< Numbers 6 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ pàtàkì, ẹ̀jẹ́ ìyara-ẹni-sọ́tọ̀ sí Olúwa nípa àìgé irun orí (Nasiri),
Vorbește copiilor lui Israel și spune-le: Când, fie un bărbat, fie o femeie, se vor separa ca să facă o promisiune de nazireu, să se separe DOMNULUI,
3 irú ẹni bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ yàgò fún wáìnì tàbí ọtí líle, ọtí wáìnì kíkan àti àwọn ohun mímu mìíràn tó bá kan. Kò gbọdọ̀ mu èso àjàrà tàbí kí ó jẹ èso àjàrà tútù tàbí gbígbẹ.
El să se separe de vin și băutură tare și să nu bea deloc oțet din vin, sau oțet din băutură tare, nici să nu bea vreo licoare din struguri, nici să nu mănânce struguri proaspeți sau uscați.
4 Níwọ́n ìgbà tí ó sì jẹ́ Nasiri, ní kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi èso àjàrà ṣe, ìbá à ṣe kóró tàbí èèpo rẹ̀.
În toate zilele separării sale să nu mănânce nimic din ceea ce este făcut din vița de vie, de la sâmburi până la pieliță.
5 “‘Ní gbogbo ìgbà ẹ̀jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, kí abẹ kankan má ṣe kàn án ní orí. Ó gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ títí tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa yóò fi pé; ó gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí rẹ̀ gùn.
În toate zilele promisiunii lui de separare, briciul să nu treacă peste capul lui, până ce se vor împlini zilele, în care el s-a separat pentru DOMNUL, va fi sfânt și să lase șuvițele părului capului său să crească.
6 “‘Ní gbogbo àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa kò gbọdọ̀ súnmọ́ òkú ènìyàn.
În toate zilele cât este el separat pentru DOMNUL, să nu vină la niciun trup mort.
7 Ìbá à ṣe òkú baba, àti ìyá rẹ̀, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin tàbí àbúrò rẹ̀, kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí wọn, nítorí pé àmì ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Ọlọ́run wà ní orí rẹ̀.
El să nu se facă necurat nici pentru tatăl său, nici pentru mama sa, nici pentru fratele său, nici pentru sora sa, când ei mor, deoarece consacrarea Dumnezeului său este asupra capului său.
8 Ní gbogbo àsìkò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
În toate zilele separării sale el este sfânt pentru DOMNUL.
9 “‘Bí ẹnìkan bá kú ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òjijì, tí ó sì ba irun rẹ̀ tó yà sọ́tọ̀ jẹ́; ó gbọdọ̀ gé irun rẹ̀ ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe ọjọ́ keje.
Și dacă vreun om moare dintr-odată lângă el, iar el și-a pângărit capul consacrării sale, atunci să își radă capul în ziua curățirii sale; în ziua a șaptea să și-l radă.
10 Ní ọjọ́ kẹjọ, yóò mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé méjì wá sọ́dọ̀ àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Și în ziua a opta să aducă două turturele, sau doi porumbei tineri, la preot, la ușa tabernacolului întâlnirii;
11 Àlùfáà yóò fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun láti fi ṣe ètùtù fún un nítorí pé ó ti ṣẹ̀ nípa wíwà níbi tí òkú ènìyàn wà. Yóò sì ya orí rẹ̀ sí mímọ́ ní ọjọ́ náà gan an.
Și preotul să ofere pe una ca ofrandă pentru păcat și pe cealaltă ca ofrandă arsă și să facă ispășire pentru el, pentru că a păcătuit prin mort și capul să și-l sfințească în aceeași zi.
12 Ó gbọdọ̀ ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ sí Olúwa fún àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀, ó sì gbọdọ̀ mú akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀bi. Kò sì ní í ka àwọn ọjọ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀ nítorí pé ó tí ba ara rẹ̀ jẹ́ ní àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀.
Și să consacre DOMNULUI zilele separării sale și să aducă un miel de un an ca ofrandă pentru fărădelege, dar zilele care au fost mai înainte vor fi pierdute, deoarece separarea lui a fost pângărită.
13 “‘Èyí ni òfin fún Nasiri nígbà tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ bá pé. Wọn ó mu wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Și aceasta este legea nazireului, când zilele separării sale vor fi împlinite, să fie adus la ușa tabernacolului întâlnirii,
14 Níbẹ̀ ni yóò ti mú ọrẹ wá fún Olúwa, akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan tí kò ní àbùkù fún ẹbọ sísun àti ẹgbọrọ-àgùntàn ọlọ́dún kan, tí kò ní àbùkù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àgbò kan tí kò ní àbùkù fún ọrẹ àlàáfíà,
Și să aducă darul său DOMNULUI, un miel de un an, fără cusur, ca ofrandă arsă și o mielușea de un an, fără cusur, ca ofrandă pentru păcat, și un berbec, fără cusur, ca ofrande de pace.
15 pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu, apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí a kò fi ìwúkàrà ṣe, àkàrà tí a fi ìyẹ̀fun dáradára pò mọ́ òróró àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a fi òróró sọjọ̀ lé lórí.
Și un coș de azime, turte din floarea făinii, amestecate cu untdelemn, și lipii din azime, unse cu untdelemn, și darul lor de mâncare și darurile lor de băutură.
16 “‘Àlùfáà yóò gbé gbogbo rẹ̀ wá síwájú Olúwa, yóò sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun.
Și preotul să le aducă înaintea DOMNULUI și să aducă ofranda lui pentru păcat și ofranda lui arsă.
17 Àlùfáà yóò fi àgbò náà rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa, pẹ̀lú apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà; yóò rú ẹbọ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu.
Și să aducă DOMNULUI berbecul ca sacrificiu al ofrandelor de pace, cu coșul de azime; preotul să aducă de asemenea și darul lui de mâncare și darul lui de băutură.
18 “‘Nígbà náà ni Nasiri náà yóò fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Yóò fi irun náà sínú iná tó wà lábẹ́ ẹbọ àlàáfíà.
Și nazireul să își radă capul separării sale la ușa tabernacolului întâlnirii și să ia părul de pe capul separării sale și să îl pună în focul care este sub sacrificiul ofrandelor de pace.
19 “‘Lẹ́yìn tí Nasiri bá ti fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ tan, àlùfáà yóò mú apá àgbò bíbọ̀, àkàrà aláìwú kan àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí kò ní ìwúkàrà láti inú apẹ̀rẹ̀ yóò sì kó gbogbo rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
Și preotul să ia spata fiartă a berbecului și o turtă nedospită din coș și o lipie nedospită și să le pună pe mâinile nazireului, după ce părul separării sale a fost ras.
20 Àlùfáà yóò fi gbogbo rẹ̀ níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì, wọ́n jẹ́ mímọ́, wọ́n sì jẹ́ ti àlùfáà pẹ̀lú igẹ̀ tí a fì àti itan tí wọ́n mú wá. Lẹ́yìn èyí, Nasiri náà lè mu wáìnì.
Și preotul să le legene ca ofrandă legănată înaintea DOMNULUI, acesta este sfânt pentru preot, cu pieptul legănat și cu spata săltată și după aceea nazireul poate bea vin.
21 “‘Èyí ni òfin Nasiri tó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ rẹ̀ sí Olúwa, yóò wà ní ìbámu pẹ̀lú ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Nasiri, ní àfikún sí àwọn ohun mìíràn tó lágbára láti mú wá. Ó gbọdọ̀ mú ẹ̀jẹ́ tó jẹ́ ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin Nasiri.’”
Aceasta este legea nazireului, care a jurat, și a darului său către DOMNUL, pentru separarea sa, în afară de ceea ce îi va da mâna, conform cu jurământul, pe care l-a jurat, astfel trebuie să facă după legea separării sale.
22 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
23 “Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, ‘Báyìí ni kí ẹ ṣe máa súre fún àwọn ọmọ Israẹli. Ẹ sọ fún wọn pé,
Vorbește lui Aaron și fiilor săi, spunând: Astfel să binecuvântați pe copiii lui Israel, spunându-le:
24 “‘“Kí Olúwa bùkún un yín, kí ó sì pa yín mọ́.
DOMNUL să te binecuvânteze și să te țină;
25 Kí Olúwa kí o mú ojú rẹ̀ kí ó mọ́lẹ̀ sí i yín lára. Kí ó sì ṣàánú fún un yín.
Să facă DOMNUL să strălucească fața sa peste tine și să aibă har fața de tine;
26 Kí Olúwa bojú wò yín, kí ó sì fún un yín ní àlàáfíà.”’
Să înalțe DOMNUL înfățișarea sa peste tine și să îți dea pacea.
27 “Báyìí ni wọn ó ṣe fi orúkọ mi sára àwọn ọmọ Israẹli, Èmi ó sì bùkún wọn.”
Și ei să pună numele meu peste copiii lui Israel, iar eu îi voi binecuvânta.

< Numbers 6 >