< Numbers 5 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
And Yahweh spake unto Moses, saying: —
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn ó lé ẹnikẹ́ni tó bá ní ẹ̀tẹ̀, ìtújáde ara ní oríṣìíríṣìí tàbí ẹni tó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífọwọ́ kan òkú.
Command the sons of Israel, that they send forth out of the camp, every leper, and every one that hath a flux, —and every one that is unclean by the dead:
3 Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yálà ọkùnrin tàbí obìnrin, ẹ lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó kí wọn má ba à ba ibùdó wọn jẹ́ níbi tí èmi ń gbé láàrín wọn.”
whether male or female, ye shall send them forth, unto the outside of the camp, shall ye send them, —that they make not their camps unclean, in the midst whereof, I, have my habitation.
4 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀; wọ́n lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó. Wọn ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
And the sons of Israel did so, and sent them forth unto the outside of the camp, —as Yahweh spake unto Moses, so, did the sons of Israel.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
And Yahweh spake unto Moses, saying:
6 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli: ‘Nígbà tí ọkùnrin kan tàbí obìnrin kan bá ṣẹ̀ ara wọn lọ́nà kan tàbí òmíràn, tí wọ́n sì ṣe àìṣòótọ́ sí Olúwa, ẹni náà jẹ̀bi.
Speak unto the sons of Israel: When any man or woman, shall do aught of any human sin, in acting unfaithfully against Yahweh, —and that person shall become aware of his guilt,
7 Ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀. Ó gbọdọ̀ san ẹ̀san rẹ̀ ní ojú owó, kí ó sì fi ìdámárùn-ún rẹ̀ lé e, kí ó sì fi fún ẹni tí òun jẹ̀bi rẹ̀.
then shall they confess their sin which they have done, and he shall make good that wherein he is guilty, in the principal thereof, and the fifth part thereof, shall he add thereunto, —and give to him against whom he is guilty,
8 Ṣùgbọ́n bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá ní ìbátan tí ó súnmọ́ ọn tí ó lè ṣe àtúnṣe àṣìṣe rẹ̀ náà fún, àtúnṣe náà jẹ́ ti Olúwa, ẹ sì gbọdọ̀ ko fún àlùfáà pẹ̀lú àgbò tí a fi ṣe ètùtù fún ẹni náà.
But if one have no kinsman unto whom he may make good that wherein he is guilty, then that wherein he is guilty, which is to be restored to Yahweh, shall be the priest’s, —besides the ram of propitiation, wherewith a propitiatory-covering is to be put over him.
9 Gbogbo ọrẹ ohun mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli bá mú wá fún àlùfáà jẹ́ tirẹ̀.
And every heave-offering, of all the hallowed things of the sons of Israel which they bring near to the priest, unto him, shall it belong.
10 Ọrẹ ohun mímọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan jẹ́ ti òun nìkan, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá fún àlùfáà yóò jẹ́ ti àlùfáà.’”
And, every man’s hallowed things, shall be, his own, —what any man giveth to the priest, shall be his.
11 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
And Yahweh spake unto Moses saying:
12 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀ kí o sọ fún wọn pé, ‘Bí ìyàwó ọkùnrin kan bá yapa tó sì ṣe àìṣòótọ́ sí i,
Speak unto the sons of Israel, and thou shalt say unto them, —When any man’s wife, shall turn aside, and commit against him an act of unfaithfulness;
13 nípa mímú kí ọkùnrin mìíràn bá a lòpọ̀ tí ó sì fi èyí pamọ́ fún ọkọ rẹ̀, tí a kò si gbá a mú nínú ìwà àìmọ́ rẹ̀ (nítorí pé kò sí ẹlẹ́rìí àti pé wọn kò ká a mọ́ nígbà tí ó ń dẹ́ṣẹ̀ náà).
and a man shall lie with her carnally, and it shall be concealed from the eyes of her husband and be kept close but, she, hath committed uncleanness, —though witness, there is none against her, and she, hath not been caught;
14 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkọ rẹ̀ dé bi pé ó ń funra sí ìyàwó rẹ̀ yìí tí ìyàwó rẹ̀ sì wà ní àìmọ́ nítòótọ́, tàbí tí ẹ̀mí owú bá bà lé ọkùnrin kan tó sì ń jowú ìyàwó rẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó wà ní mímọ́,
but there shall pass over him a spirit of jealousy, and he shall become jealous of his wife, she having committed uncleanness, —or there shall pass over him a spirit of jealousy, and he shall become jealous of his wife, she not, having committed uncleanness,
15 nígbà náà ni ọkùnrin yìí yóò mú ìyàwó rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ àlùfáà. Ọkùnrin náà yóò sì mú ọrẹ tí a yàn fún obìnrin náà, ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n efa ìyẹ̀fun barle. Kò gbọdọ̀ da òróró sí i, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fi tùràrí dídùn sí i nítorí pé ẹbọ ohun jíjẹ fún owú ni, èyí ti n mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sí ìrántí.
then shall the man bring in his wife unto the priest, and shall bring in her offering for her, the tenth of an ephah of the meal of barley, —he shall not pour thereon oil, nor put thereon frankincense, for a jealousy gift, it is, a reminding gift bringing to mind iniquity.
16 “‘Àlùfáà yóò sì mú un wá síwájú Olúwa.
Then shall the priest bring her near, —and cause her to stand before Yahweh;
17 Àlùfáà yóò sì bu erùpẹ̀ ilẹ̀ àgọ́ sínú omi mímọ́ tó bù láti ìkòkò amọ̀.
and the priest shall take hallowed water in an earthen vessel, —and of the dust which shall be upon the floor of the habitation, shall the priest take, and put into the water;
18 Lẹ́yìn èyí, àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì tú irun orí obìnrin náà lé e lọ́wọ́, èyí ni ẹbọ ohun jíjẹ ti owú, àlùfáà fúnra rẹ̀ yóò sì gbé omi kíkorò tí ń mú ègún lọ́wọ́.
and the priest shall cause the woman to stand before Yahweh, and shall bare the head of the woman, and shall place upon her hands the reminding gift, it being a jealousy gift, —and in the hand of the priest, shall be the deadly water that bringeth a curse;
19 Àlùfáà yóò sì mú obìnrin náà búra, yóò wí pé, “Bí ọkùnrin mìíràn kò bá bá ọ lòpọ̀, tí ó kò sì yapa, tí o kò sì di aláìmọ́ níwọ̀n ìgbà tí ó wà lábẹ́ àṣẹ ọkọ rẹ̀, a jẹ́ pé omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí kò ní ṣe ọ́ níbi.
and the priest shall put her on oath and shall say unto the woman: —If no man hath lain with thee, and if thou hast not turned aside in uncleanness, [unto another] instead of thy husband, be thou clear from this deadly water that causeth a curse.
20 Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá ti yapa kúrò lọ́dọ̀ ọkọ rẹ, tí o bá ti ba ara rẹ jẹ́ nípa jíjẹ́ kí ọkùnrin tí kì í ṣe ọkọ rẹ bá ọ lòpọ̀,”
But, if, thou, hast turned aside, [to another] instead of thy husband and if thou hast made thyself unclean, —in that a man hath known thee carnally, other than thy husband,
21 nígbà náà ni àlùfáà yóò mú obìnrin náà búra, yóò sọ fún obìnrin náà pé, “Kí Olúwa sọ ọ́ di ẹni ègún àti ẹni ìbáwí láàrín àwọn ènìyàn rẹ nípa mímú kí itan rẹ jẹrà, kí ikùn rẹ̀ sì wú.
then shall the priest put the woman on oath with an oath of cursing, and the priest shall say unto the woman, Yahweh give thee up for a curse and for an oath in the midst of thy people, —in that Yahweh shall give up thy thigh to fall away, and thy womb to swell:
22 Ǹjẹ́ kí omi yìí tí ń mú ègún wá wọ inú ara rẹ, kí ó mú ikùn rẹ̀ wú, kí ó sì mú itan rẹ̀ jẹrà dànù.” “‘Obìnrin náà yóò sì wí pé, “Àmín. Bẹ́ẹ̀ ni kó rí.”
so shall this water that causeth a curse enter into thy body, causing womb to swell and thigh to fall away. And the woman shall say, Amen, Amen.
23 “‘Nígbà náà ni àlùfáà yóò kọ ègún yìí sínú ìwé kíká, yóò sì sìn ín sínú omi kíkorò náà.
Then shall the priest write these curses in a scroll, —and wipe them out into the deadly water;
24 Àlùfáà yóò sì mú kí obìnrin náà mu omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí, omi náà yóò wọ inú rẹ̀ yóò sì fa ìrora kíkorò fún obìnrin náà bí ó bá jẹ̀bi.
and shall cause the woman to drink the deadly water that causeth a curse, —and the deadly water that causeth a curse shall enter into her.
25 Àlùfáà yóò gba ọrẹ ohun jíjẹ owú náà lọ́wọ́ rẹ̀, yóò fì í síwájú Olúwa, yóò sì mú iná sórí pẹpẹ.
Then shall the priest take from the hand of the woman the jealousy meal-offering, —and shall wave the meal-offering before Yahweh, and bring it near unto the altar;
26 Àlùfáà yóò bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú ọrẹ ohun jíjẹ náà, yóò sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí lẹ́yìn tí ó ti mú kí obìnrin náà mu omi.
and the priest shall take a handful from the meal-offering, a remembrancer thereof, and make a perfume at the altar, —and afterwards, shall cause the woman to drink the water.
27 Bí ó bá ti mú obìnrin yìí mu omi náà, bí ó bá sì jẹ́ pé obìnrin náà ti ba ara rẹ̀ jẹ́, tí ó sì ṣe àìṣòótọ́ sí ọkọ rẹ̀, omi tí ń mú ègún wá, yóò wọ ara rẹ̀, yóò fa ìrora kíkorò fún un, ikùn rẹ̀ yóò wú, itan rẹ̀ yóò sì jẹrà dànù, yóò sì di ẹni ègún láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
And as soon as he causeth her to drink, the water, then shall it be, that, if she have fallen into uncleanness and committed unfaithfulness against her husband, as soon as the deadly water that causeth a curse hath entered into her, so soon shall her womb swell and her thigh fall away, —thus shall the woman become a curse in the midst of her people.
28 Ṣùgbọ́n tó bá jẹ́ pé obìnrin náà kò ba ara rẹ̀ jẹ́, tó sì jẹ́ mímọ́, yóò bọ́ nínú ẹ̀bi, yóò sì le bímọ.
But, if the woman have not fallen into uncleanness, but is pure, then shall she be clear and shall bear seed.
29 “‘Èyí ni òfin owú jíjẹ nígbà tí obìnrin tó wà lábẹ́ ọkọ bá ṣe a ṣe má ṣe, tí ó bá ba ara rẹ̀ jẹ́,
This, is the law of jealousies, —when a wife shall turn aside [to another] instead of her husband, and fall into uncleanness;
30 tàbí nígbà tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkùnrin kan nítorí pé ó funra sí ìyàwó rẹ̀. Àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin ti wí fún un.
or when there passeth over, a husband, a spirit of jealousy, and he becometh jealous of his wife, then shall he cause the woman to stand before Yahweh, and the priest shall execute upon her all this law:
31 Ara ọkọ rẹ̀ mọ́ nínú ẹ̀ṣẹ̀ yìí ṣùgbọ́n obìnrin náà yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.’”
thus shall the man be clear of iniquity; but that woman, shall bear her iniquity.

< Numbers 5 >