< Numbers 5 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
I rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn ó lé ẹnikẹ́ni tó bá ní ẹ̀tẹ̀, ìtújáde ara ní oríṣìíríṣìí tàbí ẹni tó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífọwọ́ kan òkú.
Rozkaż synom Izraelskim, aby wyrzucili z obozu każdego trędowatego, i każdego, który cierpi płynienie nasienia, i każdego, który się splugawił nad umarłym;
3 Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yálà ọkùnrin tàbí obìnrin, ẹ lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó kí wọn má ba à ba ibùdó wọn jẹ́ níbi tí èmi ń gbé láàrín wọn.”
Tak mężczyznę jako i niewiastę wyrzucicie; precz za obóz wyrzucicie je, aby nie splugawili obozu tych, między którymi Ja mieszkam.
4 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀; wọ́n lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó. Wọn ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
I uczynili tak synowie Izraelscy, a wygnali je precz za obóz; jako rozkazał Pan Mojżeszowi, tak uczynili synowie Izraelscy.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
Nad to rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
6 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli: ‘Nígbà tí ọkùnrin kan tàbí obìnrin kan bá ṣẹ̀ ara wọn lọ́nà kan tàbí òmíràn, tí wọ́n sì ṣe àìṣòótọ́ sí Olúwa, ẹni náà jẹ̀bi.
Powiedz synom Izraelskim: Mąż albo niewiasta, gdyby popełnili jakikolwiek grzech ludzki, dopuściwszy się występku przeciwko Panu, a byłaby winna ona dusza:
7 Ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀. Ó gbọdọ̀ san ẹ̀san rẹ̀ ní ojú owó, kí ó sì fi ìdámárùn-ún rẹ̀ lé e, kí ó sì fi fún ẹni tí òun jẹ̀bi rẹ̀.
Tedy wyznają grzech swój, którego się dopuścili, i wrócą to, w czem by winni byli cale; a przydawszy jeszcze nad to piątą część, oddadzą onemu, przeciw któremu zgrzeszyli.
8 Ṣùgbọ́n bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá ní ìbátan tí ó súnmọ́ ọn tí ó lè ṣe àtúnṣe àṣìṣe rẹ̀ náà fún, àtúnṣe náà jẹ́ ti Olúwa, ẹ sì gbọdọ̀ ko fún àlùfáà pẹ̀lú àgbò tí a fi ṣe ètùtù fún ẹni náà.
A jeźliby nie było tego, komu by szkodę trzeba nagrodzić, ona szkoda oddana będzie Panu, i zostanie kapłanowi oprócz barana oczyszczenia, przez którego ma być oczyszczony.
9 Gbogbo ọrẹ ohun mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli bá mú wá fún àlùfáà jẹ́ tirẹ̀.
Każda też ofiara podnoszenia ze wszech rzeczy poświęconych od synów Izraelskich, którą przyniosą do kapłana, jemu się dostanie.
10 Ọrẹ ohun mímọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan jẹ́ ti òun nìkan, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá fún àlùfáà yóò jẹ́ ti àlùfáà.’”
Owe rzeczy poświęcone od kogożkolwiek, jego będą; i kto by co oddał kapłanowi, jemu zostanie.
11 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
Zatem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
12 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀ kí o sọ fún wọn pé, ‘Bí ìyàwó ọkùnrin kan bá yapa tó sì ṣe àìṣòótọ́ sí i,
Mów do synów Izraelskich, a powiedz im: Każdy mąż, którego by żona wystąpiła, i dopuściłaby się grzechu przeciwko niemu;
13 nípa mímú kí ọkùnrin mìíràn bá a lòpọ̀ tí ó sì fi èyí pamọ́ fún ọkọ rẹ̀, tí a kò si gbá a mú nínú ìwà àìmọ́ rẹ̀ (nítorí pé kò sí ẹlẹ́rìí àti pé wọn kò ká a mọ́ nígbà tí ó ń dẹ́ṣẹ̀ náà).
A złączyłby się inszy z nią złączeniem nasienia, a byłoby to skryte przed oczyma męża jej, i taiłaby się, będąc splugawioną, a świadka by nie było przeciwko niej, aniby jej zastano;
14 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkọ rẹ̀ dé bi pé ó ń funra sí ìyàwó rẹ̀ yìí tí ìyàwó rẹ̀ sì wà ní àìmọ́ nítòótọ́, tàbí tí ẹ̀mí owú bá bà lé ọkùnrin kan tó sì ń jowú ìyàwó rẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó wà ní mímọ́,
Jednak przypadłby nań duch zapalczywości, i miałby w podejrzeniu żonę swą, która by splugawiona była; albo żeby przypadł nań duch zapalczywości, i miałby w podejrzeniu żonę swą, która by splugawiona nie była:
15 nígbà náà ni ọkùnrin yìí yóò mú ìyàwó rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ àlùfáà. Ọkùnrin náà yóò sì mú ọrẹ tí a yàn fún obìnrin náà, ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n efa ìyẹ̀fun barle. Kò gbọdọ̀ da òróró sí i, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fi tùràrí dídùn sí i nítorí pé ẹbọ ohun jíjẹ fún owú ni, èyí ti n mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sí ìrántí.
Tedy przywiedzie on mąż żonę swoję do kapłana, i przyniesie z nią ofiarę jej, dziesiątą część efy mąki jęczmiennej nie lejąc na nią oliwy, ani kładąc na nią kadzidła; albowiem jest ofiara podejrzenia, ofiara śniedna, pamiętna, przywodząca na pamięć grzech.
16 “‘Àlùfáà yóò sì mú un wá síwájú Olúwa.
A tak będzie ją ofiarował kapłan, i stawi ją przed oblicznością Pańską.
17 Àlùfáà yóò sì bu erùpẹ̀ ilẹ̀ àgọ́ sínú omi mímọ́ tó bù láti ìkòkò amọ̀.
I weźmie kapłan wody świętej w naczynie gliniane, i prochu, który będzie na tle przybytku, weźmie kapłan, a wsypie do wody.
18 Lẹ́yìn èyí, àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì tú irun orí obìnrin náà lé e lọ́wọ́, èyí ni ẹbọ ohun jíjẹ ti owú, àlùfáà fúnra rẹ̀ yóò sì gbé omi kíkorò tí ń mú ègún lọ́wọ́.
Potem postawi kapłan niewiastę przed Panem, i odkryje głowę niewiasty, a da w ręce jej ofiarę śniedną pamiętną; ofiara to śniedna podejrzenia; a kapłan będzie miał w ręce wodę gorzką przeklęstwa.
19 Àlùfáà yóò sì mú obìnrin náà búra, yóò wí pé, “Bí ọkùnrin mìíràn kò bá bá ọ lòpọ̀, tí ó kò sì yapa, tí o kò sì di aláìmọ́ níwọ̀n ìgbà tí ó wà lábẹ́ àṣẹ ọkọ rẹ̀, a jẹ́ pé omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí kò ní ṣe ọ́ níbi.
I poprzysięże ją kapłan, i rzecze do niewiasty: Jeźli nie spał kto inszy z tobą, a jeźliś się nie uniosła w grzech nieczysty przy mężu swym, bądź nienaruszona od tej wody gorzkiej przeklęstwa;
20 Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá ti yapa kúrò lọ́dọ̀ ọkọ rẹ, tí o bá ti ba ara rẹ jẹ́ nípa jíjẹ́ kí ọkùnrin tí kì í ṣe ọkọ rẹ bá ọ lòpọ̀,”
Ale jeźliżeś ustąpiła od męża twego, i jesteś splugawiona, a kto inny spał z tobą oprócz męża twego:
21 nígbà náà ni àlùfáà yóò mú obìnrin náà búra, yóò sọ fún obìnrin náà pé, “Kí Olúwa sọ ọ́ di ẹni ègún àti ẹni ìbáwí láàrín àwọn ènìyàn rẹ nípa mímú kí itan rẹ jẹrà, kí ikùn rẹ̀ sì wú.
Tedy poprzysięże kapłan niewiastę onę przysięgą przeklęstwa, i rzecze do niej: Niechaj cię poda Pan na złorzeczenie, i na przeklinanie między ludem twoim, przepuściwszy, aby łono twoje wypadło, i żywot twój opuchł:
22 Ǹjẹ́ kí omi yìí tí ń mú ègún wá wọ inú ara rẹ, kí ó mú ikùn rẹ̀ wú, kí ó sì mú itan rẹ̀ jẹrà dànù.” “‘Obìnrin náà yóò sì wí pé, “Àmín. Bẹ́ẹ̀ ni kó rí.”
Niechże przenikną te wody przeklęte wnętrzności twoje, aby opuchł żywot twój, i wypadło łono twoje; i odpowie niewiasta: Amen. Amen.
23 “‘Nígbà náà ni àlùfáà yóò kọ ègún yìí sínú ìwé kíká, yóò sì sìn ín sínú omi kíkorò náà.
Tedy napisze te przeklęstwa kapłan na księgach, a omyje je oną wodą gorzką;
24 Àlùfáà yóò sì mú kí obìnrin náà mu omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí, omi náà yóò wọ inú rẹ̀ yóò sì fa ìrora kíkorò fún obìnrin náà bí ó bá jẹ̀bi.
I da się napić niewieście wody gorzkiej przeklęstwa, i przenikną ją wody przeklęstwa, i obrócą się w gorzkość.
25 Àlùfáà yóò gba ọrẹ ohun jíjẹ owú náà lọ́wọ́ rẹ̀, yóò fì í síwájú Olúwa, yóò sì mú iná sórí pẹpẹ.
Potem weźmie kapłan z rąk niewiasty onej ofiarę śniedną podejrzenia, a będzie ją podnosił przed Panem, ofiarując ją na ołtarzu;
26 Àlùfáà yóò bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú ọrẹ ohun jíjẹ náà, yóò sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí lẹ́yìn tí ó ti mú kí obìnrin náà mu omi.
Weźmie też kapłan na garść pamiętnego z ofiary śniednej, i spali to na ołtarzu, potem da wypić wodę niewieście.
27 Bí ó bá ti mú obìnrin yìí mu omi náà, bí ó bá sì jẹ́ pé obìnrin náà ti ba ara rẹ̀ jẹ́, tí ó sì ṣe àìṣòótọ́ sí ọkọ rẹ̀, omi tí ń mú ègún wá, yóò wọ ara rẹ̀, yóò fa ìrora kíkorò fún un, ikùn rẹ̀ yóò wú, itan rẹ̀ yóò sì jẹrà dànù, yóò sì di ẹni ègún láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
A gdy się jej da napić onej wody, stanie się, jeźliby splugawiona była, i wystąpiła grzechem przeciwko mężowi swemu, że ją przenikną wody przeklęstwa, i obrócą się w gorzkość, i opuchnie żywot jej, i wypadnie łono jej, i stanie się niewiasta ona przeklęstwem między ludem swoim.
28 Ṣùgbọ́n tó bá jẹ́ pé obìnrin náà kò ba ara rẹ̀ jẹ́, tó sì jẹ́ mímọ́, yóò bọ́ nínú ẹ̀bi, yóò sì le bímọ.
A jeźliby nie była splugawiona niewiasta, aleby czysta była, niewinna zostanie, i dziatki rodzić będzie.
29 “‘Èyí ni òfin owú jíjẹ nígbà tí obìnrin tó wà lábẹ́ ọkọ bá ṣe a ṣe má ṣe, tí ó bá ba ara rẹ̀ jẹ́,
Tać jest ustawa podejrzenia, gdyby ustąpiła żona od męża swego, i byłaby splugawiona;
30 tàbí nígbà tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkùnrin kan nítorí pé ó funra sí ìyàwó rẹ̀. Àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin ti wí fún un.
Albo żeby na męża przypadł duch zapalczywy, a miałby w podejrzeniu żonę swoję, i postawiłby ją przed Panem, a uczyniłby z nią kapłan wszystko według tej ustawy;
31 Ara ọkọ rẹ̀ mọ́ nínú ẹ̀ṣẹ̀ yìí ṣùgbọ́n obìnrin náà yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.’”
Tedy nie będzie mąż on winien grzechu; ale niewiasta ona poniesie nieprawość swoję.

< Numbers 5 >