< Numbers 8 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord spak to Moises, and seide, Speke thou to Aaron,
2 “Bá Aaroni sọ̀rọ̀ kí o wí fún un pé. ‘Nígbà tí ó bá ń to àwọn fìtílà, àwọn fìtílà méjèèje gbọdọ̀ tan ìmọ́lẹ̀ sí àyíká níwájú ọ̀pá fìtílà.’”
and thou schalt seie to hym, Whanne thou hast sett seuene launternes, the candilstike be reisid in the south part; therfor comaunde thou this, that the lanternes biholde euene ayens the north to the boord of looues of `settyng forth, tho schulen schyne ayenus that part which the candilstike biholdith.
3 Aaroni sì ṣe bẹ́ẹ̀; ó to àwọn fìtílà náà tí wọ́n sì fi kojú síwájú lórí ọ̀pá fìtílà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And Aaron dide, and puttide lanternes on the candilstike, as the Lord comaundide to Moises.
4 Bí a ṣe ṣe ọ̀pá fìtílà náà nìyìí, a ṣe é láti ara wúrà lílù: láti ìsàlẹ̀ títí dé ibi ìtànná rẹ̀. Wọ́n ṣe ọ̀pá fìtílà náà gẹ́gẹ́ bí bátànì tí Olúwa fihan Mose.
Sotheli this was the makyng of the candilstike; it was of gold betun out with hameris, as wel the myddil stok as alle thingis that camen forth of euer eithir side of the yeerdis; bi the saumple `whych the Lord schewide to Moises, so he wrouyte the candilstike.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord spak to Moises,
6 “Yọ àwọn ọmọ Lefi kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, kí o sì wẹ̀ wọ́n mọ́.
and seide, Take thou Leuytis fro the myddis of the sones of Israel;
7 Báyìí ni kí o ṣe wẹ̀ wọ́n mọ́. Wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ sí wọn lára, mú kí wọn ó fá irun ara wọn, kí wọn ó fọ aṣọ wọn, kí wọn ó ba à lè wẹ ara wọn mọ́ nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
and thou schalt clense hem bi this custom. Be thei spreynt with watir of clensyng, and schaue thei alle the heeris of her fleisch. And whanne thei han waische her clothis and ben clensid, take thei an oxe of drooues,
8 Jẹ́ kí wọn ó mú akọ ọ̀dọ́ màlúù pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ rẹ̀ tí í ṣe ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò, kí ìwọ náà mú akọ ọ̀dọ́ màlúù kejì fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
and the fletyng sacrifice therof, flour spreynt to gidere with oile; forsothe thou schalt take another oxe of the drooue for synne;
9 Ìwọ ó sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú àgọ́ ìpàdé, kí o sì kó gbogbo àpapọ̀ ọmọ Israẹli jọ síbẹ̀ pẹ̀lú.
and thou schalt present the Leuytis bifor the tabernacle of boond of pees, whanne al the multitude of the sones of Israel is clepid togidere.
10 Báyìí ni kí o mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa, gbogbo ọmọ Israẹli yóò sì gbọ́wọ́ lé àwọn ọmọ Lefi lórí.
And whanne the Leuytis ben bifor the Lord, the sones of Israel schulen sette her hondis on hem;
11 Aaroni yóò sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli wá, kí wọn lè máa ṣiṣẹ́ Olúwa.
and Aaron schal offre the Leuytis in the siyt of the Lord, a yifte of the sones of Israel, that thei serue in the seruice `of hym.
12 “Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi bá gbé ọwọ́ wọn lé orí àwọn akọ ọmọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun sí Olúwa, láti ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Lefi.
Also the Leuytis schulen sette her hondis on the heedis of the oxun, of whiche oxun thou schalt make oon for synne, and the tother in to brent sacrifice of the Lord, that thou preye for hem.
13 Mú kí àwọn ọmọ Lefi dúró níwájú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí ó sì gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì sí Olúwa.
And thou schalt ordeyne the Leuytis in the siyt of Aaron, and of hise sones, and thou schalt sacre hem offrid to the Lord;
14 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe ya ọmọ Lefi sọ́tọ̀, kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, àwọn ọmọ Lefi yóò sì jẹ́ tèmi.
and thou schalt departe hem fro the myddis of the sones of Israel, that thei be myne.
15 “Lẹ́yìn tí ó ti wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, tí ó sì ti gbé wọn kalẹ̀ bí ẹbọ fífì nígbà náà ni kí wọn ó lọ máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
And aftirward entre thei in to the tabernacle of boond of pees, that thei serue me; and so thou schalt clense and schalt halewe hem, in to an offryng of the Lord, for bi fre yifte thei ben youun to me of the sones of Israel.
16 Nítorí pé àwọn ni ó jẹ́ ti Èmi pátápátá nínú àwọn ọmọ Israẹli. Mo ti gbà wọ́n fún ara mi dípò àwọn àkọ́bí àní àkọ́bí ọkùnrin gbogbo Israẹli.
Y haue take hem for the firste gendrid thingis that openen ech wombe in Israel;
17 Nítorí pé gbogbo àkọ́bí ọmọ lọ́kùnrin ní Israẹli jẹ́ tèmi, ti ènìyàn àti ti ẹranko, láti ọjọ́ tí mo ti pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ara mi.
for alle the firste gendrid thingis of the sones of Israel ben myne, as wel of men as of beestis, fro the dai in which Y smoot ech firste gendrid thing in the loond of Egipt, Y halewide hem to me.
18 Mo sì ti gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí ọmọ ọkùnrin nínú Israẹli.
And Y took the Leuytis for alle the firste gendrid children of the sones of Israel;
19 Nínú Israẹli, mo fi àwọn ọmọ Lefi fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn láti máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé fun àwọn ọmọ Israẹli àti láti máa ṣe ètùtù fún wọn kí àjàkálẹ̀-ààrùn má ba à kọlu àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi mímọ́.”
and Y yaf hem bi fre yifte to Aaron and hise sones, fro the myddis of the puple, that thei serue me for Israel, in the tabernacle of boond of pees, and that thei preie for hem, lest veniaunce be in the puple, if thei ben hardi to neiye to the seyntuarye.
20 Mose, Aaroni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And Moises and Aaron, and al the multitude of the sones of Israel, diden on the Leuitis tho thingis that the Lord comaundide to Moyses.
21 Àwọn ọmọ Lefi wẹ ara wọn mọ́, wọ́n sì fọ aṣọ wọn. Aaroni sì mú wọn wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì níwájú Olúwa, Aaroni sì ṣe ètùtù fún wọn láti wẹ̀ wọ́n mọ́.
And thei weren clensid, and thei waischiden her clothis; and Aaron reiside hem in the siyt of the Lord, and preiede for hem,
22 Lẹ́yìn èyí àwọn ọmọ Lefi lọ sínú àgọ́ ìpàdé láti lọ máa ṣiṣẹ́ wọn lábẹ́ àbojútó Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
that thei schulen be clensid, and schulden entre to her offices in to the tabernacle of boond of pees, bifor Aaron and hise sones; as the Lord comaundide to Moises of the Leuytis, so it was don.
23 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord spak to Moises, and seide, This is lawe of Leuytis;
24 “Èyí ni ohun tó jẹ mọ́ àwọn ọmọ Lefi, láti ọmọ ọdún kẹẹdọ́gbọ̀n tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni kí ó máa kópa nínú iṣẹ́ àgọ́ ìpàdé.
fro fyue and twentithe yeer and aboue thei schulen entre, for to mynystre in the tabernacle of boond of pees;
25 Ṣùgbọ́n ẹni tó bá ti pé ọmọ àádọ́ta ọdún gbọdọ̀ ṣíwọ́ nínú iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn nínú àgọ́, kí wọ́n sì má ṣiṣẹ́ mọ́.
and whanne thei han fillid the fiftithe yeer of age, thei schulen ceesse to serue.
26 Wọ́n le máa ran àwọn arákùnrin wọn lọ́wọ́ nínú àgọ́ ìpàdé ṣùgbọ́n àwọn fúnra wọn kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Báyìí ni kí o ṣe pín iṣẹ́ fún àwọn ọmọ Lefi.”
And thei schulen be the mynystris of her bretheren in the tabernacle of boond of pees, that thei kepe tho thingis that ben bitakun to hem; sothely thei schulen not do tho werkis; thus thou schalt dispose Leuytis in her kepyngis.

< Numbers 8 >