọ ọ̀dọ́ màlúù pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ rẹ̀ tí í ṣe ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò, kí ìwọ náà mú akọ ọ̀dọ́ màlúù kejì fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
از ایشان بخواه که یک گوسالۀ نر و هدیهٔ آردی آن را که از آرد مرغوب مخلوط با روغن تهیه شده با یک گوسالۀ نر دیگر برای قربانی گناه بیاورند.
9 Ìwọ ó sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú àgọ́ ìpàdé, kí o sì kó gbogbo àpapọ̀ ọmọ Israẹli jọ síbẹ̀ pẹ̀lú.
بعد در حضور همۀ جماعت اسرائیل، لاویان را به کنار در خیمهٔ ملاقات بیاور.
10 Báyìí ni kí o mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa, gbogbo ọmọ Israẹli yóò sì gbọ́wọ́ lé àwọn ọmọ Lefi lórí.
پس لاویان را به حضور خداوند بیاور و بنی‌اسرائیل دستهای خود را روی سر آنها بگذارند،
11 Aaroni yóò sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli wá, kí wọn lè máa ṣiṣẹ́ Olúwa.
و هارون آنان را به جای تمام قوم اسرائیل به عنوان هدیهٔ مخصوص، وقف خداوند نماید تا لاویان به جای تمامی قوم، خداوند را خدمت کنند.
12 “Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi bá gbé ọwọ́ wọn lé orí àwọn akọ ọmọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun sí Olúwa, láti ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Lefi.
«سپس لاویان دستهای خود را بر سر گاوها بگذارند، و تو یکی را به‌عنوان قربانی گناه و دیگری را به‌عنوان قربانی سوختنی به حضور خداوند تقدیم کن تا برای لاویان کفاره شود.
13 Mú kí àwọn ọmọ Lefi dúró níwájú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí ó sì gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì sí Olúwa.
آنگاه لاویان باید به عنوان هدیهٔ مخصوص به خداوند تقدیم شده توسط هارون و پسرانش به خدمت گماشته شوند.
14 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe ya ọmọ Lefi sọ́tọ̀, kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, àwọn ọmọ Lefi yóò sì jẹ́ tèmi.
به این طریق، لاویان را از میان بقیهٔ قوم اسرائیل جدا کن و ایشان از آن من خواهند بود.
15 “Lẹ́yìn tí ó ti wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, tí ó sì ti gbé wọn kalẹ̀ bí ẹbọ fífì nígbà náà ni kí wọn ó lọ máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
پس از آنکه لاویان را به این ترتیب تطهیر و وقف نمودی، ایشان خدمت خود را در خیمهٔ ملاقات آغاز خواهند کرد.
16 Nítorí pé àwọn ni ó jẹ́ ti Èmi pátápátá nínú àwọn ọmọ Israẹli. Mo ti gbà wọ́n fún ara mi dípò àwọn àkọ́bí àní àkọ́bí ọkùnrin gbogbo Israẹli.
«لاویان از میان تمام قوم اسرائیل به من تعلق دارند و من آنها را به جای همهٔ پسران ارشد بنی‌اسرائیل قبول کرده‌ام؛
17 Nítorí pé gbogbo àkọ́bí ọmọ lọ́kùnrin ní Israẹli jẹ́ tèmi, ti ènìyàn àti ti ẹranko, láti ọjọ́ tí mo ti pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ara mi.
زیرا همۀ نخست‌زادگان در میان قوم اسرائیل، خواه انسان و خواه حیوان، به من تعلق دارند. همان شبی که نخست‌زادگان مصری‌ها را کشتم اینها را به خود اختصاص دادم.
18 Mo sì ti gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí ọmọ ọkùnrin nínú Israẹli.
آری، من لاویان را به جای تمام نخست‌زادگان بنی‌اسرائیل پذیرفته‌ام
19 Nínú Israẹli, mo fi àwọn ọmọ Lefi fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn láti máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé fun àwọn ọmọ Israẹli àti láti máa ṣe ètùtù fún wọn kí àjàkálẹ̀-ààrùn má ba à kọlu àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi mímọ́.”
و من لاویان را به هارون و پسرانش هدیه می‌کنم. لاویان باید وظایف مقدّسی را که بر عهدهٔ قوم اسرائیل می‌باشد، در خیمهٔ ملاقات انجام داده، قربانیهای قوم را تقدیم نمایند و برای ایشان کفاره کنند تا وقتی بنی‌اسرائیل به قدس نزدیک می‌شوند بلایی بر سر آنها نیاید.»
20 Mose, Aaroni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
پس موسی و هارون و قوم اسرائیل با پیروی دقیق از دستورهایی که خداوند به موسی داده بود، لاویان را وقف نمودند.
21 Àwọn ọmọ Lefi wẹ ara wọn mọ́, wọ́n sì fọ aṣọ wọn. Aaroni sì mú wọn wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì níwájú Olúwa, Aaroni sì ṣe ètùtù fún wọn láti wẹ̀ wọ́n mọ́.
لاویان خود را طاهر ساخته، لباسهایشان را شستند و هارون آنان را به عنوان هدیهٔ مخصوص به خداوند تقدیم نمود. بعد به منظور تطهیر نمودن لاویان برای ایشان مراسم کفاره را بجا آورد.
22 Lẹ́yìn èyí àwọn ọmọ Lefi lọ sínú àgọ́ ìpàdé láti lọ máa ṣiṣẹ́ wọn lábẹ́ àbojútó Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
همه چیز درست طبق دستورهایی که خداوند به موسی داده بود، انجام گردید و به این ترتیب لاویان به عنوان دستیاران هارون و پسرانش، آمادهٔ خدمت در خیمهٔ ملاقات شدند.
23 Olúwa sọ fún Mose pé,
خداوند همچنین به موسی فرمود:
24 “Èyí ni ohun tó jẹ mọ́ àwọn ọmọ Lefi, láti ọmọ ọdún kẹẹdọ́gbọ̀n tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni kí ó máa kópa nínú iṣẹ́ àgọ́ ìpàdé.
«لاویان باید خدمت در خیمۀ ملاقات را از سن بیست و پنج سالگی یا بالاتر شروع کنند
25 Ṣùgbọ́n ẹni tó bá ti pé ọmọ àádọ́ta ọdún gbọdọ̀ ṣíwọ́ nínú iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn nínú àgọ́, kí wọ́n sì má ṣiṣẹ́ mọ́.
و در سن پنجاه سالگی بازنشسته شوند.
26 Wọ́n le máa ran àwọn arákùnrin wọn lọ́wọ́ nínú àgọ́ ìpàdé ṣùgbọ́n àwọn fúnra wọn kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Báyìí ni kí o ṣe pín iṣẹ́ fún àwọn ọmọ Lefi.”
پس از بازنشستگی می‌توانند در خیمهٔ ملاقات، برادران خود را در انجام وظایفشان یاری دهند، ولی خود، مستقیم مسئولیتی نخواهند داشت. به این ترتیب وظایف لاویان را به ایشان محول کن.»

< Numbers 8 >