< Numbers 7 >

1 Nígbà tí Mose ti parí gbígbé àgọ́ dúró, ó ta òróró sí i, ó sì yà á sí mímọ́ pẹ̀lú gbogbo àwọn ohun èlò rẹ̀, Ó tún ta òróró sí pẹpẹ, ó sì yà á sí mímọ́ pẹ̀lú gbogbo ohun èlò rẹ̀.
And it came to pass, on the day when Moses made an end of rearing up the habitation and anointing it, and hallowing it, and all the furniture thereof, and the altar, and all the utensils thereof, —both of anointing them, and hallowing them,
2 Nígbà náà ni àwọn olórí Israẹli, àwọn ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, àwọn alábojútó àwọn tí a kà náà mú ọrẹ wá.
that the princes of Israel, the heads of their ancestral houses, made an offering, —they being princes of the tribes, they being the men who stood over them who were numbered:
3 Wọ́n mú ọrẹ wọn wá síwájú Olúwa: kẹ̀kẹ́ ẹrù mẹ́fà ti abo, àti akọ màlúù kan láti ọ̀dọ̀ olórí kọ̀ọ̀kan àti kẹ̀kẹ́ ẹrù kan láti ọ̀dọ̀ olórí méjì. Wọ́n sì kó wọn wá sí iwájú àgọ́.
yea then brought they in as their offering, before Yahweh—six covered waggons, and twelve oxen, a waggon for every two of the princes and an ox for each one, —yea they brought them near before the habitation.
4 Olúwa sọ fún Mose pé,
Then spake Yahweh unto Moses, saying:
5 “Gba gbogbo nǹkan wọ̀nyí lọ́wọ́ wọn, kí wọ́n ba à lè wúlò fún iṣẹ́ inú àgọ́ ìpàdé. Kó wọn fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan bá ṣe nílò rẹ̀.”
Take [them] of them, so shall they be for doing the laborious work of the tent of meeting, —and thou shalt give them unto the Levites, to every man according to the need of his laborious work.
6 Mose sì kó àwọn kẹ̀kẹ́ ẹrù àti akọ màlúù náà fún àwọn ọmọ Lefi.
So Moses took the waggons, and the oxen, —and gave them unto the Levites:
7 Ó fún àwọn ọmọ Gerṣoni ní kẹ̀kẹ́ méjì àti akọ màlúù mẹ́rin, gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn ṣe jẹ mọ́.
two of the waggons and four of the oxen, gave he unto the sons of Gershon, —according to the need of their laborious work;
8 Ó fún àwọn ọmọ Merari ní kẹ̀kẹ́ mẹ́rin àti akọ màlúù mẹ́jọ gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn ṣe jẹ mọ́. Gbogbo wọn wà lábẹ́ àkóso Itamari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà.
and four of the waggons, and eight of the oxen, gave he unto the sons of Merari, —according to the need of their laborious work, in the hand of Ithamar son of Aaron the priest;
9 Ṣùgbọ́n Mose kò fún àwọn ọmọ Kohati ní nǹkan kan nítorí pé èjìká wọn ni wọn yóò fi ru àwọn ohun mímọ́ èyí tí ó jẹ́ ojúṣe tiwọn.
but, unto the sons of Kohath, gave he none, —because as to the laborious work of the sanctuary which pertained unto them, upon their shoulders, were they to carry it.
10 Nígbà tí a ta òróró sórí pẹpẹ. Àwọn olórí mú àwọn ọrẹ wọn wá fún ìyàsímímọ́ rẹ̀, wọ́n sì kó wọn wá síwájú pẹpẹ.
So then the princes offered for the dedication of the altar, on the day it was anointed, —yea the princes offered their oblation before the altar,
11 Nítorí tí Olúwa ti sọ fún Mose pé, “Olórí kọ̀ọ̀kan ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ni yóò máa mú ọrẹ tirẹ̀ wá fún ìyàsímímọ́ pẹpẹ.”
And Yahweh said unto Moses: Each prince on his appointed day, thus shall they offer their oblation, for the dedication of the altar.
12 Ẹni tí ó mú ọrẹ tirẹ̀ wá ní ọjọ́ kìn-ín-ní Nahiṣoni ọmọ Amminadabu láti inú ẹ̀yà Juda.
And so it was, that, he who on the first day, offered his oblation, —was Nahshon son of Amminadab of the tribe of Judah;
13 Ọrẹ rẹ̀ jẹ́: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò ti fàdákà tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́ àwo kọ̀ọ̀kan kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
and his offering, was—one charger of silver, a hundred and thirty shekels, the weight thereof, one tossing bowl of silver, seventy shekels by the shekel of the sanctuary, —both of them, full of fine meal overflowed with oil for a meal-offering;
14 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;
one spoon of ten shekels of gold full of incense;
15 ọ̀dọ́ akọ màlúù kan, àgbò kan, akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun,
one choice young bullock one ram one he-lamb of the first year, as an ascending-sacrifice;
16 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀,
one young he-goat, as a sin-bearer;
17 akọ màlúù méjì, àgbò márùn-ún, òbúkọ ọlọ́dún kan márùn-ún tí wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Wọ̀nyí ni ọrẹ Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
and as a peace-offering, two oxen, five rams five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Nashon, son of Amminadab.
18 Ní ọjọ́ kejì ni Netaneli ọmọ Suari olórí àwọn ọmọ Isakari mú ọrẹ tirẹ̀ wá.
On the second day, Nethanel, son of Zuar, prince of Issachar, brought his offering.
19 Ọrẹ tí ó kó wá ní: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
He offered as his oblation—one charger of silver, a hundred and thirty shekels, the weight thereof, one tossing bowl of silver, seventy shekels by the shekel of the sanctuary, —both of them, full of fine meal overflowed with oil as a meal-offering;
20 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí,
one spoon of ten [shekels] of gold full of incense;
21 ọ̀dọ́ akọ màlúù kan, àgbò kan, àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan, fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock one ram one he-lamb of the first year, as an ascending-sacrifice;
22 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat, as a sin-bearer;
23 Màlúù méjì, àgbò márùn-ún, akọ ewúrẹ́ márùn-ún àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún tí wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Netaneli ọmọ Suari.
and, as peace-offering two oxen, five rams, five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Nethanel, son of Zuar.
24 Eliabu ọmọ Heloni, olórí àwọn ọmọ Sebuluni ni ó mú ọrẹ rẹ̀ wá ní ọjọ́ kẹta.
On the third day, the prince of the sons of Zebulun, —Eliab, son of Helon:
25 Àwọn ọrẹ rẹ̀ ni: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
his offering, —one charger of silver a hundred and thirty shekels, the weight thereof, one tossing bowl of silver, seventy shekels by the shekel of the sanctuary, —both of them, full of fine meal overflowed with oil as a meal-offering;
26 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;
one spoon, of ten [shekels] of gold full of incense;
27 akọ ọ̀dọ́ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock, one ram, one he-lamb of the first year, as an ascending-sacrifice;
28 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat, as a sin-bearer;
29 Màlúù méjì, àgbò márùn-ún, òbúkọ márùn-ún akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún tí wọn o fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Eliabu ọmọ Heloni.
and as a peace-offering, two oxen, five rams five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Eliab, son of Helon.
30 Elisuri ọmọ Ṣedeuri olórí àwọn ọmọ Reubeni ni ó mú ọrẹ wá ní ọjọ́ kẹrin.
On the fourth day, the prince of he sons of Reuben, —Elizur, son of Shedeur:
31 Ọrẹ rẹ̀ ni: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
his offering, one charger of silver, a hundred and thirty [shekels], the weight thereof, one tossing bowl of Silver, seventy shekels by the shekel of the sanctuary, —both of them, full of fine meal overflowed with oil, as a meal-offering;
32 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí,
one spoon of ten [shekels] of gold full of incense:
33 akọ ọ̀dọ́ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock one ram, one he-lamb of the first year, as an ascending-sacrifice;
34 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat for a sin-bearer;
35 màlúù méjì, àgbò márùn-ún, akọ ewúrẹ́ márùn-ún àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún tí wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
and as a peace-offering, two oxen, five rams five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Elizur, son of Shedeur.
36 Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai, olórí àwọn ọmọ Simeoni ni ó mú ọrẹ wá ní ọjọ́ karùn-ún.
On the fifth day, the prince of the sons of Simeon, —Shelumiel, son of Zurishaddai:
37 Ọrẹ tí ó kó wá ni: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
his offering, one charger of silver a hundred and thirty shekels, the weight thereof, one tossing bowl of silver, seventy shekels by the shekel of the sanctuary; both of them, full of fine meal overflowed with oil as a meal-offering;
38 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;
one spoon of ten [shekels] of gold, full of incense;
39 akọ ọ̀dọ́ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock one ram one he-lamb of the first year as an ascending-sacrifice;
40 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat as a sin-bearer;
41 màlúù méjì, àgbò márùn-ún, akọ ewúrẹ́ márùn-ún àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún tí wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
and, as a peace-offering, two oxen, five rams, five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Shelumiel, son of Zurishaddai.
42 Eliasafu ọmọ Deueli olórí àwọn ọmọ Gadi ní ó mú ọrẹ rẹ̀ wá ní ọjọ́ kẹfà.
On the sixth day, the prince of the sons of Gad, —Eliasaph, son of Deuel:
43 Ọrẹ rẹ̀ ni: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
his offering, one charger of silver, a hundred and thirty [shekels], the weight thereof, one tossing bowl, of silver, seventy shekels, by the shekel of the sanctuary, —both of them, full of fine meal overflowed with oil, as a meal-offering;
44 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;
one spoon of ten [shekels] of gold full of incense;
45 akọ ọ̀dọ́ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock one ram one he-lamb of the first year, as an ascending-sacrifice;
46 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat as a sin-bearer;
47 màlúù méjì, àgbò márùn-ún, akọ ewúrẹ́ márùn-ún àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún, wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Eliasafu ọmọ Deueli.
and as a peace-offering, two oxen, five rams, five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Eliasaph, son of Deuel.
48 Eliṣama ọmọ Ammihudu, olórí àwọn ọmọ Efraimu ni ó mú ọrẹ rẹ̀ wá ní ọjọ́ keje.
On the seventh day, the prince of the sons of Ephraim, —Elishama, son of Ammihud:
49 Ọrẹ rẹ̀ ni: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
his offering, one charger of silver a hundred and thirty shekels, the weight thereof, one tossing bowl of silver, seventy shekels, by the shekel of the sanctuary, —both of them, full of fine meal overflowed with oil as a meal-offering;
50 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;
one spoon of ten [shekels] of gold, full of incense;
51 akọ ọ̀dọ́ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock, one ram, one he-lamb of the first year, as an ascending-sacrifice;
52 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat, as a sin-bearer;
53 màlúù méjì, àgbò márùn-ún, akọ ewúrẹ́ márùn-ún àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún, tí wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Eliṣama ọmọ Ammihudu.
and as a peace-offering, two oxen, five rams five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Elishama, son of Ammihud.
54 Gamalieli ọmọ Pedasuri, olórí àwọn ọmọ Manase ni ó mú ọrẹ tirẹ̀ wá ní ọjọ́ kẹjọ.
On the eighth day, the prince of the sons of Manasseh, —Gamaliel, son of Pedahzur:
55 Ọrẹ tirẹ̀ ni: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
his offering, one charger of silver, a hundred and thirty [shekels], the weight thereof, one tossing bowl, of silver, seventy shekels by the shekel of the sanctuary, —both of them, full of fine meal overflowed with oil as a meal-offering;
56 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;
one spoon of ten [shekels] of gold full of incense;
57 akọ ọ̀dọ́ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock one ram one he-lamb of the first year as an ascending-sacrifice:
58 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat, as a sin-bearer;
59 màlúù méjì, àgbò márùn-ún, akọ ewúrẹ́ márùn-ún àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún tí wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Gamalieli ọmọ Pedasuri.
and as a peace-offering, two oxen, five rams five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Gamaliel son of Pedahzur.
60 Abidani ọmọ Gideoni, olórí àwọn ọmọ Benjamini ni ó mú ọrẹ tirẹ̀ wá ní ọjọ́ kẹsànán.
On the ninth day, the prince of the sons of Benjamin, —Abidan, son of Gideoni:
61 Ọrẹ rẹ̀ ni: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
his offering, one charger of silver, a hundred and thirty [shekels], the weight thereof, —one tossing bowl of silver, seventy shekels by the shekel of the sanctuary, —both of them, full of fine meal overflowed with oil, as a meal-offering;
62 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;
one spoon, of ten [shekels] of gold full of incense;
63 akọ ọ̀dọ́ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock, one ram, one he-lamb of the first year as an ascending-sacrifice;
64 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat as a sin-bearer;
65 màlúù méjì, àgbò márùn-ún, akọ ewúrẹ́ márùn-ún àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún tí wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Abidani ọmọ Gideoni.
and as a peace-offering, two oxen, five rams, five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Abidan, son of Gideoni.
66 Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai, olórí àwọn ọmọ Dani ni ó mú ọrẹ tirẹ̀ wá ní ọjọ́ kẹwàá.
On the tenth day, the prince of the sons of Dan, Ahiezer son of Ammishaddai:
67 Ọrẹ rẹ̀ ni: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
his offering, one charger of silver a hundred and thirty [shekels], the weight thereof, —one tossing bowl of silver, seventy shekels by the shekel of the sanctuary, —both of them, full of fine meal overflowed with oil as a meal-offering;
68 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;
one spoon, of ten [shekels] of gold, full of incense;
69 akọ ọ̀dọ́ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock one ram one he-lamb of the first year as an ascending-sacrifice;
70 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat, as a sin-bearer;
71 àti fún ẹbọ ti ẹbọ àlàáfíà, akọ màlúù méjì, àgbò márùn-ún, òbúkọ márùn-ún, akọ ọ̀dọ́-àgùntàn márùn-ún ọlọ́dún kan. Èyí ni ọrẹ ẹbọ tí Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
and as a peace-offering, two oxen, five rams, five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Ahiezer, son of Ammishaddai.
72 Pagieli ọmọ Okanri, olórí àwọn ọmọ Aṣeri ni ó mú ọrẹ rẹ̀ wá ní ọjọ́ kọkànlá.
On the eleventh day, the prince of the sons of Asher, Pagiel son of Ochran;
73 Ọrẹ rẹ̀ ni: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
his offering, one charger of silver, a hundred and thirty [shekels], the weight thereof, one tossing bowl, of silver, seventy shekels by the shekel of the sanctuary, —both of them, full of fine meal overflowed with oil as a meal-offering;
74 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;
one spoon of ten [shekels] of gold, full of incense;
75 akọ ọ̀dọ́ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock, one ram one he-lamb of the first year, as an ascending-sacrifice;
76 akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat, as a sin-bearer;
77 màlúù méjì, àgbò márùn-ún, akọ ewúrẹ́ márùn-ún àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún, tí wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Pagieli ọmọ Okanri.
and as a peace-offering, two oxen, five rams, five he-goats, five he-lambs of the first year, —this, was the offering of Pagiel, son of Ochran.
78 Ahira ọmọ Enani, olórí àwọn Naftali ni ó mú ọrẹ rẹ̀ wá ní ọjọ́ kejìlá.
On the twelfth day, the prince of the sons of Naphtali, Ahira, son of Enan:
79 Ọrẹ rẹ̀ ni: àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje ṣékélì àti àwokòtò tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, àwo kọ̀ọ̀kan sì kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí á fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;
his offering, one charger of silver a hundred and thirty [shekels], the weight thereof, one tossing bowl of silver, seventy shekels by the shekel of the sanctuary, both of them, full of fine meal overflowed with oil, as a meal-offering;
80 àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;
one spoon of ten [shekels] of gold full of incense;
81 akọ ọ̀dọ́ màlúù kan àgbò kan, àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;
one choice young bullock one ram one he-lamb of the first year, as an ascending-sacrifice;
82 akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;
one young he-goat as a sin-bearer;
83 màlúù méjì, àgbò márùn-ún, akọ ewúrẹ́ márùn-ún àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún, wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Ahira ọmọ Enani.
and, as a peace-offering, two oxen, five rams five he-goats, five he-lambs of the first year, this, was the offering of Ahira, son of Enan.
84 Wọ̀nyí ni ọrẹ tí àwọn olórí àwọn ọmọ Israẹli mú wá fún ìyàsímímọ́ pẹpẹ nígbà tí wọ́n ta òróró sí i lórí: àwo fàdákà méjìlá, àwokòtò méjìlá, àwo wúrà méjìlá.
This, was the offering for the dedication of the altar in the day when it was anointed, from the princes of Israel, —twelve chargers of silver twelve tossing bowls of silver, twelve spoons of gold;
85 Àwo fàdákà kọ̀ọ̀kan wọn àádóje ṣékélì, àwokòtò kọ̀ọ̀kan sì wọn àádọ́rin. Àpapọ̀ gbogbo àwo fàdákà jẹ́ egbèjìlá ṣékélì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́.
a hundred and thirty [shekels], each charger of silver, and seventy, each tossing bowl, —all the silver of the vessels, two thousand and four hundred [shekels], by the shekel of the sanctuary;
86 Ọ̀kọ̀ọ̀kan àwo wúrà méjìlá tí tùràrí kún inú wọn ṣékélì mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́. Àpapọ̀ ìwọ̀n gbogbo àwo wúrà jẹ́ ọgọ́fà ṣékélì.
twelve spoons of gold full of incense, ten shekels each spoon by the shekel of the sanctuary, —all the gold of the spoons, a hundred and twenty [shekels].
87 Àpapọ̀ iye ẹran fún ẹbọ sísun jẹ́ akọ ọ̀dọ́ màlúù méjìlá, àgbò méjìlá, akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan méjìlá pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ. Akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́ méjìlá.
All the herd for the ascending-sacrifice, —twelve bullocks twelve rams twelve he-lambs of the first year with their meal-offering, —twelve young he-goats for the bearing of sin;
88 Àpapọ̀ iye ẹran fún ọrẹ àlàáfíà jẹ́ màlúù mẹ́rìnlélógún, ọgọ́ta àgbò, ọgọ́ta akọ ewúrẹ́ àti ọgọ́ta akọ ọ̀dọ́ màlúù ọlọ́dún kan. Wọ̀nyí ni ọrẹ ìyàsímímọ́ pẹpẹ lẹ́yìn tí a ta òróró sí i.
and all the herd for the peace-offering, twenty-four bullocks sixty rams, sixty he-goats sixty he-lambs of the first year, —this, was the offering for the dedication of the altar, after it was anointed.
89 Nígbà tí Mose wọ inú àgọ́ ìpàdé láti bá Olúwa sọ̀rọ̀, Olúwa sì sọ̀rọ̀ sí i láti àárín àwọn kérúbù méjì láti orí ìtẹ́ àánú tí ó bo àpótí ẹ̀rí, ohùn náà sì bá Mose sọ̀rọ̀.
And when Moses entered into the tent of meeting, that He might speak with him, then heard he the Voice speaking unto him from off the propitiatory that was upon the ark of the testimony, from between the two cherubim, —so He spake unto him.

< Numbers 7 >