< Numbers 5 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
I korero ano a Ihowa ki a Mohi, i mea,
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn ó lé ẹnikẹ́ni tó bá ní ẹ̀tẹ̀, ìtújáde ara ní oríṣìíríṣìí tàbí ẹni tó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífọwọ́ kan òkú.
Whakahaua nga tama a Iharaira kia motuhia ketia atu nga repera katoa i roto i te puni, nga tangata katoa e rere ana te pirau, me nga tangata katoa e poke ana i te tupapaku.
3 Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yálà ọkùnrin tàbí obìnrin, ẹ lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó kí wọn má ba à ba ibùdó wọn jẹ́ níbi tí èmi ń gbé láàrín wọn.”
Ko te tane, ko te wahine, me ngare atu, me ngare e koutou ki waho o te puni: kei poke i a ratou o ratou puni e nohoia nei e ahau.
4 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀; wọ́n lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó. Wọn ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
Na peratia ana e nga tama a Iharaira, a motuhia ketia ana ratou i roto i te puni: rite tonu ki ta Ihowa i korero ai ki a Mohi ta nga tama a Iharaira i mea ai.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
I korero ano a Ihowa ki a Mohi, i mea,
6 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli: ‘Nígbà tí ọkùnrin kan tàbí obìnrin kan bá ṣẹ̀ ara wọn lọ́nà kan tàbí òmíràn, tí wọ́n sì ṣe àìṣòótọ́ sí Olúwa, ẹni náà jẹ̀bi.
Mea atu ki nga tama a Iharaira, Ki te mahia e te tangata, e te wahine ranei, tetahi mea e hara ai te tangata, hei mahi i te kino ki a Ihowa, a ka he taua wairua;
7 Ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀. Ó gbọdọ̀ san ẹ̀san rẹ̀ ní ojú owó, kí ó sì fi ìdámárùn-ún rẹ̀ lé e, kí ó sì fi fún ẹni tí òun jẹ̀bi rẹ̀.
Na me whaki to ratou hara i hara ai: me whakahoki e ia te mea i he ai ia, te tino mea, me tapiri ano ki tona whakarima, ka hoatu ai ki te tangata i hara nei ia ki a ia.
8 Ṣùgbọ́n bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá ní ìbátan tí ó súnmọ́ ọn tí ó lè ṣe àtúnṣe àṣìṣe rẹ̀ náà fún, àtúnṣe náà jẹ́ ti Olúwa, ẹ sì gbọdọ̀ ko fún àlùfáà pẹ̀lú àgbò tí a fi ṣe ètùtù fún ẹni náà.
Otiia ki te kahore he whanaunga o taua tangata hei hoatutanga mo te utu, me hoatu te utu mo te hara ki a Ihowa, ara ki te tohunga; hei tapiri mo te hipi whakamarie hei whakamarie mona.
9 Gbogbo ọrẹ ohun mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli bá mú wá fún àlùfáà jẹ́ tirẹ̀.
Na, ko nga whakahere hapahapai katoa o nga mea tapu katoa a nga tama a Iharaira, e kawea ana ki te tohunga, mana era.
10 Ọrẹ ohun mímọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan jẹ́ ti òun nìkan, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá fún àlùfáà yóò jẹ́ ti àlùfáà.’”
Mana ake nga mea tapu a te tangata: ko ta te tangata e hoatu ai ki te tohunga, mana tena.
11 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
I korero ano a Ihowa ki a Mohi, i mea,
12 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀ kí o sọ fún wọn pé, ‘Bí ìyàwó ọkùnrin kan bá yapa tó sì ṣe àìṣòótọ́ sí i,
Korero ki nga tama a Iharaira, mea atu ki a ratou, Ki te peka ke te wahine a tetahi tangata, a ka hara ki a ia,
13 nípa mímú kí ọkùnrin mìíràn bá a lòpọ̀ tí ó sì fi èyí pamọ́ fún ọkọ rẹ̀, tí a kò si gbá a mú nínú ìwà àìmọ́ rẹ̀ (nítorí pé kò sí ẹlẹ́rìí àti pé wọn kò ká a mọ́ nígbà tí ó ń dẹ́ṣẹ̀ náà).
A ka takoto, ka puremu tetahi ki a ia, a ka ngaro i nga kanohi o tana tahu, ka huna, a ka poke te wahine, kahore ano hoki he kaiwhakaatu mo tona he, kahore ano ia i mau rawa;
14 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkọ rẹ̀ dé bi pé ó ń funra sí ìyàwó rẹ̀ yìí tí ìyàwó rẹ̀ sì wà ní àìmọ́ nítòótọ́, tàbí tí ẹ̀mí owú bá bà lé ọkùnrin kan tó sì ń jowú ìyàwó rẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó wà ní mímọ́,
A ka tau ki a ia te wairua hae, a ka hae ia ki tana wahine, a ka poke te wahine: ki te tau ranei ki a ia te wairua hae, a ka hae ia ki tana wahine kihai nei i poke;
15 nígbà náà ni ọkùnrin yìí yóò mú ìyàwó rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ àlùfáà. Ọkùnrin náà yóò sì mú ọrẹ tí a yàn fún obìnrin náà, ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n efa ìyẹ̀fun barle. Kò gbọdọ̀ da òróró sí i, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fi tùràrí dídùn sí i nítorí pé ẹbọ ohun jíjẹ fún owú ni, èyí ti n mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sí ìrántí.
Katahi ka kawe taua tangata i tana wahine ki te tohunga, me kawe ano e ia ta te wahine whakahere hei mea mona, te whakatekau epa paraoa parei; kaua he hinu e ringihia ki runga, kaua ano he parakihe e hoatu ki runga; he whakahere totokore hoki mo te hae, he whakahere whakamahara, hei whakamahara ki te kino.
16 “‘Àlùfáà yóò sì mú un wá síwájú Olúwa.
Na ka nekehia mai ia e te tohunga, a ka whakaturia ki te aroaro o Ihowa:
17 Àlùfáà yóò sì bu erùpẹ̀ ilẹ̀ àgọ́ sínú omi mímọ́ tó bù láti ìkòkò amọ̀.
A ka mau te tohunga ki te wai tapu i te oko oneone; ka mau ano te tohunga ki tetahi wahi o te puehu o te papa o te tapenakara, ka maka ai ki te wai:
18 Lẹ́yìn èyí, àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì tú irun orí obìnrin náà lé e lọ́wọ́, èyí ni ẹbọ ohun jíjẹ ti owú, àlùfáà fúnra rẹ̀ yóò sì gbé omi kíkorò tí ń mú ègún lọ́wọ́.
Na ka whakaturia e te tohunga te wahine ki te aroaro o Ihowa, a ka tuku i nga makawe o te wahine kia mahora noa, ka hoatu ai i te whakahere whakamahara ki ona ringa, ara i te whakahere totokore mo te hae: hei te ringa ia o te tohunga te wai kawa e tau ai te kanga:
19 Àlùfáà yóò sì mú obìnrin náà búra, yóò wí pé, “Bí ọkùnrin mìíràn kò bá bá ọ lòpọ̀, tí ó kò sì yapa, tí o kò sì di aláìmọ́ níwọ̀n ìgbà tí ó wà lábẹ́ àṣẹ ọkọ rẹ̀, a jẹ́ pé omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí kò ní ṣe ọ́ níbi.
Na ka whakaoati te tohunga i a ia, a ka mea ki te wahine, Ki te mea kahore ano tetahi tangata i takoto ki a koe, ki te kahore ano hoki koe i peka atu, i poke, i te mea i raro koe i tau tane, kia ora koe i tenei wai kawa e tau ai te kanga:
20 Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá ti yapa kúrò lọ́dọ̀ ọkọ rẹ, tí o bá ti ba ara rẹ jẹ́ nípa jíjẹ́ kí ọkùnrin tí kì í ṣe ọkọ rẹ bá ọ lòpọ̀,”
Ki te mea ia kua peka ke koe, i te mea i raro koe i tau tane, a kua poke koe, a kua takoto ki a koe tetahi tangata ehara nei i te tane nau:
21 nígbà náà ni àlùfáà yóò mú obìnrin náà búra, yóò sọ fún obìnrin náà pé, “Kí Olúwa sọ ọ́ di ẹni ègún àti ẹni ìbáwí láàrín àwọn ènìyàn rẹ nípa mímú kí itan rẹ jẹrà, kí ikùn rẹ̀ sì wú.
Katahi ka whakaoati te tohunga i te wahine ki te oati kanga, a ka mea te tohunga ki te wahine, Ma Ihowa koe e mea hei kanga, hei oati i roto i tou iwi, ina mea a Ihowa kia pirau tou huha, kia pupuhi hoki tou puku;
22 Ǹjẹ́ kí omi yìí tí ń mú ègún wá wọ inú ara rẹ, kí ó mú ikùn rẹ̀ wú, kí ó sì mú itan rẹ̀ jẹrà dànù.” “‘Obìnrin náà yóò sì wí pé, “Àmín. Bẹ́ẹ̀ ni kó rí.”
A ka tae ki roto ki ou whekau tenei wai e tau ai te kanga, e pupuhi ai tou puku, e pirau ai tou huha: me ki te wahine, Amine, Amine.
23 “‘Nígbà náà ni àlùfáà yóò kọ ègún yìí sínú ìwé kíká, yóò sì sìn ín sínú omi kíkorò náà.
A me tuhituhi enei kanga e te tohunga ki te pukapuka, ka horoi atu ano e ia ki roto ki te wai kawa:
24 Àlùfáà yóò sì mú kí obìnrin náà mu omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí, omi náà yóò wọ inú rẹ̀ yóò sì fa ìrora kíkorò fún obìnrin náà bí ó bá jẹ̀bi.
Na ka whakainumia e ia te wahine ki te wai kawa e tau ai te kanga, a ka tae te wai e tau ai te kanga ki roto ki a ia, ka kawa.
25 Àlùfáà yóò gba ọrẹ ohun jíjẹ owú náà lọ́wọ́ rẹ̀, yóò fì í síwájú Olúwa, yóò sì mú iná sórí pẹpẹ.
Me tango hoki e te tohunga te whakahere mo te hae i te ringa o te wahine, a ka poipoia te whakahere ki te aroaro o Ihowa, ka whakaherea ki runga ki te aata:
26 Àlùfáà yóò bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú ọrẹ ohun jíjẹ náà, yóò sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí lẹ́yìn tí ó ti mú kí obìnrin náà mu omi.
Na ka aohia e te tohunga tetahi wahi o te whakahere, kia ki te ringa, ko tona whakamaharatanga hoki, a ka tahuna ki runga ki te aata, a muri iho ka whakainumia te wahine ki te wai.
27 Bí ó bá ti mú obìnrin yìí mu omi náà, bí ó bá sì jẹ́ pé obìnrin náà ti ba ara rẹ̀ jẹ́, tí ó sì ṣe àìṣòótọ́ sí ọkọ rẹ̀, omi tí ń mú ègún wá, yóò wọ ara rẹ̀, yóò fa ìrora kíkorò fún un, ikùn rẹ̀ yóò wú, itan rẹ̀ yóò sì jẹrà dànù, yóò sì di ẹni ègún láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
A ka oti ia te whakainu ki te wai, na ki te mea kua poke ia, kua hara ki tana tahu, na ka tae ki roto ki a ia te wai e tau ai te kanga, ka kawa, a ka pupuhi tona puku, ka pirau hoki tona huha: a hei mea kanga tena wahine i roto i tona iwi.
28 Ṣùgbọ́n tó bá jẹ́ pé obìnrin náà kò ba ara rẹ̀ jẹ́, tó sì jẹ́ mímọ́, yóò bọ́ nínú ẹ̀bi, yóò sì le bímọ.
A ki te mea kihai i poke te wahine, a e ma ana; na ka ora, a ka whai tamariki.
29 “‘Èyí ni òfin owú jíjẹ nígbà tí obìnrin tó wà lábẹ́ ọkọ bá ṣe a ṣe má ṣe, tí ó bá ba ara rẹ̀ jẹ́,
Ko te ture tenei mo nga hae, mehemea te wahine, kei raro nei ia i tana tane, ka peka ke, a ka poke;
30 tàbí nígbà tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkùnrin kan nítorí pé ó funra sí ìyàwó rẹ̀. Àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin ti wí fún un.
Ina tau iho ranei te wairua hae ki tetahi, a ka hae ia ki tana wahine; na me whakatu taua wahine e ia ki te aroaro o Ihowa; na ka mahia e te tohunga tenei ture katoa ki a ia.
31 Ara ọkọ rẹ̀ mọ́ nínú ẹ̀ṣẹ̀ yìí ṣùgbọ́n obìnrin náà yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.’”
Na ka kore he he mo te tangata, a ka waha e taua wahine tona kino.

< Numbers 5 >