< Numbers 5 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse, et dit:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn ó lé ẹnikẹ́ni tó bá ní ẹ̀tẹ̀, ìtújáde ara ní oríṣìíríṣìí tàbí ẹni tó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífọwọ́ kan òkú.
« Ordonne aux enfants d'Israël de faire sortir du camp tout lépreux, toute personne qui a des pertes, et quiconque est souillé par un cadavre.
3 Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yálà ọkùnrin tàbí obìnrin, ẹ lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó kí wọn má ba à ba ibùdó wọn jẹ́ níbi tí èmi ń gbé láàrín wọn.”
Tu feras sortir du camp l'homme et la femme, afin qu'ils ne souillent pas leur camp, au milieu duquel j'habite. »
4 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀; wọ́n lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó. Wọn ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
Les enfants d'Israël firent ainsi, et les mirent hors du camp; les enfants d'Israël firent ce que l'Éternel avait dit à Moïse.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse et dit:
6 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli: ‘Nígbà tí ọkùnrin kan tàbí obìnrin kan bá ṣẹ̀ ara wọn lọ́nà kan tàbí òmíràn, tí wọ́n sì ṣe àìṣòótọ́ sí Olúwa, ẹni náà jẹ̀bi.
Parle aux enfants d'Israël: « Lorsqu'un homme ou une femme commettra un des péchés que commettent les hommes, au point de porter atteinte à Yahvé, et que cette âme sera coupable,
7 Ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀. Ó gbọdọ̀ san ẹ̀san rẹ̀ ní ojú owó, kí ó sì fi ìdámárùn-ún rẹ̀ lé e, kí ó sì fi fún ẹni tí òun jẹ̀bi rẹ̀.
il confessera le péché qu'il a commis; il restituera la totalité de sa faute, y ajoutera un cinquième et la donnera à celui pour qui il s'est rendu coupable.
8 Ṣùgbọ́n bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá ní ìbátan tí ó súnmọ́ ọn tí ó lè ṣe àtúnṣe àṣìṣe rẹ̀ náà fún, àtúnṣe náà jẹ́ ti Olúwa, ẹ sì gbọdọ̀ ko fún àlùfáà pẹ̀lú àgbò tí a fi ṣe ètùtù fún ẹni náà.
Mais si l'homme n'a pas de parent à qui restituer la culpabilité, la restitution de la culpabilité qui sera faite à Yahvé appartiendra au prêtre, en plus du bélier d'expiation, par lequel l'expiation sera faite pour lui.
9 Gbogbo ọrẹ ohun mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli bá mú wá fún àlùfáà jẹ́ tirẹ̀.
Toute offrande par élévation de toutes les choses saintes des enfants d'Israël, qu'ils présenteront au sacrificateur, lui appartiendra.
10 Ọrẹ ohun mímọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan jẹ́ ti òun nìkan, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá fún àlùfáà yóò jẹ́ ti àlùfáà.’”
Les choses saintes de chacun seront à lui; tout ce que quelqu'un donnera au prêtre sera à lui.'"
11 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
Yahvé parla à Moïse, et dit:
12 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀ kí o sọ fún wọn pé, ‘Bí ìyàwó ọkùnrin kan bá yapa tó sì ṣe àìṣòótọ́ sí i,
« Parle aux enfants d'Israël, et dis-leur: Si la femme d'un homme s'égare et lui est infidèle,
13 nípa mímú kí ọkùnrin mìíràn bá a lòpọ̀ tí ó sì fi èyí pamọ́ fún ọkọ rẹ̀, tí a kò si gbá a mú nínú ìwà àìmọ́ rẹ̀ (nítorí pé kò sí ẹlẹ́rìí àti pé wọn kò ká a mọ́ nígbà tí ó ń dẹ́ṣẹ̀ náà).
et qu'un homme couche avec elle charnellement, et que cela soit caché aux yeux de son mari, et que cela reste caché, et qu'elle soit souillée, il n'y a pas de témoin contre elle, et elle n'est pas prise sur le fait;
14 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkọ rẹ̀ dé bi pé ó ń funra sí ìyàwó rẹ̀ yìí tí ìyàwó rẹ̀ sì wà ní àìmọ́ nítòótọ́, tàbí tí ẹ̀mí owú bá bà lé ọkùnrin kan tó sì ń jowú ìyàwó rẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó wà ní mímọ́,
et l'esprit de jalousie vient sur lui, et il est jaloux de sa femme et elle est souillée; ou si l'esprit de jalousie vient sur lui, et il est jaloux de sa femme et elle n'est pas souillée;
15 nígbà náà ni ọkùnrin yìí yóò mú ìyàwó rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ àlùfáà. Ọkùnrin náà yóò sì mú ọrẹ tí a yàn fún obìnrin náà, ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n efa ìyẹ̀fun barle. Kò gbọdọ̀ da òróró sí i, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fi tùràrí dídùn sí i nítorí pé ẹbọ ohun jíjẹ fún owú ni, èyí ti n mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sí ìrántí.
alors l'homme amènera sa femme au prêtre, et il apportera pour elle une offrande: un dixième d'un épha de farine d'orge. Il ne versera pas d'huile dessus et n'y mettra pas d'encens, car c'est une offrande de jalousie, une offrande de souvenir, pour rappeler l'iniquité.
16 “‘Àlùfáà yóò sì mú un wá síwájú Olúwa.
Le prêtre la fera approcher et la présentera devant l'Éternel.
17 Àlùfáà yóò sì bu erùpẹ̀ ilẹ̀ àgọ́ sínú omi mímọ́ tó bù láti ìkòkò amọ̀.
Le prêtre prendra de l'eau bénite dans un vase de terre; il prendra un peu de la poussière qui est sur le sol du tabernacle et la mettra dans l'eau.
18 Lẹ́yìn èyí, àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì tú irun orí obìnrin náà lé e lọ́wọ́, èyí ni ẹbọ ohun jíjẹ ti owú, àlùfáà fúnra rẹ̀ yóò sì gbé omi kíkorò tí ń mú ègún lọ́wọ́.
Le prêtre placera la femme devant l'Éternel, il détachera les cheveux de la tête de la femme, et il mettra dans ses mains l'offrande de farine commémorative, qui est l'offrande de farine de jalousie. Le prêtre aura dans sa main l'eau amère qui apporte la malédiction.
19 Àlùfáà yóò sì mú obìnrin náà búra, yóò wí pé, “Bí ọkùnrin mìíràn kò bá bá ọ lòpọ̀, tí ó kò sì yapa, tí o kò sì di aláìmọ́ níwọ̀n ìgbà tí ó wà lábẹ́ àṣẹ ọkọ rẹ̀, a jẹ́ pé omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí kò ní ṣe ọ́ níbi.
Le prêtre lui fera prêter serment et dira à la femme: « Si aucun homme n'a couché avec toi, et si tu ne t'es pas égarée dans l'impureté, étant sous l'autorité de ton mari, libère-toi de cette eau amère qui entraîne la malédiction.
20 Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá ti yapa kúrò lọ́dọ̀ ọkọ rẹ, tí o bá ti ba ara rẹ jẹ́ nípa jíjẹ́ kí ọkùnrin tí kì í ṣe ọkọ rẹ bá ọ lòpọ̀,”
Mais si tu t'es égarée, étant sous l'autorité de ton mari, et si tu t'es souillée, et qu'un homme a couché avec toi en dehors de ton mari - »
21 nígbà náà ni àlùfáà yóò mú obìnrin náà búra, yóò sọ fún obìnrin náà pé, “Kí Olúwa sọ ọ́ di ẹni ègún àti ẹni ìbáwí láàrín àwọn ènìyàn rẹ nípa mímú kí itan rẹ jẹrà, kí ikùn rẹ̀ sì wú.
alors le prêtre fera jurer la femme avec le serment de malédiction, et le prêtre dira à la femme: « Que Yahvé te maudisse et te fasse jurer parmi ton peuple, lorsque Yahvé permettra que ta cuisse se dérobe et que ton corps se gonfle;
22 Ǹjẹ́ kí omi yìí tí ń mú ègún wá wọ inú ara rẹ, kí ó mú ikùn rẹ̀ wú, kí ó sì mú itan rẹ̀ jẹrà dànù.” “‘Obìnrin náà yóò sì wí pé, “Àmín. Bẹ́ẹ̀ ni kó rí.”
et que cette eau qui apporte la malédiction entrera dans tes entrailles, fera gonfler ton corps et tomber ta cuisse ». La femme dira: « Amen, Amen. »
23 “‘Nígbà náà ni àlùfáà yóò kọ ègún yìí sínú ìwé kíká, yóò sì sìn ín sínú omi kíkorò náà.
"'Le prêtre écrira ces malédictions dans un livre, et il les fera passer dans l'eau d'amertume.
24 Àlùfáà yóò sì mú kí obìnrin náà mu omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí, omi náà yóò wọ inú rẹ̀ yóò sì fa ìrora kíkorò fún obìnrin náà bí ó bá jẹ̀bi.
Il fera boire à la femme l'eau amère qui provoque la malédiction; l'eau qui provoque la malédiction entrera en elle et deviendra amère.
25 Àlùfáà yóò gba ọrẹ ohun jíjẹ owú náà lọ́wọ́ rẹ̀, yóò fì í síwájú Olúwa, yóò sì mú iná sórí pẹpẹ.
Le prêtre prendra de la main de la femme l'offrande de jalousie; il agitera l'offrande devant l'Éternel et l'apportera sur l'autel.
26 Àlùfáà yóò bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú ọrẹ ohun jíjẹ náà, yóò sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí lẹ́yìn tí ó ti mú kí obìnrin náà mu omi.
Le prêtre prendra une poignée de l'offrande de farine, comme portion commémorative, et il la brûlera sur l'autel; ensuite, il fera boire l'eau à la femme.
27 Bí ó bá ti mú obìnrin yìí mu omi náà, bí ó bá sì jẹ́ pé obìnrin náà ti ba ara rẹ̀ jẹ́, tí ó sì ṣe àìṣòótọ́ sí ọkọ rẹ̀, omi tí ń mú ègún wá, yóò wọ ara rẹ̀, yóò fa ìrora kíkorò fún un, ikùn rẹ̀ yóò wú, itan rẹ̀ yóò sì jẹrà dànù, yóò sì di ẹni ègún láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Lorsqu'il lui aura fait boire l'eau, il arrivera, si elle s'est souillée et a commis une infidélité envers son mari, que l'eau qui est à l'origine de la malédiction entrera en elle et deviendra amère, que son corps enflera, que sa cuisse tombera, et que la femme sera maudite parmi son peuple.
28 Ṣùgbọ́n tó bá jẹ́ pé obìnrin náà kò ba ara rẹ̀ jẹ́, tó sì jẹ́ mímọ́, yóò bọ́ nínú ẹ̀bi, yóò sì le bímọ.
Si la femme n'est pas souillée, mais qu'elle est pure, alors elle sera libre et concevra une progéniture.
29 “‘Èyí ni òfin owú jíjẹ nígbà tí obìnrin tó wà lábẹ́ ọkọ bá ṣe a ṣe má ṣe, tí ó bá ba ara rẹ̀ jẹ́,
"'Voici la loi de la jalousie, lorsqu'une femme, sous l'autorité de son mari, s'égare et se souille,
30 tàbí nígbà tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkùnrin kan nítorí pé ó funra sí ìyàwó rẹ̀. Àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin ti wí fún un.
ou lorsque l'esprit de jalousie s'empare d'un homme et qu'il est jaloux de sa femme; alors il présentera la femme devant Yahvé, et le prêtre exécutera sur elle toute cette loi.
31 Ara ọkọ rẹ̀ mọ́ nínú ẹ̀ṣẹ̀ yìí ṣùgbọ́n obìnrin náà yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.’”
L'homme sera libéré de son iniquité, et la femme portera son iniquité.'"

< Numbers 5 >